< Romans 11 >

1 Ǹjẹ́ mo ní, Ọlọ́run ha ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù bí? Kí a má ri. Nítorí Israẹli ni èmi pẹ̀lú, láti inú irú-ọmọ Abrahamu, ni ẹ̀yà Benjamini.
NO ia hoi, ke ninau aku nei au, Ua kiola anei ke Akua i kona poe kanaka ponoi? Aole loa; no ka mea, he mamo na Iseraela au, no na hua o Aberahama, no ka ohana hoi a Beniamina.
2 Ọlọ́run kò ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù ti ó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀. Tàbí ẹ̀yin kò mọ bí ìwé mímọ́ ti wí ní ti Elijah? Bí ó ti ń bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run fún Israẹli, wí pé:
Aole no ke Akua i kiola i kona poe kanaka ana i ike mua ai. Aole anei oukou i ike i ka ka palapala hemolele i hai mai ai ia Elia, ia ia i hoopii aku ai i ke Akua i ka Iseraela, i ka i ana,
3 “Olúwa, wọ́n ti pa àwọn wòlíì rẹ, wọn sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sì kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi.”
E ka Haku, ua pepehi lakou i kau poe kaula, ua wawahi lakou i kou mau kuahu, owau wale no koe, a ke imi nei lakou e kaili i kuu ola?
4 Ṣùgbọ́n ìdáhùn wo ni Ọlọ́run fi fún un? “Mo ti ṣẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn kù sílẹ̀ fún ara mi, àwọn tí kò tẹ eékún ba fún Baali.”
A pehea mai ka ke Akua olelo ia ia? Ua hoana e au no'u i ehiku tausani kanaka aole i kukuli iho ia Baala.
5 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni, ní àkókò yìí àṣẹ́kù àwọn ènìyàn kan wà nípa ìyànfẹ́ ti oore-ọ̀fẹ́.
Pela hoi i keia manawa, ua koe mai kekahi poe ma ka wae ana o ka lokomaikai.
6 Bí ó bá sì ṣe pé nípa ti oore-ọ̀fẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti iṣẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́ oore-ọ̀fẹ́ kì yóò jẹ́ oore-ọ̀fẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe pé nípa ti iṣẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti oore-ọ̀fẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, iṣẹ́ kì í ṣe iṣẹ́ mọ́.
A ina ma ka lokomaikai, alaila aole ma na hana. A i ole pela, alaila o ka lokomaikai, aole ia he lokomaikai. Aka ina ma na hana, aole ma ka lokomaikai, a i ole pela, alaila, o ka hana aole ia he hana.
7 Kí ha ni? Ohun tí Israẹli ń wá kiri, òun náà ni kò rí; ṣùgbọ́n àwọn ẹni àyànfẹ́ ti rí i, a sì sé àyà àwọn ìyókù le.
Heaha hoi ilaila? Aole i loaa i ka Iseraela ka mea ana i imi aku ai; aka, ua loaa ae la i ka poe i waeia, a na hoomakapoia ka poe i koe;
8 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ọlọ́run ti fún wọn ní ẹ̀mí oorun, àwọn ojú tí kò le ríran àti àwọn etí tí kò le gbọ́rọ̀, títí ó fi di òní olónìí yìí.”
(E like me ka mea i palapalaia, Ua haawi mai ke Akua ia lakou i naau hiamoe, a me na maka ike ole, a me na pepeiao lohe ole, ) a hiki i keia la.
9 Dafidi sì wí pé: “Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìdẹ̀kùn àti tàkúté, ohun ìkọ̀sẹ̀ àti ẹ̀san fún wọn.
Olelo mai la hoi o Davida, E lilo ko lakou papaaina i pahele e hei ai lakou, i mea e hina ai hoi, a i uku hoi no lakou.
10 Jẹ́ kí ojú wọn ṣókùnkùn, kí wọn kí ó má le ríran, Kí wọn kí ó sì tẹ ẹ̀yìn wọn ba nígbà gbogbo.”
E hoopouliia ko lakou mau maka, i ole ai lakou e ike, a e hookulou mau ia ko lakou kua.
11 Ǹjẹ́ mo ní, wọ́n ha kọsẹ̀ kí wọn kí ó lè ṣubú? Kí a má ri i, ṣùgbọ́n nípa ìṣubú wọn, ìgbàlà dé ọ̀dọ̀ àwọn Kèfèrí, láti mú Israẹli jowú.
Ke ninau aku nei hoi an, Ua okupe anei lakou i hina loa ai? Aole loa: aka, o ko lakou hina ana, he mea ia e ola ai ko na aina e, i mea e hooikaika hou ai ia lakou.
12 Ṣùgbọ́n bí ìṣubú wọn bá di ọrọ̀ ayé, àti bí ìfàsẹ́yìn wọn bá di ọrọ̀ àwọn Kèfèrí; mélòó mélòó ni kíkún ọrọ̀ wọn?
