< 2 Летописи 34 >
1 Иосия бе осем години на възраст когато се възцари, и царува в Ерусалим тридесет и една година.
Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
2 Той върши това, което бе право пред Господа, като ходи в пътищата на баща си Давида, без да се отклони на дясно или на ляво.
Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
3 В осмата година на царуването си, като бе още млад, почна да търси Бога на баща си Давида; а в дванадесетата година почна да чисти Юда и Ерусалим от високите места, от ашерите, от ваяните идоли, от леяните.
Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
4 В неговото присъствие събориха жертвениците на ваалимите; и изсече кумирите на слънцето, които бяха върху тях и сломи ашерите и ваяните и леянити идоли, и като ги стри на прах, разпръсна го върху гробовете на ония, които бяха им жертвували.
Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
5 Изгори и костите на жреците на жертвениците им, и така очисти Юда и Ерусалим.
Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
6 Същото направи и в градовете на Манасия, Ефрема и Симеона, и дори до Нефталима, всред околните им развалини;
Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
7 събори жертвениците, стри на прах ашерите и ваяните идоли, и изсече всичките кумири на слънцето по цялата Израилева земя. Тогава се върна в Ерусалим.
Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
8 А в осемнадесетата година на царуването си, когато беше очистил земята и Божия дом, прати Сафана, Азалиевия син, и градския началник Маасия, и летописеца Иоах, син на Иоахаза, за да поправят дома на Господа неговия Бог.
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
9 И те отидоха при първосвещеник Хелкия, та предадоха парите внесени в Божия дом, които вратарите левити бяха събрали от Манасия и Ефрема, и от всички останали от Израил, и от целия Юда и Вениамина, и от жителите на Ерусалим.
Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
10 Предадоха ги в ръката на работниците, които надзираваха Господния дом; а те ги дадоха на работниците, които работеха в Господния дом, за да поправят и обновят дома,
Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
11 дадоха ги на дърводелците и на зидарите, за да купят дялани камъни и дървета за греди, и да поправят зданията, които Юдовите царе бяха съборили.
Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
12 И мъжете вършеха работата честно; а надзирателите над тях бяха левитите Яат и Авдия от Мерариевите потомци, Захария и Месулам от Каатовите потомци, за да настояват, а от другите левити всички изкусни свирачи на музикални инструменти.
Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
13 Имаше още настойници над бременосците и над всички, които работеха в каква да било работа; а някои от левитите бяха писари, надзиратели и вратари.
Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
14 А като изнасяха внесените в Господния дом пари, свещеник Хелкия намери книгата на Господния закон даден чрез Моисея.
Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
15 И Хелкия проговаряйки рече на секретаря Сафан: Намериха книгата на закона в Господния дом. И Хелкия даде книгата на Сафана.
Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
16 А Сафан донесе книгата на царя, занесе и дума на царя, казвайки: Слугите ти вършат всичко, що им е определено;
Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
17 и събраха намерените в Господния дом пари, и ги предадоха в ръката на настоятелите и в ръката на работниците.
Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
18 Тоже секретарят Сафан извести на царя, казвайки: Свещеник Хелкия ми даде една книга. И Сафан я прочете пред царя.
Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
19 А царят, като чу думите на закона, раздра дрехите си.
Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
20 И царят заповяда на Хелкия, на Ахикама Сафановия син, на Авдона, Михеевия син, на секретаря Сафан и на царевия слуга Асаия, казвайки:
Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
21 Идете, допитайте се до Господа за мене и за останалите в Израиля и в Юда, относно думите на намерената книга; защото голям е Господният гняв, който се изля на нас, понеже бащите ни не опазиха Господното слово да постъпват напълно според както е писано в тая книга.
“Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
22 И така, Хелкия и ония, които царят беше определил, отидоха при пророчицата Олда, жена на одеждопазителя Селум, син на Текуя, Арасовия син. А тя живееше в Ерусалим, във втория участък; и те й говориха според поръчаното.
Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
23 И тя им рече: Така казва Господ Израилевият Бог: Кажете на човека, който ви е пратил до мене:
Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
24 Така казва Господ: Ето, Аз ще докарам зло на това място и на жителите му, всичките проклетии написани в книгата, която прочетоха пред Юдовия цар.
‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
25 Понеже Ме оставиха и кадяха на други богове, та Ме разгневиха с всичките си дела на ръцете си, затова гневът Ми ще се излее на това място, и няма да угасне.
Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
26 Но на Юдовия цар, който ви прати да се допитате до Господа, така да му кажете: Така казва Господ Израилевият Бог: Относно думите, които ти си чул,
Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
27 понеже сърцето ти е омекнало, и ти си се смирил пред Бога, когато си чул Неговите думи против това място и против жителите му, и ти си се смирил пред Мене, раздрал си дрехите си, и си плакал пред Мене, затова и Аз те послушах, казва Господ.
Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
28 Ето, Аз ще те прибера при бащите ти, и ще се прибереш в гроба си с мир; и твоите очи няма да видят нищо от цялото зло, което ще докарам на това място и на жителите му. И те доложиха на царя.
Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
29 Тогава царят прати та събра всичките Юдови и ерусалимски старейшини.
Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
30 И царят възлезе в Господния дом, заедно с всичките Юдови мъже и ерусалимските жители, - свещениците, левитите и всичките люде от голям до малък; и прочете на всеослушание пред тях всичките думи от книгата на завета, която се намери в Господния дим.
Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
31 И царят застана на мястото си, та направи завет пред Господа да следва Господа, да пази заповедите Му, заявленията Му и повеленията Му с цялото си сърце и с цялата си душа, та да изпълнява думите на завета, които са написани в тая книга.
Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
32 И накара всички, които се намериха в Ерусалим и във Вениамин, да потвърдят завета. И ерусалимските жители постъпиха според завета на Бога, Бога на бащите си.
Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
33 И Иосия отмахна всичките мерзости от всичките места принадлежащи на израилтяните, и накара всички, които се намериха в Израил, да служат, да служат на Господа своя Бог; през всичките му дни те не се отклониха от следване Господа Бога на бащите си.
Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.