< Zephaniah 3 >

1 Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
Asi pay ti managsukir a siudad! Natulawanen ti naranggas a siudad!
2 Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
Saan daytoy a dimngeg iti timek ti Dios, wenno saan nga immawat iti pannursuro manipud kenni Yahweh! Saan isuna nga agtalek kenni Yahweh ken saan nga umasideg iti Diosna.
3 Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
Dagiti prinsipena ket kasla ngumerngernger a leon iti nagtengngaanna! Dagiti ukomna ket kasla kadagiti lobo iti rabii a saan a mangitedda iti kanenda iti agsapa!
4 Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
Dagiti profetana ket nadursok ken manangliput a lallaki! Rinugitan dagiti padina ti nasantoan ken nagaramid iti panaglabsing iti linteg!
5 Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
Nalinteg ni Yahweh iti nagtengngaanna! Dinto agaramid iti biddut! Iti tunggal bigat, ipaayna ti husticia! Saanto nga mailemmeng iti lawag, ngem ti managdakdakes ket dina ammo ti agbain!
6 “Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
“Dinadaelko dagiti nasion; nadadael dagiti sarikedkedda. Dinadaelko dagiti kalsadada tapno awan a pulos iti makalabas kadagitoy. Nadadael dagiti siudadda ket awan ti tao a makapagnaed kadagitoy.
7 Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
Kinunak, ‘Sigurado nga agbutengkanto kaniak! Umawatka iti pannakaisuro ket saanka a mapapanaw kadagiti pagtaengam iti amin a pinanggepko nga aramiden kenka!' Ngem aggagarda a mangirugi iti tunggal agsapa babaen iti panangpadakesda kadagiti amin nga aramidda.
8 Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
Ngarud, urayendak”—kastoy ti pakaammo ni Yahweh— “agingga iti aldaw a tumakderak nga agsamsam! Ta ti pangngedengko ket urnongek dagiti nasion, ummongek dagiti pagarian, ken tapno idissuorko kadakuada ti ungetko, ti narungsot a pungtotko, tapno maikisap amin ti daga babaen iti apuy ti ungetko.
9 “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
Ngem urayno kasta, ikkakto iti nadalus a pagsasao dagiti tattao, tapno umawagda amin iti nagan ni Yahweh, tapno agserbida kaniak nga addaan iti panagkaykaysa.
10 Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
Manipud iti labes ti karayan ti Etiopia a mangidaydayaw kaniak—dagiti naiwara-wara a tattaok—mangyegto kadagiti daton a para kaniak.
11 Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
Iti dayta nga aldaw, saankayonto a maibabain gapu kadagiti amin nga aramidyo a maibusor kaniak, agsipud ta iti dayta a tiempo, ikkatekto kadakayo dagiti nangramrambak iti kinatangsityo, ken gapu ta saankayontno nga agtignay a sipapalangguad iti tapaw ti nasantoan a bantayko.
12 Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
Ngem ibatikayo a kas nanumo ken napanglaw a tattao, ket agkamangkayonto iti nagan ni Yahweh.
13 Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
Saanton nga aglabsing wenno agulbod dagiti nabatbati iti Israel, ken awan ti manangallilaw a dila iti masarakanto kadagiti ngiwatda; isu nga agarab ken agiddada, ken awanto iti pagbutbutnganda.”
14 Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
Agkantaka, O anak a babbai ti Sion! Agdir-ika, O Israel! Agrag-o ken agragsakka iti amin a pusom, O anak a babai ti Jerusalem!
15 Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
Inikkaten ni Yahweh ti dusam; pinapanawnan dagiti kabusormo! Ni Yahweh ti ari ti Israel nga adda kadagiti nagtengngaanyo. Saanmonto manen a kabuteng ti dakes!
16 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
Iti dayta nga aldaw, kunaendanto iti Jerusalem, “Saanka nga agbuteng, O Sion. Saanmo nga itulok a kumapuy dagiti imam.
17 Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
Ni Yahweh a Diosyo ket adda kadakayo, ti mannakabalin a mangisalakan kadakayo. Agrambakto isuna gapu kadakayo ken paginanaennakayonto iti ayatna nga addaan rag-o; Maragsakanto isuna kadakayo ket agpukkawto isuna iti rag-o.
18 “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
Dagiti nagladingit gapu iti naituding a fiesta—inummongko ida manipud kadakayo, nagbalinda a dadagsen ken nakaigapuan ti pannakaibabainyo.
19 Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
Adtoy, iti dayta a tiempo, dusaekto dagiti amin a nangparparigat kadakayo. Ispalekto dagiti pilay ken ummongekto dagiti napatalaw. Ikkatekto ti nakaibabainanda ket pagbalinekto ida a nadayaw ken natan-ok iti entero a daga.
20 Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.
Iti dayta a tiempo, idauloan ken pagmaymaysaenkayonto. Raemen ken idayawdakayonto dagiti amin a nasion iti daga, inton makitayo nga insublik ti kinarang-ayyo,” kuna ni Yahweh.

< Zephaniah 3 >