Ina hoi o ko lakou hina ana ka mea e waiwai ai ke ao nei, a o ko lakou kiolaia ka mea e waiwai ai ko na aina e, aole anei e nui aku ia ma ko lakou pomaikai hou ana?
13 Ẹ̀yin tí i ṣe Kèfèrí ni èmi sá à ń bá sọ̀rọ̀, níwọ̀n bí èmi ti jẹ́ aposteli àwọn Kèfèrí, mo gbé oyè mi ga
(No ka mea, ke olelo nei au ia oukou, e ko na aina e, no ka mea, he lunaolelo wau no na kanaka e, a ke hoomaikai nei au i kuu oihana;
14 bí ó le ṣe kí èmi kí ó lè mú àwọn ará mi jowú, àti kí èmi kí ó lè gba díẹ̀ là nínú wọn.
I hooikaika ae au i ko'u poe hoahanau ma ke kino, a e hoola au i kekahi poe o lakou.)
15 Nítorí bí títanù wọn bá jẹ́ ìlàjà ayé, gbígbà wọn yóò ha ti rí, bí kò sí ìyè kúrò nínú òkú?
No ka mea, ina o ka hemo ana o lakou ka mea e hoomaluhia ai ke ao nei, heaha hoi ka loaa hou ana mai o lakou, aole anei ia o ke ola mai ka make mai?
16 Ǹjẹ́ bí àkọ́so bá jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ ni àkópọ̀ yóò jẹ́ mímọ́; bí gbòǹgbò bá sì jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ẹ̀ka rẹ̀ náà.
A ina i laa ka hua mua, pela aku hoi ka popo palaoa; a ina i laa ke kumu, pela aku hoi na lala.
17 Ṣùgbọ́n bí a bá ya nínú àwọn ẹ̀ka kúrò, tí a sì lọ́ ìwọ, tí í ṣe igi òróró igbó sára wọn, tí ìwọ sì ń bá wọn pín nínú gbòǹgbò àti ọ̀rá igi olifi náà,
A ina i haihaiia kekahi mau lala, a o oe he oliva ulu wale, i pakuiia, ma ko lakou wahi, e loaa pu ana ia oe ko ke kumu, a me ka momona o ka oliva;
18 má ṣe ṣe féfé sí àwọn ẹ̀ka igi náà. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ṣe féfé, ìwọ kọ́ ni ó rù gbòǹgbò, ṣùgbọ́n gbòǹgbò ni ó rù ìwọ.
Mai hookiekie ae oe maluna o na lala: aka, ina hookiekie ae oe, aole e kau ke kumu maluna ou, aka, o oe maluna o ke kumu.
19 Ǹjẹ́ ìwọ ó wí pé, “A ti fa àwọn ẹ̀ka náà ya, nítorí kí a lè lọ́ mi sínú rẹ̀.”
Alaila e olelo no oe, Ua haihaiia na lala i pakuiia'ku ai au.
20 Ó dára; nítorí àìgbàgbọ́ ni a ṣe fà wọn ya kúrò, ìwọ sì dúró nípa ìgbàgbọ́ rẹ. Má ṣe gbé ara rẹ ga, ṣùgbọ́n bẹ̀rù.
Oia, ua haihaiia na lala no ka manaoio ole, a ma ka manaoio e ku nei oe. Mai hoonaaukiekie oe, e hopohopo nae:
21 Nítorí bí Ọlọ́run kò bá dá ẹ̀ka-ìyẹ́ka sí, kíyèsára kí ó má ṣe ṣe àìdá ìwọ náà sí.
No ka mea, ina i hookoe ole ke Akua i na lala maoli, e ao o hookoe ole oia ia oe.
22 Nítorí náà wo oore àti ìkáàánú Ọlọ́run; lórí àwọn tí ó ṣubú, ìkáàánú; ṣùgbọ́n lórí ìwọ, oore, bi ìwọ bá dúró nínú oore rẹ̀; kí a má bá ké ìwọ náà kúrò.
No ia mea, e nana oe i ka lokomaikai a me ka oolea o ke Akua: he oolea i ka poe i haule; aka, he lokomaikai no ia oe ke noho mau oe ma ka pono; a i ole, e okiia auanei oe.
23 Àti àwọn pẹ̀lú, bí wọn kò bá jókòó sínú àìgbàgbọ́, a ó lọ́ wọn sínú rẹ̀, nítorí Ọlọ́run le tún wọn lọ́ sínú rẹ̀.
A o lakou nei hoi, i ole lakou e noho mau ma ka manaoio ole, e pnkui hou ia auanei lakou; no ka mea e hiki no i ke Akua ke pakui hou ia lakou.
