< Zechariah 1 >

1 Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
Dárius második esztendejében, a nyolczadik hónapban szóla az Úr Zakariáshoz, a Berekiás fiához, a ki Iddó próféta fia, mondván:
2 “Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
Igen megharagudott az Úr a ti atyáitokra.
3 Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Mondjad azért nékik: Ezt mondja a Seregeknek Ura: Térjetek hozzám, szól a Seregeknek Ura, és hozzátok térek, mond a Seregeknek Ura.
4 Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
Ne legyetek olyanok, mint atyáitok, a kikhez az elébbi próféták kiáltottak, mondván: Ezt mondja a Seregeknek Ura: Térjetek meg kérlek a ti gonosz útaitokról, és a ti gonosz cselekedeteitekből, de nem hallgattak meg, és nem figyelmeztek reám, szól az Úr.
5 Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
Atyáitok? Hol vannak ők? És a próféták örökké élnek-é?
6 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
De az én beszédeim és végzéseim, a melyeket szolgáim, a próféták által hirdettem: nem beteljesedtek-é a ti atyáitokon? És megtértek és azt mondták: A mint elhatározta vala a Seregeknek Ura, hogy a mi útaink és cselekedeteink szerint bánik velünk: úgy bánt velünk.
7 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
A tizenegyedik hónapnak, azaz a Sebat hónapnak huszonnegyedik napján, Dáriusnak második esztendejében, szóla az Úr Zakariáshoz, a Berekiás fiához, a ki Iddó próféta fia, mondván:
8 Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
Látám éjszaka, hogy ímé, egy férfiú veres lovon ül vala, és áll vala a mirtus-fák között, a melyek egy árnyas völgyben valának; háta megett pedig veres, tarka és fehér lovak.
9 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
És mondám: Mik ezek Uram? És mondá nékem az angyal, a ki beszél vala nékem: Én megmutatom néked: mik ezek.
10 Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
Akkor felele az a férfiú, a ki a mirtus-fák között áll vala, és mondá: Azok ezek, a kiket az Úr küldött, hogy járják be e földet;
11 Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
És felelének az Úr angyalának, a ki a mirtus-fák között áll vala, és mondák: Bejártuk a földet, és ímé, az egész föld vesztegel és nyugodt.
12 Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
Az Úr angyala pedig felele, és mondá: Seregeknek Ura! Meddig nem könyörülsz még Jeruzsálemen és Júdának városain, a melyekre haragszol immár hetven esztendő óta?
13 Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
És nyájas szavakkal, vígasztaló szókkal felele az Úr az angyalnak, a ki beszél vala velem.
14 Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
És mondá nékem az angyal, a ki beszél vala velem: Kiálts, ezt mondván: Ezt mondja a Seregeknek Ura: szeretem Jeruzsálemet és a Siont nagy szeretettel!
15 Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
De nagy haraggal haragszom én a hivalkodó népekre, a kikre kevéssé haragudtam ugyan, de ők gonoszra törtek.
16 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
Azt mondja azért az Úr: könyörületességgel fordulok Jeruzsálemhez; benne építtetik meg az én házam, szól a Seregeknek Ura, és mérőzsinór nyujtatik ki Jeruzsálem felett.
17 “Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
Mégis kiálts, mondván: Ezt mondja a Seregeknek Ura: Bővelkedni fognak még városaim a jóban, mert megvígasztalja még az Úr a Siont, és magáévá fogadja még Jeruzsálemet!
18 Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
Majd felemelém szemeimet, és ímé, négy szarvat láték.
19 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
És mondám az angyalnak, a ki beszél vala velem: Mik ezek? És monda nékem: Ezek azok a szarvak, a melyek szétszórták Júdát, Izráelt és Jeruzsálemet.
20 Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
Azután mutata nékem az Úr négy mesterembert.
21 Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”
És mondám: Mit jöttek ezek cselekedni? Ő pedig szóla, mondván: Ezek azok a szarvak, a melyek szétszórták Júdát annyira, hogy senki sem emelheti vala fel fejét: de eljöttek ezek, hogy elrettentsék őket, hogy letörjék a pogányok szarvait, a kik szarvakkal támadtak vala Júda földe ellen, hogy szétszórják azt.

< Zechariah 1 >