< Djela apostolska 15 >

1 Uto neki siđoše iz Judeje i počeše učiti braću: “Ako se ne obrežete po običaju Mojsijevu, ne možete se spasiti.”
Àwọn ọkùnrin kan tí Judea sọ̀kalẹ̀ wá, wọ́n sì kọ́ àwọn arákùnrin pé, “Bí kò ṣe pé a bá kọ yín ni ilà bí ìṣe Mose, ẹ̀yin kí yóò lè là.”
2 Kad između njih te Pavla i Barnabe nasta prepirka i raspra nemalena, odrediše da Pavao i Barnaba i još neki drugi između njih uzađu u Jeruzalem k apostolima i starješinama poradi tog pitanja.
Nígbà tí Paulu àti Barnaba ni ìyapa àti ìyàn jíjà tí kò mọ níwọ̀n pẹ̀lú ara wọn, wọ́n yan Paulu àti Barnaba àti àwọn mìíràn nínú aposteli kí wọn gòkè lọ sí Jerusalẹmu, sọ́dọ̀ àwọn alàgbà nítorí ọ̀ràn yìí.
3 Oni su dakle, ispraćeni od Crkve, prolazili kroz Feniciju i Samariju pripovijedajući o obraćenju pogana i donoseći svoj braći veliku radost.
Nítorí náà, bí ìjọ ti rán wọn jáde lọ sí ọ̀nà wọn, wọn la Fonisia àti Samaria kọjá, wọ́n ń ròyìn ìyípadà àwọn aláìkọlà, wọ́n sì fi ayọ̀ ńlá fún gbogbo àwọn arákùnrin.
4 Kada pak stigoše u Jeruzalem, primi ih Crkva, apostoli i starješine. Ispripovjediše što sve Bog učini po njima.
Nígbà tí wọn sì dé Jerusalẹmu, ìjọ àti àwọn aposteli àti àwọn alàgbà tẹ́wọ́gbà wọ́n, wọ́n sì ròyìn ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti ṣe nípasẹ̀ wọn.
5 Onda ustanu neki od onih što iz farizejske sljedbe bijahu prigrlili vjeru pa reknu: “Treba ih obrezati i zapovjediti im da opslužuju Zakon Mojsijev.”
Ṣùgbọ́n àwọn kan nínú ẹ̀yà àwọn Farisi tí wọ́n gbàgbọ́ dìde, wọ́n ń wí pé, “A ní láti kọ wọ́n ní ilà, àti láti pàṣẹ fún wọn pé kí wọn máa pa òfin Mose mọ́.”
6 Nato se apostoli i starješine sastanu da to razmotre.
Àwọn aposteli àti àwọn alàgbà péjọ láti rí si ọ̀ràn yìí.
7 Nakon duge raspre ustade Petar i reče im: “Braćo, vi znate kako me Bog od najprvih dana između vas izabra da iz mojih usta pogani čuju riječ evanđelja i uzvjeruju.
Nígbà tí iyàn sì di púpọ̀, Peteru dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ará, ẹ̀yin mọ̀ pé, láti ìbẹ̀rẹ̀ ni Ọlọ́run ti yàn nínú yín pé, kí àwọn aláìkọlà lè gbọ́ ọ̀rọ̀ ìyìnrere láti ẹnu mi, kí wọn sì gbàgbọ́.
8 I Bog, Poznavatelj srdaca, posvjedoči za njih: dade im Duha Svetoga kao i nama.
Ọlọ́run, tí ó jẹ́ olùmọ̀-ọkàn, sì jẹ́ wọn lẹ́rìí, ó fún wọn ni Ẹ̀mí Mímọ́, gẹ́gẹ́ bí àwa.
9 Nikakve razlike nije pravio između nas i njih: vjerom očisti njihova srca.
Kò sí fi ìyàtọ̀ sí àárín àwa àti àwọn, ó ń fi ìgbàgbọ́ wẹ̀ wọ́n lọ́kàn mọ́.
10 Što dakle sada iskušavate Boga stavljajući učenicima na vrat jaram kojeg ni oci naši ni mi nismo mogli nositi?
Ǹjẹ́ nítorí náà èéṣe tí ẹ̀yin o fi dán Ọlọ́run wò, láti fi àjàgà bọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn lọ́rùn, èyí tí àwọn baba wa àti àwa kò lè rù?
11 Vjerujemo, naprotiv: po milosti smo Gospodina Isusa spašeni, baš kao i oni.”
Ṣùgbọ́n àwa gbàgbọ́ pé nípa oore-ọ̀fẹ́ Olúwa Jesu àwa ó là, gẹ́gẹ́ bí àwọn.”
12 Nato sve mnoštvo umuknu. Slušali su Barnabu i Pavla koji pripovjedahu kolika je znamenja i čudesa Bog po njima učinio među poganima.
