< Zephaniah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.
Cuvântul DOMNULUI, care a venit la Ţefania, fiul lui Cuşi, fiul lui Ghedalia, fiul lui Amaria, fiul lui Hizchia, în zilele lui Iosia, fiul lui Amon, împăratul lui Iuda.
2 “Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò lórí ilẹ̀ náà pátápátá,” ni Olúwa wí.
Voi mistui cu desăvârşire totul de pe faţa pământului, spune DOMNUL.
3 “Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run kúrò, àti ẹja inú Òkun, àti ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,” ni Olúwa wí.
Voi mistui pe om şi pe animal; voi mistui păsările cerului şi peştii mării şi pietrele de poticnire împreună cu cei stricaţi; şi voi stârpi omul de pe pământ, spune DOMNUL.
4 “Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu. Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,
De asemenea îmi voi întinde mâna asupra lui Iuda şi asupra tuturor locuitorilor Ierusalimului; şi voi stârpi rămăşiţa lui Baal din acest loc şi numele chemarimilor împreună cu preoţii;
5 àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé, àwọn tí ń sin ogun ọ̀run, àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra, tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.
Şi pe cei care se închină oştirii cerului pe acoperişuri; şi pe cei care se închină şi care jură pe DOMNUL şi care jură pe Malcam;
6 Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa; àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”
Şi pe cei care se întorc de la a-l urma pe DOMNUL şi pe cei care nu l-au căutat pe DOMNUL, nici nu au întrebat de el.
7 Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè, nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀. Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀, ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.
Taci în prezenţa Domnului DUMNEZEU, pentru că ziua DOMNULUI este aproape, pentru că DOMNUL a pregătit un sacrificiu, el şi-a chemat oaspeţii.
8 “Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa, Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn ọmọ ọba ọkùnrin, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.
Şi se va întâmpla că în ziua sacrificiului DOMNULUI voi pedepsi prinţii şi copiii împăratului şi pe toţi care sunt îmbrăcaţi cu haine străine.
9 Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà, tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.
De asemenea, în aceeaşi zi voi pedepsi pe toţi cei care sar pragul, care umplu casele stăpânilor lor cu violenţă şi înşelăciune.
10 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí, “Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà ibodè ẹja, híhu láti ìhà kejì wá àti ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.
Şi se va întâmpla, în acea zi, spune DOMNUL, că va fi zgomotul unui strigăt de la poarta peştelui şi un urlet de la a doua şi un trosnet mare dinspre dealuri.
11 Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní agbègbè ọjà, gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò, gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.
Urlaţi, voi locuitori din Macteş, pentru că tot poporul comercianţilor este doborât; toţi cei ce cară argint sunt stârpiţi.
12 Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà, èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn, tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn, àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’
Şi se va întâmpla, în acel timp, că voi cerceta Ierusalimul cu candele şi voi pedepsi oamenii care sunt aşezaţi pe drojdiile lor, care spun în inima lor: DOMNUL nu va face bine, nici nu va face rău.
13 Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun, àti ilé wọn yóò sì run. Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n wọn kì yóò gbé nínú ilé náà, wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí wáìnì láti inú rẹ̀.”
De aceea bunurile lor vor deveni o pradă, şi casele lor o pustietate; de asemenea vor zidi case, dar nu le vor locui; şi vor sădi vii, dar nu le vor bea vinul.
14 “Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀, ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀ kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún àwọn alágbára; ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,
Ziua cea mare a DOMNULUI este aproape, este aproape, şi se grăbeşte foarte mult, vocea zilei DOMNULUI; viteazul va striga acolo cu amar.
15 ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú, ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú, ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba, ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,
Ziua aceea este o zi a furiei, o zi de necaz şi strâmtorare, o zi de secătuire şi de pustiire, o zi de întuneric şi de întunecime, o zi cu nori şi de întuneric gros,
16 ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun sí àwọn ìlú olódi àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.
O zi a trâmbiţei şi a alarmei împotriva cetăţilor întărite şi împotriva turnurilor înalte.
17 “Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú, nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa. Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.
Şi voi aduce strâmtorare peste oameni pentru ca ei să umble ca orbii, pentru că au păcătuit împotriva DOMNULUI; şi sângele lor va fi vărsat ca ţărâna, şi carnea lor ca balega.
18 Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn kì yóò sì le gbà wọ́n là ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.” Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná ìjowú rẹ̀ parun, nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.
Nici argintul lor, nici aurul lor nu va fi în stare să îi scape în ziua furiei DOMNULUI; dar tot ţinutul va fi mistuit de focul geloziei lui, pentru că el va face chiar o descotorosire grabnică de toți cei care locuiesc în ţinut.

< Zephaniah 1 >