< Zephaniah 3 >
1 Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
Hélas! elle est salie et souillée, la ville étourdie comme une colombe!
2 Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
Elle ne veut écouter aucune voix, accepter aucune leçon; elle n’a pas confiance en l’Eternel, elle ne s’approche pas de son Dieu.
3 Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
Ses grands, dans son enceinte, sont des lions rugissants, ses juges des loups nocturnes qui n’ont rien à déchiqueter au matin.
4 Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
Ses prophètes sont des aventuriers, des gens de mauvaise foi; ses prêtres profanent les choses saintes, font violence à la loi.
5 Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
Cependant l’Eternel est juste au milieu d’elle, il ne commet pas d’iniquité; chaque matin, il fait éclater au grand jour sa droiture, sans y manquer jamais. Mais le malfaiteur ne connaît pas la honte.
6 “Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
J’Ai anéanti des nations, leurs tours fortifiées sont en ruines; j’ai dévasté leurs campagnes, qui ne voient plus de passants, leurs villes sont ravagées, abandonnées de tous, dépeuplées.
7 Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
Je disais: "Si seulement tu me craignais et acceptais une leçon!" Ainsi cette résidence échapperait à la destruction, à toutes les menaces dirigées contre elle. Mais non! Ils s’empressent de commettre toutes les mauvaises actions.
8 Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
Eh bien! Comptez sur moi, dit l’Eternel, comptez sur le jour où je me lèverai pour saccager! Aussi bien c’est l’arrêt de ma volonté de réunir les peuples, de convoquer les royaumes, afin de déverser sur eux mon courroux, tout le feu de ma colère: oui, par le feu de mon indignation toute la terre sera dévorée.
9 “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
Mais alors aussi je gratifierai les peuples d’un idiome épuré, pour que tous ils invoquent le nom de l’Eternel et l’adorent d’un cœur unanime.
10 Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
D’Au-delà des fleuves de Couch, mes adorateurs, mes fidèles dispersés m’amèneront des offrandes.
11 Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
En ce jour, tu n’auras plus à rougir des actes qui t’ont rendue fautive à mon égard, car j’éloignerai du milieu de toi tes exaltés d’orgueil, tu ne continueras plus à porter haut le front sur ma sainte montagne.
12 Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
Je ne laisserai subsister dans ton sein que des gens humbles et modestes, qui chercheront un abri dans le nom de l’Eternel.
13 Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
Les survivants d’Israël rie commettront plus d’injustice, ne diront pas de mensonge; on ne surprendra dans leur bouche aucun langage trompeur; mais ils pâtureront, ils prendront leur repos, sans personne pour les troubler.
14 Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
Entonne des chants, fille de Sion, pousse des cris de joie, ô Israël! Réjouis-toi et exulte de tout cœur, fille de Jérusalem!
15 Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
L’Eternel a rapporté les sentences qui te condamnaient, il a expulsé tes ennemis; le roi d’Israël, l’Eternel, est au milieu de toi: tu n’auras plus de malheur à redouter!
16 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
En ce jour on dira à Jérusalem: "Sois sans crainte! Sion, ne laisse pas défaillir tes bras!"
17 Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
L’Eternel, ton Dieu, est au milieu de toi, comme un héros qui prête main forte. II éprouvera une vive joie à ton sujet; dans son amour, il fera le silence sur tes fautes, se réjouira de toi avec transport.
18 “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
Ceux qui souffraient d’être éloignés des solennités, je les recueille comme faisant corps avec toi; assez longtemps l’opprobre fut leur partage.
19 Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
En ce temps j’accablerai tous tes oppresseurs, je porterai secours aux brebis qui boitent, je rassemblerai celles qui sont pourchassées, et j’établirai leur gloire et leur renommée dans tous les pays qui ont connu leur honte.
20 Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.
En ce temps, je vous ramènerai, en ce temps je vous rassemblerai, car je veux faire éclater votre renommée et votre gloire parmi toutes les nations de la terre, en ramenant vos captifs, sous vos propres yeux, dit l’Eternel.