Gbogbo àjọ sí dákẹ́, wọ́n sì fi etí sí Barnaba àti Paulu, tí wọn ń ròyìn iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì tí Ọlọ́run tí ti ọwọ́ wọn ṣe láàrín àwọn aláìkọlà.
13 Kad oni ušutješe, progovori Jakov: “Poslušajte me, braćo!
Lẹ́yìn tí wọn sì dákẹ́, Jakọbu dáhùn, wí pé, “Ará, ẹ gbọ́ tèmi,
14 Šimun je izložio kako se Bog već na početku pobrinu između pogana uzeti narod imenu svojemu.
Simeoni ti ròyìn bí Ọlọ́run ti kọ́kọ́ bojú wo àwọn aláìkọlà, láti yàn ènìyàn nínú wọn fún orúkọ rẹ̀.
15 S time su u skladu riječi Proroka. Ovako je doista pisano:
Báyìí ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì bá ṣe déédé; bí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé:
16 Nakon toga vratit ću se i opet podići pali šator Davidov, iz ruševina ga podići, opet ga sazidati
“‘Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni èmi ó padà, èmi ó sì tún àgọ́ Dafidi pa tí ó ti wó lulẹ̀: èmi ó sì tún ahoro rẹ̀ kọ́, èmi ó sì gbé e ró.
17 da preostali ljudi potraže Gospodina i svi pogani na koje je zazvano ime moje, govori Gospodin, koji to
Kí àwọn ènìyàn ìyókù lè máa wá Olúwa, àti gbogbo àwọn kèfèrí, lára ẹni tí a ń pe orúkọ mi,’ ni Olúwa wí, ta ni ó ń ṣe nǹkan wọ̀nyí,
18 obznanjuje odvijeka. (aiōn g165)
ẹni tí ó sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí di mímọ́ láti ọjọ́ pípẹ́ wá. (aiōn g165)
19 Zato smatram da ne valja dodijavati onima koji se s poganstva obraćaju k Bogu,
“Ǹjẹ́ ìmọ̀ràn tèmi ni pé, kí a máa ṣe yọ àwọn ti aláìkọlà ti ó yípadà sí Ọlọ́run lẹ́nu.
20 nego im poručiti da se uzdržavaju od mesa okaljana idolima, od bludništva, od udavljenoga i od krvi.
Ṣùgbọ́n kí a kọ̀wé si wọn, kí wọ́n fàsẹ́yìn kúrò nínú oúnjẹ tí a ṣe fún òrìṣà, àti kúrò nínú àgbèrè, àti nínú ẹ̀jẹ̀.
21 Ta Mojsije od pradavnih naraštaja ima po gradovima propovjednike koji ga u sinagogama svake subote čitaju.”
Nítorí òfin Mose nígbà àtijọ́ ṣá ní a ti ń wàásù rẹ̀, ni ìlú gbogbo, a máa ń kà á nínú Sinagọgu ni ọjọọjọ́ ìsinmi.”
22 Tad apostoli i starješine zajedno sa svom Crkvom zaključe izabrati neke muževe između sebe i poslati ih u Antiohiju s Pavlom i Barnabom. Bijahu to Juda zvani Barsaba, i Sila, muževi vodeći među braćom.
Nígbà nà án ni ó tọ́ lójú àwọn aposteli, àti àwọn alàgbà pẹ̀lú gbogbo ìjọ, láti yan ènìyàn nínú wọn, àti láti rán wọ́n lọ sí Antioku pẹ̀lú Paulu àti Barnaba: Judasi ti a ń pè àpèlé rẹ̀ ní Barsaba, àti Sila, ẹni tí ó lórúkọ nínú àwọn arákùnrin.
23 Po njima pošalju ovo pismo: “Apostoli i starješine, braća, braći iz poganstva po Antiohiji, Siriji i Ciliciji - pozdrav!”
Wọn sì kọ ìwé lé wọn lọ́wọ́ báyìí pé, Àwọn aposteli, àti àwọn alàgbà, tí ó jẹ́ ti aláìkọlà tí ó wà ní Antioku, àti ní Siria, àti ní Kilikia.
24 “Budući da smo čuli kako vas neki od naših, ali bez našega naloga, nekakvim izjavama smetoše i duše vam uznemiriše,
Níwọ́n bí àwa ti gbọ́ pé, àwọn kan ti ó ti ọ̀dọ̀ wa jáde wá ń fi ọ̀rọ̀ yọ yín lẹ́nu, tí wọ́n ń yí yín ní ọkàn padà (wí pé, ẹ kò gbọdọ̀ ṣàìmá kọ ilà, àti ṣàìmá pa òfin Mose mọ́), ẹni tí àwa kò fún ní àṣẹ.
25 zaključismo jednodušno izabrati neke muževe i poslati ih k vama zajedno s našim ljubljenim Barnabom i Pavlom,
Ó yẹ lójú àwa, bí wa ti fi ìmọ̀ ṣọ̀kan láti yan ènìyàn láti rán wọn sí yín, pẹ̀lú Barnaba àti Paulu àwọn olùfẹ́ wa.
