< Zephaniah 2 >
1 Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
Adunaţi-vă, da, adunaţi-vă, naţiune nedorită;
2 kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà, kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín, kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
Înainte de a se da hotărârea, înainte ca ziua să treacă precum pleava, înainte ca mânia înverşunată a DOMNULUI să vină asupra voastră, înainte ca ziua mâniei DOMNULUI să vină asupra voastră.
3 Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà, ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ. Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú, bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
Căutaţi-l pe DOMNUL, voi toţi cei blânzi ai pământului, care aţi lucrat judecata lui; căutaţi dreptatea, căutaţi blândeţea, poate că veţi fi ascunşi în ziua mâniei DOMNULUI.
4 Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀, Aṣkeloni yóò sì dahoro. Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde, a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
Fiindcă Gaza va fi părăsită şi Ascalonul va fi un pustiu, ei vor alunga Asdodul la amiază şi Ecronul va fi dezrădăcinat.
5 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun, ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti; ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani, ilẹ̀ àwọn ara Filistini. “Èmi yóò pa yín run, ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
Vai locuitorilor ţărmului mării, naţiunea cheretiţilor! Cuvântul DOMNULUI este împotriva voastră; Canaane, ţara filistenilor, te voi nimici până nu va mai fi niciun locuitor.
6 Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti, ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
Şi ţărmul mării va fi locaşuri şi colibe pentru păstori şi staule pentru turme.
7 Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda, níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran. Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́. Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò, yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
Şi ţărmul va fi pentru rămăşiţa casei lui Iuda; ei se vor hrăni de acolo; ei se vor culca seara în casele Ascalonului, pentru că DOMNUL Dumnezeul lor îi va cerceta şi îi va întoarce din captivitatea lor.
8 “Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu, àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni, àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
Am auzit ocara Moabului şi dispreţuirile copiilor lui Amon, cu care au ocărât poporul meu şi s-au preamărit peste graniţa lor.
9 Nítorí náà, bí Èmi tí wà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí, “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu, àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra, ibi tí ó kún fún yèrèpè, àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé. Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn; àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
De aceea, precum eu trăiesc, spune DOMNUL oştirilor, Dumnezeul lui Israel, negreşit Moabul va fi ca Sodoma şi copiii lui Amon ca Gomora, locul înmulţirii urzicilor şi ocnelor de sare şi o pustiire veşnică, restul poporului meu îi va prăda, şi rămăşiţa poporului meu îi va stăpâni.
10 Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn, nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
Aceasta vor avea pentru mândria lor, pentru că au ocărât şi s-au preamărit împotriva poporului DOMNULUI oştirilor.
11 Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn; nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run. Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn, olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
DOMNUL va fi înfricoşător împotriva lor, pentru că el îi va înfometa pe toţi dumnezeii pământului; şi oamenii i se vor închina, fiecare din locul lui, toate insulele păgânilor.
12 “Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú, a ó fi idà mi pa yín.”
Voi, de asemenea, etiopienilor, veţi fi ucişi de sabia mea.
13 Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá, yóò sì pa Asiria run, yóò sì sọ Ninefe di ahoro, àti di gbígbẹ bí aginjù.
Şi el îşi va întinde mâna împotriva nordului şi va distruge Asiria; şi va face Ninive o pustietate şi uscat ca o sălbăticie.
14 Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀, àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè. Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ̀n rẹ̀. Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé, ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà, òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
Şi turme se vor culca în mijlocul ei, toate animalele naţiunilor: şi cormoranul şi cocostârcul vor cuibări pe capitelurile stâlpilor ei; vocea lor va cânta la ferestre; pustiirea va fi pe praguri, pentru că el va dezgoli lucrarea de cedru.
15 Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu. Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé, “Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.” Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́, ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó! Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀ yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.
Aceasta este cetatea care se bucură, care a trăit fără grijă, care a spus în inima ei: Eu sunt şi nu este niciuna în afară de mine; cum a devenit ea o pustietate, un loc în care animalele să se culce! Fiecare ce trece pe lângă ea va şuiera şi va face semn cu mână.