< Zephaniah 3 >

1 Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
Mi pacaekthlaek, panuet thok moe, kamhnong vangpui loe khosak bing!
2 Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
Jerusalem loe lok tahngai ai, amkhraih han thuih ih lok doeh talawk ai; anih loe Angraeng oephaih tawn ai, angmah ih Sithaw khaeah doeh anghnai ai.
3 Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
Vangpui thungah kaom angmah ih ukkung angraengnawk loe kaipui baktiah hangh o, anih ih lokcaek kaminawk loe akhawnbang caak hanah ahuh kasuem ai, duembang ih tasuinawk baktiah oh o.
4 Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
Anih ih tahmaanawk loe poek kasang, aling kop kami ah oh o; anih ih qaimanawk loe ahmuen ciim to panuet thok ah sak o moe, Sithaw mah patuk ih lok to amro o sak.
5 Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
Toenghaih Angraeng loe anih salakah oh, anih loe katoeng ai hmuen tidoeh sah ai: akhawnbang kruek a toenghaih to amtuengsak; anih loe natuek naah doeh thazok ai; toe katoeng ai kami loe azathaih roe panoek ai.
6 “Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
Prae kaminawk to kam rosak boih boeh; nihcae ih misa buephaih tapangnawk doeh ka paro pae boeh; nihcae ih lampuinawk doeh ka paro pae moe, kaminawk caeh o ai boeh; vangpuinawk to ka phraek pae boeh pongah, kami om ai, anghmat kami mi doeh om ai.
7 Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
Kai mah, Vangpui khaeah kai hae zii ah loe, thuitaekhaih lok to talawk ah, tiah ka naa. Anih to ka thuitaek, toe a thungah kaom kaminawk loe kam rosak mak ai; toe nihcae loe khawnthaw ah angthawk o moe, a sak o ih hmuen baktih toengah, zaehaih a sak o let.
8 Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
To pongah amrosak hanah kang thawkhaih ni khoek to, na zing oh, tiah Angraeng mah thuih. Kanung parai palungphuihaih nihcae nuiah ka kraih hanah, prae kaminawk boih, siangpahrang mah uk ih praenawk boih nawnto ka pakhueng han, tiah lok takroekhaih ka sak boeh, tiah thuih: to naah pauep thai ai palung ka phuihaih hmai mah long to kang boih tih.
9 “Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
To pacoengah kaminawk khaeah kaciim lok to ka suek han, poekhaih maeto hoiah anih ih tok nawnto sak o hanah, nihcae boih mah Angraeng ih ahmin to kawk o tih.
10 Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
Ethiopia ih tuipui yaeh hoiah kai bok kaminawk, ampraek phang ka canunawk mah, kai khaeah hmuen tathlanghaih to sin o tih.
11 Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
To na niah loe ka koeh ai ih hmuen na sakpazae o ih hmuennawk boih pongah azathaih na tongh o mak ai boeh, nangcae amoekhaih pongah anghoe kaminawk to nangcae salak hoiah ka lak ving han, to naah loe kaciim kai ih mae ah nam oek o mak ai boeh.
12 Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
Pacaekthlaek ih kami, amtang kaminawk to ka hum mak ai, nangcae salakah ka caeh taak han, to naah nihcae mah Angraeng ih ahmin to tang o tih.
13 Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
Kanghmat Israel kaminawk loe zaehaih sah o mak ai, lok amlai o mak ai; nihcae pakha ah lok amlaihaih hnu o mak ai: nihcae to caa o ueloe, mi doeh zithaih om ai ah khosah o tih boeh.
14 Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
Aw Zion canu, laa to sah ah; Aw Israel, tha hoi hang ah; Aw Jerusalem canu, na palungthin boih hoi oep ah loe, palung anghoesak ah.
15 Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
Na lokcaekhaih loe Angraeng mah boengsak boeh, anih mah na misa to haek boih boeh; Angraeng, Israel siangpahrang loe nangcae salakah oh: nangcae mah sethaih na hnu o mak ai boeh.
16 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
To na niah Jerusalem khaeah, Zii hmah, Zion khaeah, Na ban to thahnaem hmah nasoe.
17 Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
Nangcae salakah kaom, Angraeng na Sithaw loe thacak; anih mah pahlong tih, anih loe oephaih hoi na nuiah anghoe tih; angmah ih amlunghaih hoiah nang to kamong ah omsak tih; laasakhaih hoiah na nuiah paroeai anghoe tih, tiah thuihaih to om tih.
18 “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
Palungset hoi na ohhaih, nangcae han hmuenzit ah kaom pahnui thuih ih hmuennawk to ka boengsak han boeh.
19 Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
Khenah, to nathuem ah nangcae pacaekthlaek kaminawk to ka thuitaek boih han; khokkhaem kaminawk to ka pahlong moe, pakak ih kaminawk to nawnto kam khuengsak han; azathaih prae ah kaom kaminawk boih pakoehhaih hoi ahmin hoihhaih to ka paek han.
20 Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.
To naah kang hoih o let han, nangcae to kang tacuu naah kang hoih o let han: nangmacae mikhnuk ah misong thung hoiah kam laemsak let han, to naah long kaminawk boih salakah kahoih ahmin hoi saphawhaih to kang paek o han, nangmacae hma roe ah nangcae taham kang hoih o sak let naah, long kaminawk boih thungah tahamhoihaih hoi khingyahaih kang paek o han, tiah Angraeng mah thuih.

< Zephaniah 3 >