24 Nítorí bí a bá ti ké ìwọ kúrò lára igi òróró igbó nípa ẹ̀dá rẹ̀, tí a sì lọ́ ìwọ sínú igi òróró rere lòdì sí ti ẹ̀dá; mélòó mélòó ni a ó lọ́ àwọn wọ̀nyí, tí í ṣe ẹ̀ka-ìyẹ́ka sára igi òróró wọn?
No ka mea, ina i okiia oe no luna mai o ka oliva ulu wale ma ke ano maoli, a ua pakuiia ma ka oliva maikai me ke ano e, aole anei e pakui io ia na lala maoli i ko lakou oliva ponoi?
25 Ará, èmi kò ṣá fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó wà ní òpè ní ti ohun ìjìnlẹ̀ yìí, kí ẹ̀yin má ba á ṣe ọlọ́gbọ́n ní ojú ara yín, pé ìfọ́jú bá Israẹli ní apá kan, títí kíkún àwọn Kèfèrí yóò fi dé.
No ka mea, aole au makemake e ike ole oukou, e na hoahanau, i keia pohihihi, o akamai oukou i ko oukou manao; ua loaa ka moowini i kekahi poe o ka Iseraela a hiki i ka manawa e komo mai ai ka nui o ko na aina e.
26 Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gba gbogbo Israẹli là, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ní Sioni ni Olùgbàlà yóò ti jáde wá, yóò sì yìí àìwà-bí-Ọlọ́run kúrò lọ́dọ̀ Jakọbu.
Alaila e hoolaia ka Iseraela a pau; e like me ka mea i palapalaia, Noloko mai o Ziona e puka mai ai ka hoola, a e pale aku ia i ka aia ana, mai o Iakoba aku:
27 Èyí sì ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn. Nígbà tí èmi yóò mú ẹ̀ṣẹ̀ wọn kúrò.”
A o keia ka'u berita me lakou i ka manawa e kala aku ai au i na hewa o lakou.
28 Nípa ti ìyìnrere, ọ̀tá ni wọ́n nítorí yín; bí ó sì ṣe ti ìyànfẹ́ ni, olùfẹ́ ni wọ́n nítorí ti àwọn baba.
No oukou hoi i lilo ai lakou i poe enemi, ma ka euanelio; aka, no na kupuna, he poe aloha, ma ka wae ana.
29 Nítorí àìlábámọ̀ ni ẹ̀bùn àti ìpè Ọlọ́run.
No ka mea, o na haawina a me ke koho ana a ke Akua, me ka luli ole no ia.
30 Nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin kò ti gba Ọlọ́run gbọ́ rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí tí ẹ̀yin rí àánú gbà nípa àìgbàgbọ́ wọn.
Me oukou i hoolohe ole ai i ke Akua mamua, a i keia manawa ua loaa ia oukou ke alohaia mai, ma ko lakou hoolohe ole;
31 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn wọ̀nyí tí ó ṣe àìgbọ́ràn nísinsin yìí, kí àwọn pẹ̀lú bá le rí àánú gbà nípa àánú tí a fihàn yín.
Pela hoi lakou i hoolohe ole ai i keia manawa, i loaa ia lakou ke alohaia ma ko oukou alohaia.
32 Nítorí Ọlọ́run sé gbogbo wọn mọ́ pọ̀ sínú àìgbàgbọ́, kí ó le ṣàánú fún gbogbo wọn. (eleēsē g1653)
No ka mea, ua kuu iho ke Akua ia lakou a pau i ka manaoio ole, i aloha mai ai oia ia lakou. (eleēsē g1653)
33 A! Ìjìnlẹ̀ ọ̀rọ̀ àti ọgbọ́n àti ìmọ̀ Ọlọ́run! Àwámárídìí ìdájọ́ rẹ̀ ti rí, ọ̀nà rẹ̀ sì jù àwárí lọ!
Nani ka hohonu o ka waiwai a me ke akamai, a me ka ike o ke Akua! nani hoi ke kupanaha o kona mau manao, a me ka ike ole ia ku o kona mau aoao!
34 “Nítorí ta ni ó mọ ọkàn Olúwa? Tàbí ta ni í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀?”
No ka mea, owai la ka mea i ike i ka naau o ka Haku? Owai aku la hoi kona hoakukakuka?
35 “Tàbí ta ni ó kọ́ fi fún un, tí a kò sì san padà fún un?”
Owai la hoi ka mea i haawi e aku ia ia e uku hou ia mai ai ia?
36 Nítorí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti nípa rẹ̀, àti fún un ni ohun gbogbo; ẹni tí ògo wà fún láéláé! Àmín. (aiōn g165)
No ka mea, nana mai, a ma o na la, a nona no hoi na mea a pau; ia ia ka hoonani mau loa ia'ku. Amene. (aiōn g165)

< Romans 11 >