< Zechariah 1 >
1 Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
Восьмого місяця другого року Да́рія було́ Господнє слово до пророка Заха́рія, сина Берехії, сина Іддового, таке:
2 “Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
„Розгні́вався Господь на батьків ваших палю́чим гнівом.
3 Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
І скажи їм: Так говорить Госпо́дь Савао́т: Верні́ться до Мене, — говорить Господь Саваот, — і верну́ся до вас, говорить Господь Саваот.
4 Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
Не будьте, як ваші батьки́, що до них кли́кали стародавні пророки, говорячи: Так говорить Господь Саваот: Верніться з доріг ваших злих і з чи́нів ваших лихих! Та не слуха́ли ви й не прислуха́лись до Мене, говорить Господь.
5 Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
Де вони, батьки ваші? А пророки — чи ж наві́ки живуть?
6 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
Та слова́ Мої й постано́ви Мої, що Я наказа́в рабам Моїм пророкам, чи ж не досягли́ вони до ваших батькі́в? І вернулись вони та й сказали: Як заду́мав Господь Саваот зробити нам за нашими дорогами й за нашими чинами, так зробив Він із нами“.
7 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
Двадцятого й четвертого дня, одина́дцятого місяця, — це місяць шеват, — за другого року Да́рія було слово Господнє до пророка Заха́рія, сина Берехії сина Іддового, таке:
8 Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
„Бачив я цієї но́чі, аж ось на черво́ному коні їде муж, і він стоїть між ми́ртами, що в глибині, а за ним ко́ні черво́ні, руді́ та білі.
9 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
І сказав я: „Що́ це, мій пане?“І відказав мені той ангол, що говорив зо мною: „Я тобі покажу́, що́ це таке“.
10 Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
І відповів той муж, що стояв між ми́ртами, та й сказав: „Це ті, що Господь їх послав обійти́ землю“.
11 Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
І відповіли́ вони Господньому анголові, що стояв між ми́ртами, та й сказали: „Перейшли ми землю, і ось уся земля сидить спокі́йно“.
12 Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
І відповів ангол Господній та й сказав: „Го́споди Савао́те, аж до́ки Ти не змилосе́рдишся над Єрусалимом та над Юдиними міста́ми, на які Ти гніваєшся оце сімдеся́т літ?“
13 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
І відповів Господь анголові, що говорив зо мною, слова́ добрі, слова́ вті́шливі.
14 Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
І сказав до мене той ангол, що говорив зо мною: „Клич, говорячи: Так говорить Господь Саваот: Піклуюся Я про Єрусалим та про Сіон великим піклува́нням.
15 Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
І гнівом великим Я гніваюся на ті спокі́йні наро́ди, на яких Я мало гнівався, а вони допомогли́ злому.
16 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
Тому так промовляє Господь: Вернуся Я до Єрусалиму з милосердям, храм Мій буде збудо́ваний у ньому, — говорить Госпо́дь Савао́т, — а мірни́чий шнур буде розтя́гнений над Єрусалимом.
17 “Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
Ще клич та й скажи: Так говорить Господь Саваот: Знов добром перепо́вняться міста́ Мої, і Господь ще поті́шить Сіона, і ще ви́бере Єрусалима!“
18 Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
І звів я очі свої, та й побачив, аж ось чотири ро́ги.
19 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
І запита́в я ангола, що говорив зо мною: „Що́ це?“А він відказав мені: „Це ті ро́ги, що розпоро́шили Юду й Ізраїля та Єрусалим“.
20 Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
І Господь показав мені чотирьох майстрів.
21 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”
І запитав я: „Що́ вони приходять зробити?“А Він відказав, говорячи: „Це ті ро́ги, що розпоро́шили Юду, так що ніхто не підвів голови́. А ці прийшли́ настраши́ти їх, щоб скинути ро́ги тих наро́дів, що підносять ро́га проти Юдиного кра́ю, щоб його розпоро́шити“.