< Zechariah 9 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki, Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀; nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn, àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.
Brzemię słowa PANA w ziemi Chadraku, a Damaszek będzie jego odpoczynkiem, gdyż PANU przypatrzą się oczy ludzi i wszystkich pokoleń Izraela;
2 Àti Hamati pẹ̀lú yóò ṣe ààlà rẹ̀ Tire àti Sidoni bí o tilẹ̀ ṣe ọlọ́gbọ́n gidigidi.
Nawet Chamat będzie miał z nim granicę, [a także] Tyr i Sydon, choć są bardzo mądre.
3 Tire sì mọ odi líle fún ara rẹ̀, ó sì kó fàdákà jọ bí eruku, àti wúrà dáradára bí ẹrẹ̀ ìgboro.
Tyr bowiem zbudował sobie twierdzę i nagromadził srebra jak prochu, a złota jak błota na ulicach.
4 Ṣùgbọ́n, Olúwa yóò kó gbogbo ohun ìní rẹ̀ lọ, yóò sì pa agbára rẹ̀ run ní ojú Òkun, a ó sì fi iná jó o run.
Oto PAN go wypędzi i wrzuci w morze jego siłę, on sam zostanie strawiony ogniem.
5 Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù; Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi, àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í. Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀, Aṣkeloni yóò sì di ahoro.
Ujrzy to Aszkelon i ulęknie się, podobnie Gaza – i pogrąży się w smutku; również Ekron, bo jego nadzieja zawiedzie. I zginie król z Gazy, a Aszkelon nie będzie zamieszkany.
6 Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu, Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.
I bękart będzie mieszkał w Aszdodzie, a tak zniszczę pychę Filistynów.
7 Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀, àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀: ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa, wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda, àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.
Usunę krew każdego z jego ust i obrzydliwości spomiędzy jego zębów. Kto pozostanie, będzie należał do naszego Boga, aby był jak książę w Judzie i Ekron, jak Jebusyta.
8 Èmi yóò sì dó yí ilẹ̀ mi ká nítorí ogun àwọn tí wọ́n ń wá ohun tí wọn yóò bàjẹ́ kiri, kò sí aninilára tí yóò bori wọn mọ́: nítorí ni ìsinsin yìí ni mo fi ojú ṣọ́ wọn.
I rozłożę obóz dokoła swego domu z powodu wojska i z powodu tych, którzy przechodzą i wracają. I już nie przejdzie przez nich żaden ciemięzca. Teraz bowiem widziały to moje oczy.
9 Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu. Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ: òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà; ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Raduj się wielce, córko Syjonu! Wykrzykuj, córko Jerozolimy! Oto twój Król przychodzi do ciebie; sprawiedliwy i Zbawiciel, cichy i siedzący na ośle, na oślątku, źrebięciu oślicy.
10 Èmi ó sì gbé kẹ̀kẹ́ kúrò ni Efraimu, àti ẹṣin ogun kúrò ni Jerusalẹmu, a ó sì ṣẹ́ ọrun ogun. Òun yóò sì kéde àlàáfíà sí àwọn kèfèrí. Ìjọba rẹ̀ yóò sì gbilẹ̀ láti Òkun dé Òkun, àti láti odò títí de òpin ayé.
Zniszczę bowiem rydwany z Efraima i konie z Jerozolimy, a łuki wojenne będą połamane. I ogłosi pokój narodom, a jego władza będzie [sięgać] od morza aż do morza i od rzeki aż po krańce ziemi.
11 Ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, Èmi ó dá àwọn ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun.
A co do ciebie, ze względu na krew twego przymierza wypuściłem twoich więźniów z dołu, w którym nie ma wody.
12 Ẹ padà sínú odi agbára yín, ẹ̀yin òǹdè ti o ni ìrètí: àní lónìí yìí èmi sọ pé, èmi o san án fún ọ ni ìlọ́po méjì.
Wróćcie do twierdzy, więźniowie, którzy macie nadzieję. Dziś bowiem ogłaszam, że wynagrodzę w dwójnasób;
13 Èmi ó fa Juda le bí mo ṣe fa ọrun mi le, mo sì fi Efraimu kún un, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin dìde, ìwọ Sioni, sí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ìwọ Giriki, mo ṣe ọ́ bí idà alágbára.
Gdy [jak] łuk naciągnę Judę, a na nim nałożę Efraima; wzbudzę twoich synów, Syjonie, przeciwko twoim synom, Jawanie, i zrobię z ciebie miecz mocarza.
14 Olúwa yóò sì fi ara hàn ní orí wọn; ọfà rẹ̀ yóò sì jáde lọ bí mọ̀nàmọ́ná. Olúwa Olódùmarè yóò sì fọn ìpè, Òun yóò sì lọ nínú atẹ́gùn ìjì gúúsù.
PAN bowiem ukaże się nad nimi i jak błyskawica wyleci jego strzała. Pan BÓG zadmie w trąbę i wyruszy w wichrach południa.
15 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bò wọ́n; wọn ó sì jẹ ni run, wọn ó sì tẹ òkúta kànnàkànnà mọ́lẹ̀; wọn ó sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn bí wáìnì, wọn ó sì kún bí ọpọ́n, wọn ó sì rin ṣinṣin bí àwọn igun pẹpẹ.
PAN zastępów będzie ochraniać swój lud; pochłoną i przemogą kamienie z procy, będą pić i krzyczeć jak od wina; i napełnią się jak czasza i jak rogi ołtarza.
16 Olúwa Ọlọ́run wọn yóò sì gbà wọ́n là ni ọjọ́ náà bí agbo ènìyàn rẹ̀: nítorí wọn ó dàbí àwọn òkúta adé, tí a gbé sókè bí àmì lórí ilẹ̀ rẹ̀.
W tym dniu PAN, ich Bóg, wybawi ich jak trzodę swego ludu. Będą bowiem jak kamienie w koronie, wystawieni jak sztandar w jego ziemi.
17 Nítorí oore rẹ̀ tí tóbi tó, ẹwà rẹ̀ sì tí pọ̀! Ọkà yóò mú ọ̀dọ́mọkùnrin dárayá, àti ọtí wáìnì tuntun yóò mú àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
Jak wielkie bowiem jest jego błogosławieństwo! Jak wspaniałe jego piękno! Zboże pocieszy młodzieńców, a moszcz – panny.

< Zechariah 9 >