< Romans 11 >
1 Ǹjẹ́ mo ní, Ọlọ́run ha ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù bí? Kí a má ri. Nítorí Israẹli ni èmi pẹ̀lú, láti inú irú-ọmọ Abrahamu, ni ẹ̀yà Benjamini.
NO ia hoi, ke ninau aku nei au, Ua kiola anei ke Akua i kona poe kanaka ponoi? Aole loa; no ka mea, he mamo na Iseraela au, no na hua o Aberahama, no ka ohana hoi a Beniamina.
2 Ọlọ́run kò ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù ti ó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀. Tàbí ẹ̀yin kò mọ bí ìwé mímọ́ ti wí ní ti Elijah? Bí ó ti ń bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run fún Israẹli, wí pé:
Aole no ke Akua i kiola i kona poe kanaka ana i ike mua ai. Aole anei oukou i ike i ka ka palapala hemolele i hai mai ai ia Elia, ia ia i hoopii aku ai i ke Akua i ka Iseraela, i ka i ana,
3 “Olúwa, wọ́n ti pa àwọn wòlíì rẹ, wọn sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sì kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi.”
E ka Haku, ua pepehi lakou i kau poe kaula, ua wawahi lakou i kou mau kuahu, owau wale no koe, a ke imi nei lakou e kaili i kuu ola?
4 Ṣùgbọ́n ìdáhùn wo ni Ọlọ́run fi fún un? “Mo ti ṣẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn kù sílẹ̀ fún ara mi, àwọn tí kò tẹ eékún ba fún Baali.”
A pehea mai ka ke Akua olelo ia ia? Ua hoana e au no'u i ehiku tausani kanaka aole i kukuli iho ia Baala.
5 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni, ní àkókò yìí àṣẹ́kù àwọn ènìyàn kan wà nípa ìyànfẹ́ ti oore-ọ̀fẹ́.
Pela hoi i keia manawa, ua koe mai kekahi poe ma ka wae ana o ka lokomaikai.
6 Bí ó bá sì ṣe pé nípa ti oore-ọ̀fẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti iṣẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́ oore-ọ̀fẹ́ kì yóò jẹ́ oore-ọ̀fẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe pé nípa ti iṣẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti oore-ọ̀fẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, iṣẹ́ kì í ṣe iṣẹ́ mọ́.
A ina ma ka lokomaikai, alaila aole ma na hana. A i ole pela, alaila o ka lokomaikai, aole ia he lokomaikai. Aka ina ma na hana, aole ma ka lokomaikai, a i ole pela, alaila, o ka hana aole ia he hana.
7 Kí ha ni? Ohun tí Israẹli ń wá kiri, òun náà ni kò rí; ṣùgbọ́n àwọn ẹni àyànfẹ́ ti rí i, a sì sé àyà àwọn ìyókù le.
Heaha hoi ilaila? Aole i loaa i ka Iseraela ka mea ana i imi aku ai; aka, ua loaa ae la i ka poe i waeia, a na hoomakapoia ka poe i koe;
8 Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ọlọ́run ti fún wọn ní ẹ̀mí oorun, àwọn ojú tí kò le ríran àti àwọn etí tí kò le gbọ́rọ̀, títí ó fi di òní olónìí yìí.”
(E like me ka mea i palapalaia, Ua haawi mai ke Akua ia lakou i naau hiamoe, a me na maka ike ole, a me na pepeiao lohe ole, ) a hiki i keia la.
9 Dafidi sì wí pé: “Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìdẹ̀kùn àti tàkúté, ohun ìkọ̀sẹ̀ àti ẹ̀san fún wọn.
Olelo mai la hoi o Davida, E lilo ko lakou papaaina i pahele e hei ai lakou, i mea e hina ai hoi, a i uku hoi no lakou.
10 Jẹ́ kí ojú wọn ṣókùnkùn, kí wọn kí ó má le ríran, Kí wọn kí ó sì tẹ ẹ̀yìn wọn ba nígbà gbogbo.”
E hoopouliia ko lakou mau maka, i ole ai lakou e ike, a e hookulou mau ia ko lakou kua.
11 Ǹjẹ́ mo ní, wọ́n ha kọsẹ̀ kí wọn kí ó lè ṣubú? Kí a má ri i, ṣùgbọ́n nípa ìṣubú wọn, ìgbàlà dé ọ̀dọ̀ àwọn Kèfèrí, láti mú Israẹli jowú.
Ke ninau aku nei hoi an, Ua okupe anei lakou i hina loa ai? Aole loa: aka, o ko lakou hina ana, he mea ia e ola ai ko na aina e, i mea e hooikaika hou ai ia lakou.