26 ljudima koji su svoje živote izložili za ime Gospodina našega Isusa Krista.
Àwọn ọkùnrin ti ó fi ọkàn wọn wéwu nítorí orúkọ Olúwa wa Jesu Kristi.
27 Šaljemo vam dakle Judu i Silu. Oni će vam i usmeno priopćiti to isto.
Nítorí náà àwa rán Judasi àti Sila àwọn tí yóò sì fi ọ̀rọ̀ ẹnu sọ ohun kan náà fún yín.
28 Zaključismo Duh Sveti i mi ne nametati vam nikakva tereta osim onoga što je potrebno:
Nítorí ó dára lójú Ẹ̀mí Mímọ́, àti lójú wa, kí a má ṣe di ẹrù le é yin lórí, bí kò ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣe pàtàkì;
29 uzdržavati se od mesa žrtvovana idolima, od krvi, od udavljenoga i od bludništva. Budete li se toga držali, dobro ćete učiniti. Živjeli!”
í ẹ̀yin fàsẹ́yìn kúrò nínú ẹran ti à pa bọ òrìṣà, àti nínú ẹ̀jẹ̀ àti nínú ohun ìlọ́lọ́rùnpa, àti nínú àgbèrè. Bí ẹ̀yin bá pa ara yín mọ́ kúrò, ẹ̀yin ó ṣe rere. Àlàáfíà.
30 Oni su se dakle oprostili i sišli u Antiohiju; sabrali su mnoštvo i predali pismo.
Ǹjẹ́ nígbà tí wọ́n sì fi wọ́n sílẹ̀ láti lọ, wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá si Antioku. Nígbà tí wọn sì pé àwọn ìjọ papọ̀, wọn fi ìwé náà fún wọn.
31 Kad ga pročitaše, svi se obradovaše zbog ohrabrenja.
Nígbà tí wọn sì kà á, wọ́n yọ̀ fún ìtùnú náà.
32 Juda i Sila, i sami proroci, mnogim riječima ohrabriše i utvrdiše braću.
Bí Judasi àti Sila tìkára wọn ti jẹ́ wòlíì pẹ̀lú, wọ́n fi ọ̀rọ̀ púpọ̀ gba àwọn arákùnrin níyànjú, wọ́n sì mú wọn lọ́kàn le.
33 Neko se vrijeme zadrže pa se onda s mirom od braće vrate onima koji ih poslaše.
Nígbà tí wọn sì pẹ́, díẹ̀, àwọn arákùnrin rán wọn padà lọ ni àlàáfíà sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ó rán wọn wá.
35 A Pavao i Barnaba ostadoše u Antiohiji naučavajući i navješćujući zajedno s mnogima drugima riječ Gospodnju.
Paulu àti Barnaba sì dúró díẹ̀ ni Antioku, wọ́n ń kọ́ni, wọ́n sì ń wàásù ọ̀rọ̀, Olúwa, àti àwọn púpọ̀ mìíràn pẹ̀lú wọn.
36 Nakon nekog vremena reče Pavao Barnabi: “Vratimo se i pohodimo braću po svim gradovima u kojima smo navješćivali riječ Gospodnju, da vidimo kako su!”
Lẹ́yìn ọjọ́ mélòó kan, Paulu sì sọ fún Barnaba pé, “Jẹ́ kí a tún padà lọ bẹ àwọn arákùnrin wa wò, bí wọn ti ń ṣe sí ni ìlú gbogbo tí àwa ti wàásù ọ̀rọ̀ Olúwa.”
37 Barnaba je htio povesti i Ivana zvanog Marko.
Barnaba sì pinnu rẹ̀ láti mú Johanu lọ pẹ̀lú wọn, ẹni tí àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Marku.
38 Pavao pak nije smatrao uputnim sa sobom voditi onoga koji se u Pamfiliji odvojio od njih te nije s njima pošao na djelo.
Ṣùgbọ́n Paulu rò pé, kò yẹ láti mú un lọ pẹ̀lú wọn, ẹni tí ó fi wọn sílẹ̀ ni Pamfilia, tí kò sì bá wọn lọ sí iṣẹ́ náà.
39 Spopade ih takva ogorčenost da se raziđoše: Barnaba povede Marka i otplovi na Cipar,
Ìjà náà sì pọ̀ tó bẹ́ẹ̀, tí wọn ya ara wọn sì méjì, Barnaba sì mu Marku ó tẹ ọkọ́ létí lọ sí Saipurọsi.
40 a Pavao sebi izabra Silu pa od braće povjeren milosti Gospodnjoj
Ṣùgbọ́n Paulu yan Sila, ó sì lọ, bí a ti fi lé oore-ọ̀fẹ́ Olúwa lọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin.
41 proputova Siriju i Ciliciju, utvrđujući Crkve.
Ó sì la Siria àti Kilikia lọ, ó ń mú ìjọ ní ọkàn le.

< Djela apostolska 15 >