< Zephaniah 2 >
1 Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
Zbierzcie się, zbierzcie, narodzie wstrętny;
2 kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà, kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín, kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
Zanim wyjdzie dekret i dzień przeminie jak plewy; [zanim] przyjdzie na was zapalczywość gniewu PANA, zanim przyjdzie na was dzień gniewu PANA.
3 Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà, ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ. Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú, bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
Szukajcie PANA, wszyscy pokorni ziemi, którzy wypełniacie jego prawo; szukajcie sprawiedliwości, szukajcie pokory, może ukryjecie się w dniu gniewu PANA.
4 Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀, Aṣkeloni yóò sì dahoro. Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde, a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
Gaza bowiem będzie opuszczona i Aszkelon spustoszony, Aszdod w południe wyrzucą, a Ekron będzie wykorzeniony.
5 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun, ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti; ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani, ilẹ̀ àwọn ara Filistini. “Èmi yóò pa yín run, ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
Biada mieszkańcom wybrzeża morskiego, narodowi Keretytów! Słowo PANA jest przeciwko wam, Kanaanie, ziemio Filistynów; wytracę cię tak, że nie będzie [żadnego] mieszkańca.
6 Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti, ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
Wybrzeże morskie będzie [przeznaczone] na schroniska i budki dla pasterzy, i na zagrody dla trzód.
7 Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda, níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran. Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́. Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò, yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
Wybrzeże też przypadnie reszcie domu Judy i będą na nim wypasać. W domach Aszkelonu będą się kłaść wieczorem, gdyż nawiedzi ich PAN, ich Bóg, i odwróci ich niewolę.
8 “Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu, àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni, àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
Słyszałem obelgi Moabu i lżenie synów Ammona, którymi urągali mojemu ludowi i wynosili się na jego granicach.
9 Nítorí náà, bí Èmi tí wà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí, “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu, àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra, ibi tí ó kún fún yèrèpè, àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé. Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn; àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
Dlatego jak żyję, mówi PAN zastępów, Bóg Izraela, Moab stanie się jak Sodoma, a synowie Ammona jak Gomora – miejscem pokrzyw, dołem soli i pustynią aż na wieki. Resztka mego ludu złupi ich i pozostali z mego ludu posiądą ich.
10 Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn, nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
To ich [spotka] za ich pychę, gdyż lżyli i wynosili się nad lud PANA zastępów.
11 Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn; nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run. Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn, olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
PAN okaże się dla nich straszny, bo sprawi, że zmarnieją wszyscy bogowie ziemi; [i] wszystkie wyspy pogan [będą] mu oddawać pokłon, każdy ze swego miejsca.
12 “Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú, a ó fi idà mi pa yín.”
Wy też, Etiopczycy, będziecie pobici moim mieczem.
13 Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá, yóò sì pa Asiria run, yóò sì sọ Ninefe di ahoro, àti di gbígbẹ bí aginjù.
Wyciągnie bowiem swoją rękę na północ i wytraci Asyrię; zamieni Niniwę w spustoszenie [i] suchy [obszar] jak pustynię.
14 Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀, àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè. Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ̀n rẹ̀. Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé, ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà, òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
I będą się w niej wylegiwać trzody, wszelkie zwierzęta narodów; i pelikan, i bąk na głowicach jej [kolumn] będą nocować, ich głos będzie słychać w oknach, jej filary spustoszą, gdyż zerwą cedrowe obicie.
15 Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu. Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé, “Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.” Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́, ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó! Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀ yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.
Takie będzie to wesołe miasto, które mieszkało bezpiecznie i mówiło w swoim sercu: Ja jestem i oprócz mnie [nie ma] innego. Jakże stało się spustoszeniem, legowiskiem zwierząt! Każdy, kto będzie przechodził obok niego, zaświśnie i machnie ręką.