12 Ṣùgbọ́n bí ìṣubú wọn bá di ọrọ̀ ayé, àti bí ìfàsẹ́yìn wọn bá di ọrọ̀ àwọn Kèfèrí; mélòó mélòó ni kíkún ọrọ̀ wọn?
Ina hoi o ko lakou hina ana ka mea e waiwai ai ke ao nei, a o ko lakou kiolaia ka mea e waiwai ai ko na aina e, aole anei e nui aku ia ma ko lakou pomaikai hou ana?
13 Ẹ̀yin tí i ṣe Kèfèrí ni èmi sá à ń bá sọ̀rọ̀, níwọ̀n bí èmi ti jẹ́ aposteli àwọn Kèfèrí, mo gbé oyè mi ga
(No ka mea, ke olelo nei au ia oukou, e ko na aina e, no ka mea, he lunaolelo wau no na kanaka e, a ke hoomaikai nei au i kuu oihana;
14 bí ó le ṣe kí èmi kí ó lè mú àwọn ará mi jowú, àti kí èmi kí ó lè gba díẹ̀ là nínú wọn.
I hooikaika ae au i ko'u poe hoahanau ma ke kino, a e hoola au i kekahi poe o lakou.)
15 Nítorí bí títanù wọn bá jẹ́ ìlàjà ayé, gbígbà wọn yóò ha ti rí, bí kò sí ìyè kúrò nínú òkú?
No ka mea, ina o ka hemo ana o lakou ka mea e hoomaluhia ai ke ao nei, heaha hoi ka loaa hou ana mai o lakou, aole anei ia o ke ola mai ka make mai?
16 Ǹjẹ́ bí àkọ́so bá jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ ni àkópọ̀ yóò jẹ́ mímọ́; bí gbòǹgbò bá sì jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ẹ̀ka rẹ̀ náà.
A ina i laa ka hua mua, pela aku hoi ka popo palaoa; a ina i laa ke kumu, pela aku hoi na lala.
17 Ṣùgbọ́n bí a bá ya nínú àwọn ẹ̀ka kúrò, tí a sì lọ́ ìwọ, tí í ṣe igi òróró igbó sára wọn, tí ìwọ sì ń bá wọn pín nínú gbòǹgbò àti ọ̀rá igi olifi náà,
A ina i haihaiia kekahi mau lala, a o oe he oliva ulu wale, i pakuiia, ma ko lakou wahi, e loaa pu ana ia oe ko ke kumu, a me ka momona o ka oliva;
18 má ṣe ṣe féfé sí àwọn ẹ̀ka igi náà. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ṣe féfé, ìwọ kọ́ ni ó rù gbòǹgbò, ṣùgbọ́n gbòǹgbò ni ó rù ìwọ.
Mai hookiekie ae oe maluna o na lala: aka, ina hookiekie ae oe, aole e kau ke kumu maluna ou, aka, o oe maluna o ke kumu.
19 Ǹjẹ́ ìwọ ó wí pé, “A ti fa àwọn ẹ̀ka náà ya, nítorí kí a lè lọ́ mi sínú rẹ̀.”
Alaila e olelo no oe, Ua haihaiia na lala i pakuiia'ku ai au.
20 Ó dára; nítorí àìgbàgbọ́ ni a ṣe fà wọn ya kúrò, ìwọ sì dúró nípa ìgbàgbọ́ rẹ. Má ṣe gbé ara rẹ ga, ṣùgbọ́n bẹ̀rù.
Oia, ua haihaiia na lala no ka manaoio ole, a ma ka manaoio e ku nei oe. Mai hoonaaukiekie oe, e hopohopo nae:
21 Nítorí bí Ọlọ́run kò bá dá ẹ̀ka-ìyẹ́ka sí, kíyèsára kí ó má ṣe ṣe àìdá ìwọ náà sí.
No ka mea, ina i hookoe ole ke Akua i na lala maoli, e ao o hookoe ole oia ia oe.
22 Nítorí náà wo oore àti ìkáàánú Ọlọ́run; lórí àwọn tí ó ṣubú, ìkáàánú; ṣùgbọ́n lórí ìwọ, oore, bi ìwọ bá dúró nínú oore rẹ̀; kí a má bá ké ìwọ náà kúrò.
No ia mea, e nana oe i ka lokomaikai a me ka oolea o ke Akua: he oolea i ka poe i haule; aka, he lokomaikai no ia oe ke noho mau oe ma ka pono; a i ole, e okiia auanei oe.
23 Àti àwọn pẹ̀lú, bí wọn kò bá jókòó sínú àìgbàgbọ́, a ó lọ́ wọn sínú rẹ̀, nítorí Ọlọ́run le tún wọn lọ́ sínú rẹ̀.
A o lakou nei hoi, i ole lakou e noho mau ma ka manaoio ole, e pnkui hou ia auanei lakou; no ka mea e hiki no i ke Akua ke pakui hou ia lakou.
