< Zephaniah 3 >

1 Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
Ve den genstridige og besmittede, den Stad, som øver Undertrykkelse!
2 Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
Den hører ikke paa nogen Røst, dep annammer ikke Tugt; den forlader sig ikke paa Herren, den holder sig ikke nær til sin Gud.
3 Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
Dens Fyrster i dens Midte ere brølende Løver; dens Dommere ere Aftenulve, som ikke levne et Ben til om Morgenen.
4 Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
Dens Profeter ere letfærdige, troløse Mænd; dens Præster vanhellige Helligdommen, gøre Vold paa Loven.
5 Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
Herren er retfærdig i dens Midte, han gør ikke Uret; hver Morgen lader han sin Ret komme for Lyset, det fattes ikke derpaa; men den uretfærdige kender ikke til Skam.
6 “Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
Jeg udryddede Hedningerne, deres Hjørnetaarne ere ødelagte, jeg gjorde deres Gader øde, saa at ingen gaar igennem dem; deres Stæder ere forstyrrede, saa at der er ingen Mand der, og ingen bor der.
7 Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
Jeg sagde: Du skal kun frygte mig, annamme Tugt, saa skal dens Bolig ikke udryddes, alt eftersom jeg havde bestemt over den; men de have aarle gjort sig rede til at gøre alle deres Gerninger fordærvelige.
8 Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
Derfor, bier efter mig, siger Herren, efter den Dag, da jeg rejser mig til Rov! thi min Ret er den, at jeg vil sanke Hedningerne, at jeg vil samle Rigerne, for over dem at udøse min Fortørnelse, al min brændende Vrede; thi ved min Nidkærheds Ild skal den hele Jord fortæres.
9 “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
Thi da vil jeg omskifte Læberne til rene for Folkene, at de alle skulle paakalde Herrens Navn og tjene ham endrægtelig.
10 Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
Fra hin Side af Morlands Floder skulle de bringe mine Tilbedere, mit adspredte Folk, som en Gave til mig.
11 Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
Paa den Dag skal du ikke skamme dig ved nogen af dine Gerninger, med hvilke du forsyndede dig imod mig; thi da vil jeg borttage af din Midte dine stolte Pralere, og du skal ikke blive ved at ophøje dig ydermere paa mit hellige Bjerg.
12 Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
Men jeg vil lade et nedtrykt og ringe Folk blive tilovers i din Midte, og de skulle forlade sig paa Herrens Navn.
13 Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
De overblevne af Israel skulle ikke gøre Uret og ikke tale Løgn, Og der skal ikke findes en svigefuld Tunge i deres Mund; thi de skulle finde Føde og Hvile, og ingen skal forfærde dem.
14 Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
Syng, du Zions Datter! raab højt, o Israel! vær glad og fryd dig af dit ganske Hjerte, du Jerusalems Datter!
15 Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
Herren har borttaget Dommene over dig, har udryddet din Fjende; Herren, Israels Konge, er i din Midte, du skal ikke se Ulykke ydermere.
16 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
Paa den Dag skal siges til Jerusalem: Frygt ikke! til Zion: Lad ikke dine Hænder synke!
17 Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
Herren din Gud i din Midte, din vældige, skal frelse; han skal glæde sig over dig med Fryd, han skal tie i sin Kærlighed, han skal juble over dig med Frydesang.
18 “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
Dem, som vare bedrøvede, fordi de ikke kunde komme til Højtiden, dem vil jeg samle; fra dig vare de; Forhaanelse har hvilet som en Byrde over dem.
19 Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
Se, paa den Tid vil jeg skride ind imod alle, som plage dig; og jeg vil frelse den haltende og samle de fordrevne og sætte dem til Pris og til Navnkundighed i hele det Land, hvori de lede Skændsel.
20 Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.
Paa den Tid vil jeg lade eder komme, og det paa den Tid naar jeg sanker eder; thi jeg vil sætte eder til Navnkundighed og til Pris iblandt alle Folk paa Jorden, naar jeg omvender eders Fangenskab for eders Øjne, siger Herren.

< Zephaniah 3 >