< Zephaniah 3 >

1 Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
Ô ville insigne et mise à rançon, malheur à toi! La colombe
2 Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
n'a pas entendu Ma voix ni recueilli l'avertissement; elle n'a point eu foi au Seigneur, et ne s'est point approchée de son Dieu.
3 Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
Ses princes sont, au milieu d'elle, comme des lions rugissants, et ses juges comme des loups d'Arabie; et ils n'ont pas subsisté jusqu'à l'aurore.
4 Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
Ses prophètes, hommes méprisants, sont inspirés par le mauvais esprit; ses prêtres profanent les choses saintes, et ne respectent point la loi.
5 Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
Mais le Seigneur juste est au milieu d'elles, et Il ne fera rien d'inique; demain Il produira Son jugement à la lumière: car Dieu ne Se cache point; Il ne connaît l'iniquité ni par exaction ni par violence.
6 “Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
J'ai attiré les superbes dans la ruine; leurs tours sont en poussière; Je ferai leurs rues si désertes, que nul n'y passera; leurs villes ont dépéri, parce qu'il n'y a plus personne qui vive et demeure en elles.
7 Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
J'ai dit: Craignez-Moi, recueillez Mon enseignement, et vous ne serez pas exterminés de la face de la terre, partout où Je me suis vengé d'elle; tiens- toi prêt, lève-toi et fuis dès l'aurore, car tous leurs raisins sont gâtés.
8 Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
Attends-Moi, dit le Seigneur; jusqu'au jour de Ma résurrection, où Je rendrai témoignage; car Mon jugement s'exercera dans l'assemblée des nations pour y recevoir les rois et répandre sur eux toute ma colère, parce que dans le feu de Mon zèle toute la terre périra.
9 “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
Alors Je rendrai aux peuples une langue comme à l'origine, afin que tous invoquent le Nom du Seigneur, et le servent sous un joug unique.
10 Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
Depuis les sources des fleuves de l'Éthiopie, J'accueillerai les gentils avec ceux de Mon peuple qui sont dispersés, et ils M'offriront leurs sacrifices.
11 Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
En ce jour, tu n'auras plus à rougir des œuvres où tu as prévariqué contre Moi; car alors Je t'aurai ôté de ton orgueil dédaigneux, et tu ne continueras plus de te glorifier sur la montagne de Mon sanctuaire.
12 Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
Et Je trouverai en toi un peuple rempli d'humilité et de douceur; et ils auront en vénération le Nom du Seigneur,
13 Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
ceux qui resteront encore d'Israël; et ils ne feront plus d'iniquité; et ils ne parleront plus de vanités, et, dans leur bouche, la langue ne sera plus trouvée trompeuse; et Mon troupeau pourra paître et se reposer sans être effrayé de personne.
14 Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
Réjouis-toi, Sion, Ma fille; proclame ton allégresse, Jérusalem, Ma fille; tressaille et réjouis-toi de tout ton cœur, Jérusalem, Ma fille.
15 Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
Le Seigneur t'a remis tes iniquités; Il t'a racheté des mains de tes ennemis; le roi d'Israël, qui est le Seigneur, est au milieu de toi: tu ne verras plus de malheurs.
16 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
En ce temps-là, le Seigneur dira à Jérusalem: Rassure-toi, Sion, que tes mains ne soient pas défaillantes.
17 Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
Le Seigneur ton Dieu est avec toi; le Tout-Puissant te sauvera: Il te rendra la joie; Il te rajeunira de Son amour; en toi Il sera ravi de joie, comme en un jour de fête.
18 “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
Et Je rassemblerai tes affligés; malheur à qui l'a outragée!
19 Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
Voilà que J'agirai en toi, pour l'amour de toi, en ce temps-là, dit le Seigneur; et je sauverai celle qui a été opprimée, et je recueillerai celle qui a été répudiée, et je glorifierai ses fils, et ils auront un nom par toute la terre.
20 Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.
En ce temps-là vos ennemis seront confondus lorsque J'en userai ainsi avec vous, et que Je vous aurai bien accueillis; car Je vous donnerai un nom célèbre, et vous serez glorifiés par tous les peuples de la terre, après que Je vous aurai ramené tous vos captifs, dit le Seigneur.

< Zephaniah 3 >