24 Nítorí bí a bá ti ké ìwọ kúrò lára igi òróró igbó nípa ẹ̀dá rẹ̀, tí a sì lọ́ ìwọ sínú igi òróró rere lòdì sí ti ẹ̀dá; mélòó mélòó ni a ó lọ́ àwọn wọ̀nyí, tí í ṣe ẹ̀ka-ìyẹ́ka sára igi òróró wọn?
No ka mea, ina i okiia oe no luna mai o ka oliva ulu wale ma ke ano maoli, a ua pakuiia ma ka oliva maikai me ke ano e, aole anei e pakui io ia na lala maoli i ko lakou oliva ponoi?
25 Ará, èmi kò ṣá fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó wà ní òpè ní ti ohun ìjìnlẹ̀ yìí, kí ẹ̀yin má ba á ṣe ọlọ́gbọ́n ní ojú ara yín, pé ìfọ́jú bá Israẹli ní apá kan, títí kíkún àwọn Kèfèrí yóò fi dé.
No ka mea, aole au makemake e ike ole oukou, e na hoahanau, i keia pohihihi, o akamai oukou i ko oukou manao; ua loaa ka moowini i kekahi poe o ka Iseraela a hiki i ka manawa e komo mai ai ka nui o ko na aina e.
26 Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gba gbogbo Israẹli là, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ní Sioni ni Olùgbàlà yóò ti jáde wá, yóò sì yìí àìwà-bí-Ọlọ́run kúrò lọ́dọ̀ Jakọbu.
Alaila e hoolaia ka Iseraela a pau; e like me ka mea i palapalaia, Noloko mai o Ziona e puka mai ai ka hoola, a e pale aku ia i ka aia ana, mai o Iakoba aku:
27 Èyí sì ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn. Nígbà tí èmi yóò mú ẹ̀ṣẹ̀ wọn kúrò.”
A o keia ka'u berita me lakou i ka manawa e kala aku ai au i na hewa o lakou.
28 Nípa ti ìyìnrere, ọ̀tá ni wọ́n nítorí yín; bí ó sì ṣe ti ìyànfẹ́ ni, olùfẹ́ ni wọ́n nítorí ti àwọn baba.
No oukou hoi i lilo ai lakou i poe enemi, ma ka euanelio; aka, no na kupuna, he poe aloha, ma ka wae ana.
29 Nítorí àìlábámọ̀ ni ẹ̀bùn àti ìpè Ọlọ́run.
No ka mea, o na haawina a me ke koho ana a ke Akua, me ka luli ole no ia.
30 Nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin kò ti gba Ọlọ́run gbọ́ rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí tí ẹ̀yin rí àánú gbà nípa àìgbàgbọ́ wọn.
Me oukou i hoolohe ole ai i ke Akua mamua, a i keia manawa ua loaa ia oukou ke alohaia mai, ma ko lakou hoolohe ole;
31 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn wọ̀nyí tí ó ṣe àìgbọ́ràn nísinsin yìí, kí àwọn pẹ̀lú bá le rí àánú gbà nípa àánú tí a fihàn yín.
Pela hoi lakou i hoolohe ole ai i keia manawa, i loaa ia lakou ke alohaia ma ko oukou alohaia.
32 Nítorí Ọlọ́run sé gbogbo wọn mọ́ pọ̀ sínú àìgbàgbọ́, kí ó le ṣàánú fún gbogbo wọn. (eleēsē )
No ka mea, ua kuu iho ke Akua ia lakou a pau i ka manaoio ole, i aloha mai ai oia ia lakou. (eleēsē )
33 A! Ìjìnlẹ̀ ọ̀rọ̀ àti ọgbọ́n àti ìmọ̀ Ọlọ́run! Àwámárídìí ìdájọ́ rẹ̀ ti rí, ọ̀nà rẹ̀ sì jù àwárí lọ!
Nani ka hohonu o ka waiwai a me ke akamai, a me ka ike o ke Akua! nani hoi ke kupanaha o kona mau manao, a me ka ike ole ia ku o kona mau aoao!
34 “Nítorí ta ni ó mọ ọkàn Olúwa? Tàbí ta ni í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀?”
No ka mea, owai la ka mea i ike i ka naau o ka Haku? Owai aku la hoi kona hoakukakuka?
35 “Tàbí ta ni ó kọ́ fi fún un, tí a kò sì san padà fún un?”
Owai la hoi ka mea i haawi e aku ia ia e uku hou ia mai ai ia?
36 Nítorí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti nípa rẹ̀, àti fún un ni ohun gbogbo; ẹni tí ògo wà fún láéláé! Àmín. (aiōn )
No ka mea, nana mai, a ma o na la, a nona no hoi na mea a pau; ia ia ka hoonani mau loa ia'ku. Amene. (aiōn )