< Zephaniah 2 >

1 Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀ orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
Szedjétek össze magatokat, szedjétek, nemzet, mely erre nem vágyik!
2 kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà, kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín, kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
Mielőtt megszületnék a végzés – mint – polyva múlnak a napok – mielőtt még nem jön reátok az Örökkévaló föllobbanó haragja, mielőtt még nem jön reátok az Örökkévaló haragjának napja.
3 Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà, ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ. Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú, bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.
Keressétek az Örökkévalót, ti mind az ország alázatosai, kik az ő törvényét cselekedték; keressetek igazságot, keressetek alázatosságot: hátha rejtve lehetnétek az Örökkévaló haragjának napján.
4 Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀, Aṣkeloni yóò sì dahoro. Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde, a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
Mert Azza elhagyatottá lészen és Askelón pusztasággá; Asdódot délben kergetik ki és Ekrón gyökerestől kitépetik.
5 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun, ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti; ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani, ilẹ̀ àwọn ara Filistini. “Èmi yóò pa yín run, ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
Oh ti lakói a tengermelléknek, kerétiek népe! Az Örökkévaló igéje rátok, Kanaán, filiszteusok országa: Elveszítelek, lakó nélkül lészsz!
6 Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti, ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
És lészen a tengermellék pásztorok tanyáivá, rétjeivé és juhok aklaivá.
7 Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda, níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran. Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́. Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò, yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.
És osztály része lesz Jehúda háza maradékának, azokon legeltetnek: Askelón házaiban estennen heverésznek, mert gondol majd rájuk az Örökkévaló, az ő Istenök, és visszahozza foglyaikat.
8 “Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu, àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni, àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
Hallottam Móáb gyalázását, és Ammón fiainak szidalmait, a melyekkel gyalázták a népemet és fennhéjáztak az ő határa ellen.
9 Nítorí náà, bí Èmi tí wà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí, “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu, àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra, ibi tí ó kún fún yèrèpè, àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé. Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn; àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni yóò jogún ilẹ̀ wọn.”
Azért, ahogy élek, úgymond az Örökkévaló, a seregek Ura, Izraél Istene, bizony Móáb olyan lesz mint Szodoma és Ammón fiai mint Amóra, csalánnak birtoka és sónak bányája és pusztaság mindörökké: népem maradéka prédálja őket és nemzetem megmaradt része birtokba veszi őket.
10 Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn, nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
Ez jut nekik gőgjük fejében, a miért gyaláztak és fennhéjáztak az Örökkévaló, a seregek Urának népe ellen.
11 Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn; nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run. Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn, olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
Félelmetes az Örökkévaló felettük, mert elsorvasztotta mind a föld isteneit, és leborulnak előtte, kiki a maga helyéről, mind a nemzetek szigetei.
12 “Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú, a ó fi idà mi pa yín.”
Ti is kúsiták, kardom megöltjei vagytok.
13 Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá, yóò sì pa Asiria run, yóò sì sọ Ninefe di ahoro, àti di gbígbẹ bí aginjù.
Nyújtsa ki kezét az észak ellen, veszítse el Assúrt és tegye Ninivét pusztasággá, szárazsággá, mint a sivatag.
14 Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀, àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè. Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ̀n rẹ̀. Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé, ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà, òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
És heverésznek benne nyájak, mindennemű vad, pelikán is, sün is, ott hálnak oszlopcsúcsain, énekelő hang az ablakban, rom a küszöbön, mert czédrusa csupasszá lett.
15 Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu. Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé, “Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.” Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́, ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó! Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀ yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà, wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.
Ez az az ujjongó város, mely biztosságban lakott, a mely azt mondta szívében: én és senki más! Mint lett pusztulássá, vadnak heverőjévé! Bárki elmegy mellette, az pisszeg, rázza kezét.

< Zephaniah 2 >