< Zephaniah 1 >

1 Sí olórí akọrin lórí ohun èlò orin olókùn mi. Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.
Amonning oƣli Yosiya Yǝⱨudaƣa padixaⱨ bolƣan waⱪitlarda, Ⱨǝzǝkiyaning qǝwrisi, Amariyaning ǝwrisi, Gǝdaliyaning nǝwrisi, Kuxining oƣli Zǝfaniyaƣa yǝtkǝn Pǝrwǝrdigarning sɵzi: —
2 “Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò lórí ilẹ̀ náà pátápátá,” ni Olúwa wí.
Mǝn yǝr yüzidin ⱨǝmmini ⱪurutuwetimǝn, — dǝydu Pǝrwǝrdigar;
3 “Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run kúrò, àti ẹja inú Òkun, àti ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,” ni Olúwa wí.
— Insan ⱨǝm ⱨaywanni ⱪurutuwetimǝn, Asmandiki uqar-ⱪanatlar ⱨǝm dengizdiki beliⱪlarni, Barliⱪ putlikaxanglarni rǝzil adǝmlǝr bilǝn tǝng ⱪurutuwetimǝn, Insaniyǝtni yǝr yüzidin üzüp taxlaymǝn, — dǝydu Pǝrwǝrdigar.
4 “Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu. Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,
— Xuning bilǝn Mǝn Yǝⱨuda üstigǝ, Barliⱪ Yerusalemdikilǝr üstigǝ ⱪolumni sozimǝn; Muxu yǝrdǝ «Baal»ning ⱪalduⱪini, «Ⱪemar»larning namini kaⱨinlar bilǝn billǝ üzüp taxlaymǝn;
5 àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé, àwọn tí ń sin ogun ọ̀run, àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra, tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.
Xundaⱪla ɵgzidǝ turup asmandiki jisimlarƣa bax uridiƣanlarni, Pǝrwǝrdigarƣa bax urup, xundaⱪla Uning nami bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilip turup, «Malkam»ning nami bilǝnmu ⱪǝsǝm ⱪilidiƣanlarni,
6 Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa; àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”
Pǝrwǝrdigardin tǝzgǝnlǝrni, Pǝrwǝrdigarni izdimǝydiƣan yaki Uningdin yol sorimiƣanlarnimu üzüp taxlaymǝn.
7 Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè, nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀. Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀, ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.
Rǝb Pǝrwǝrdigarning ⱨuzuri aldida süküt ⱪilinglar; Qünki Pǝrwǝrdigarning küni yeⱪindur; Qünki Pǝrwǝrdigar ⱪurbanliⱪni tǝyyarlidi, U meⱨmanlarni «taⱨarǝt ⱪildurup» ⱨalal ⱪildi;
8 “Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa, Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn ọmọ ọba ọkùnrin, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.
Pǝrwǝrdigarning ⱪurbanliⱪining künidǝ xundaⱪ boliduki, Mǝn ǝmirlǝrni, padixaⱨlarning oƣullirini wǝ yat ǝllǝrning kiyimlirini kiyiwalƣanlarning ⱨǝmmisini jazalaymǝn;
9 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà, tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.
Xu küni Mǝn bosuƣidin dǝssimǝy atlaydiƣanlarni, Yǝni zulum-zorawanliⱪ ⱨǝm aldamqiliⱪⱪa tayinip, hojayinlirining ɵylirini tolduridiƣanlarni jazalaymǝn.
10 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà ibodè ẹja, híhu láti ìhà kejì wá àti ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.
Xu künidǝ, — dǝydu Pǝrwǝrdigar, «Beliⱪ dǝrwazisi»din «Waydad», «Ikkinqi mǝⱨǝllǝ»din ⱨɵrkirǝxlǝr, Dɵng-egizliklǝrdin ƣayǝt zor «gum-gum» ⱪilip wǝyran ⱪilinƣan awazlar anglinidu.
11 Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní agbègbè ọjà, gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò, gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.
«Ⱨɵrkirǝnglar, i «Oymanliⱪ mǝⱨǝllisi»dikilǝr; Qünki «sodigǝr hǝlⱪ»ning ⱨǝmmisi ⱪiliqlandi, Kümüx bilǝn qingdalƣanlar ⱪirildi!»
12 Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà, èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn, tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn, àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’
— Wǝ xu qaƣda xundaⱪ boliduki, Mǝn Yerusalemni qiraƣlar bilǝn ahturimǝn, Arzangliri üstidǝ tinƣan xarabtǝk turƣan ǝndixisiz adǝmlǝrni, Yǝni kɵnglidǝ: «Pǝrwǝrdigar ⱨeq yahxiliⱪni ⱪilmaydu, yamanliⱪnimu ⱪilmaydu» degǝnlǝrni jazalaymǝn.
13 Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun, àti ilé wọn yóò sì run. Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n wọn kì yóò gbé nínú ilé náà, wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí wáìnì láti inú rẹ̀.”
Əmdi bayliⱪliri olja, Ɵyliri bǝrbat bolidu; Ular ɵylǝrni salƣini bilǝn, Ularda turmaydu; Üzümzarlarni bǝrpa ⱪilƣini bilǝn, Ularning xarabini iqmǝydu.
14 “Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀, ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀ kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún àwọn alágbára; ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,
Pǝrwǝrdigarning uluƣ küni yeⱪindur; Bǝrⱨǝⱪ yeⱪindur, intayin tez yetip kelidu; Angla, Pǝrwǝrdigarning künining sadasi! Yetip kǝlgǝndǝ palwanmu ǝlǝmlik warⱪiraydu.
15 ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú, ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú, ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba, ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,
Xu küni ⱪǝⱨr elip kelidiƣan bir kün, Külpǝtlik ⱨǝm dǝrd-ǝlǝmlik bir kün, Wǝyranqiliⱪ ⱨǝm bǝrbatliⱪ qüxidiƣan bir kün, Zulmǝtlik ⱨǝm sürlük bir kün, Bulutlar ⱨǝm ⱪap-ⱪarangƣuluⱪ bilǝn ⱪaplanƣan bir kün,
16 ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun sí àwọn ìlú olódi àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.
Istiⱨkamlaxⱪan xǝⱨǝrlǝrgǝ, sepilning egiz potǝylirigǝ ⱨujum ⱪilidiƣan, Kanay qelinidiƣan, agaⱨ signali kɵtürülidiƣan bir kün bolidu.
17 “Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú, nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa. Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.
Mǝn adǝmlǝr üstigǝ külpǝtlǝrni qüxürimǝn, — Ular ⱪariƣulardǝk yüridu; Qünki ular Pǝrwǝrdigarƣa ⱪarxi gunaⱨ ⱪildi; Ularning ⱪanliri topa-qangdǝk, Ularning üqǝy-ⱪerinliri poⱪtǝk tɵkülidu;
18 Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn kì yóò sì le gbà wọ́n là ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.” Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná ìjowú rẹ̀ parun, nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.
Pǝrwǝrdigarning ⱪǝⱨri qüxkǝn künidǝ altun-kümüxliri ularni ⱪutⱪuzalmaydu; Bǝlki pütkül jaⱨan Uning ƣǝzǝp oti tǝripidin yǝwetilidu; Qünki U barliⱪ yǝr yüzidikilǝrning üstigǝ mutlǝⱪ bir ⱨalakǝt, dǝⱨxǝtlik bir ⱨalakǝt qüxüridu.

< Zephaniah 1 >