< Zechariah 1 >

1 Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
În luna a opta, în anul al doilea al lui Darius, a venit cuvântul DOMNULUI la profetul Zaharia, fiul lui Berechia, fiul profetului Ido, spunând:
2 “Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
DOMNUL s-a înfuriat pe părinţii voştri.
3 Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
De aceea spune-le: Astfel spune DOMNUL oştirilor: Întoarceţi-vă la mine, spune DOMNUL oştirilor şi eu mă voi întoarce la voi, spune DOMNUL oştirilor.
4 Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
Nu fiţi ca părinţii voştri, la care au strigat profeţii dinainte, spunând: Astfel spune DOMNUL oştirilor: Întoarceţi-vă acum de la căile voastre rele şi de la faptele voastre rele; dar nu au auzit, nici nu mi-au dat ascultare, spune DOMNUL.
5 Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
Părinţii voştri, unde sunt ei? Şi profeţii, trăiesc ei pentru totdeauna?
6 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
Dar cuvintele mele şi statutele mele pe care le-am poruncit servitorilor mei, profeţii, nu i-au apucat ele pe părinţii voştri? Şi ei s-au întors şi au spus: Precum DOMNUL oştirilor a gândit să ne facă, conform căilor noastre şi conform faptelor noastre, astfel s-a purtat el cu noi.
7 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
În ziua a douăzeci şi patra a lunii a unsprezecea, care este luna Şebat, în anul al doilea al lui Darius, a venit cuvântul DOMNULUI la profetul Zaharia, fiul lui Berechia, fiul profetului Ido, spunând:
8 Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
Am văzut în noapte şi iată, un om călărind pe un cal roşu şi stătea între pomii de mirt care erau jos; şi în urma lui erau acolo cai roşii, pestriţi şi albi.
9 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
Atunci am spus: Ce sunt aceştia, domnul meu? Şi îngerul care vorbea cu mine mi-a zis: Îţi voi arăta ce sunt aceştia.
10 Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
Şi bărbatul care stătea între pomii de mirt a răspuns şi a zis: Aceştia sunt cei pe care DOMNUL i-a trimis să umble încoace şi încolo pe pământ.
11 Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
Şi ei au răspuns îngerului DOMNULUI, care stătea între pomii de mirt, şi au zis: Noi am umblat încoace şi încolo pe pământ şi, iată, tot pământul şade liniştit şi este în odihnă.
12 Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
Atunci îngerul DOMNULUI a răspuns şi a zis: DOAMNE al oştirilor, până când nu vei avea milă de Ierusalim şi de cetăţile lui Iuda, împotriva cărora te-ai indignat aceşti şaptezeci de ani?
13 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
Şi DOMNUL a răspuns îngerului care vorbea cu mine, cuvinte bune şi cuvinte mângâietoare.
14 Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
Astfel îngerul care vorbea cu mine îndeaproape, mi-a zis: Strigă, spunând: Astfel spune DOMNUL oştirilor: Sunt gelos, cu o mare gelozie, pentru Ierusalim şi pentru Sion.
15 Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
Şi mă înfurii pe păgânii care sunt în tihnă; fiindcă eu eram numai puţin înfuriat iar ei au ajutat nenorocirii.
16 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
De aceea astfel spune DOMNUL: M-am întors la Ierusalim cu îndurări; casa mea va fi construită în el, spune DOMNUL oştirilor, şi o frânghie de măsurat va fi întinsă peste Ierusalim.
17 “Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
Strigă totuşi, spunând: Astfel spune DOMNUL oştirilor: Cetăţile mele, prin prosperitate, vor fi împrăştiate peste tot şi DOMNUL va mângâia încă Sionul şi va alege încă Ierusalimul.
18 Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
Atunci mi-am ridicat ochii şi am văzut şi iată, patru coarne.
19 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
Şi am spus îngerului care vorbea cu mine: Ce sunt acestea? Şi el mi-a răspuns: Acestea sunt coarnele care au împrăştiat pe Iuda, pe Israel şi Ierusalimul.
20 Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
Şi DOMNUL mi-a arătat patru tâmplari.
21 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”
Atunci eu am zis: Ce vin aceştia să facă? Iar el a vorbit, spunând: Acestea sunt coarnele care au împrăştiat pe Iuda, astfel încât niciun om nu şi-a ridicat capul; dar aceştia au venit să le sperie, ca să alunge coarnele neamurilor care şi-au înălţat cornul împotriva ţării lui Iuda pentru a o împrăştia.

< Zechariah 1 >