< Zechariah 9 >
1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki, Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀; nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn, àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.
Paroles du Seigneur contre la terre de Sedrach; et celle de Damas sera sacrifiée comme elle; car le Seigneur surveille les hommes et toutes les tribus d'Israël.
2 Àti Hamati pẹ̀lú yóò ṣe ààlà rẹ̀ Tire àti Sidoni bí o tilẹ̀ ṣe ọlọ́gbọ́n gidigidi.
Et cette parole est contre la terre d'Émath qui contient Tyr et Sidon, parce qu'elles ont trop connu la sagesse.
3 Tire sì mọ odi líle fún ara rẹ̀, ó sì kó fàdákà jọ bí eruku, àti wúrà dáradára bí ẹrẹ̀ ìgboro.
Or Tyr s'est bâti des forteresses, et elle a thésaurisé de l'argent par monceaux comme de la poussière, et des amas d'or comme la boue des chemins.
4 Ṣùgbọ́n, Olúwa yóò kó gbogbo ohun ìní rẹ̀ lọ, yóò sì pa agbára rẹ̀ run ní ojú Òkun, a ó sì fi iná jó o run.
Et à cause de cela le Seigneur en prendra possession, et Il jettera ses forces à la mer, et elle-même sera dévorée par le feu.
5 Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù; Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi, àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í. Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀, Aṣkeloni yóò sì di ahoro.
Ascalon le verra et en tremblera; Gaza le verra et en souffrira cruellement; Ascaron le verra et sera confondue de sa chute; et le roi de Gaza périra, et Ascalon ne sera plus habitée.
6 Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu, Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.
Et des étrangers repeupleront Azot; et J'abattrai l'orgueil des Philistins.
7 Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀, àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀: ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa, wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda, àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.
Et J'ôterai de leur bouche le sang des victimes, et l'abomination d'entre leurs dents; et ils seront aussi délaissés par notre Dieu, et ils seront comme un chef de mille hommes en Juda, et Ascaron sera comme un Jébuséen.
8 Èmi yóò sì dó yí ilẹ̀ mi ká nítorí ogun àwọn tí wọ́n ń wá ohun tí wọn yóò bàjẹ́ kiri, kò sí aninilára tí yóò bori wọn mọ́: nítorí ni ìsinsin yìí ni mo fi ojú ṣọ́ wọn.
Et J'élèverai un rempart autour de Ma maison, pour qu'on ne puisse plus la traverser et y revenir, et que nul envahisseur n'y pénètre désormais; car maintenant Je la vois de Mes yeux.
9 Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu. Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ: òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà; ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Réjouis-toi grandement, Sion, Ma fille, annonce à haute voix, Jérusalem, Ma fille: Voilà que ton Roi vient à toi, juste et sauveur, et Il est plein de douleur, Il est monté sur un âne, et sur un ânon, petit de l'ânesse.
10 Èmi ó sì gbé kẹ̀kẹ́ kúrò ni Efraimu, àti ẹṣin ogun kúrò ni Jerusalẹmu, a ó sì ṣẹ́ ọrun ogun. Òun yóò sì kéde àlàáfíà sí àwọn kèfèrí. Ìjọba rẹ̀ yóò sì gbilẹ̀ láti Òkun dé Òkun, àti láti odò títí de òpin ayé.
Et Il détruira les chars d'Éphraïm et la cavalerie de Jérusalem; et l'arc des batailles sera brisé, et il y aura paix et abondance parmi les nations; et Il régnera depuis les eaux jusqu'à la mer, depuis les fleuves jusqu'aux confins de la terre.
11 Ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, Èmi ó dá àwọn ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun.
Et toi, à cause du sang de ton alliance, tu as retiré tes captifs d'une citerne sans eau.
12 Ẹ padà sínú odi agbára yín, ẹ̀yin òǹdè ti o ni ìrètí: àní lónìí yìí èmi sọ pé, èmi o san án fún ọ ni ìlọ́po méjì.
Et vous, captifs de la Synagogue, établissez-vous en des forteresses; et, pour un jour de captivité, Je vous rétribuerai doublement.
13 Èmi ó fa Juda le bí mo ṣe fa ọrun mi le, mo sì fi Efraimu kún un, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin dìde, ìwọ Sioni, sí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ìwọ Giriki, mo ṣe ọ́ bí idà alágbára.
Juda, tu es Mon arc, et Je t'ai tendu; J'ai rempli Éphraïm; J'exciterai tes enfants, ô Sion, contre les enfants des Hellènes, et Je te manierai comme le glaive des combattants.
14 Olúwa yóò sì fi ara hàn ní orí wọn; ọfà rẹ̀ yóò sì jáde lọ bí mọ̀nàmọ́ná. Olúwa Olódùmarè yóò sì fọn ìpè, Òun yóò sì lọ nínú atẹ́gùn ìjì gúúsù.
Et le Seigneur sera près d'eux; Son trait partira comme un éclair; et le Seigneur tout-puissant sonnera de la trompette, et Il S'avancera dans le tumulte de Ses menaces.
15 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bò wọ́n; wọn ó sì jẹ ni run, wọn ó sì tẹ òkúta kànnàkànnà mọ́lẹ̀; wọn ó sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn bí wáìnì, wọn ó sì kún bí ọpọ́n, wọn ó sì rin ṣinṣin bí àwọn igun pẹpẹ.
Mais le Seigneur tout-puissant protégera les siens; ils extermineront leurs ennemis; ils les couvriront de pierres de leurs frondes; ils boiront leur sang comme du vin, et ils en rempliront leurs coupes, comme l'autel.
16 Olúwa Ọlọ́run wọn yóò sì gbà wọ́n là ni ọjọ́ náà bí agbo ènìyàn rẹ̀: nítorí wọn ó dàbí àwọn òkúta adé, tí a gbé sókè bí àmì lórí ilẹ̀ rẹ̀.
Et en ce jour le Seigneur leur Dieu les sauvera; Il sauvera Son peuple, comme un troupeau de brebis, parce que des pierres saintes sont roulées sur Sa terre.
17 Nítorí oore rẹ̀ tí tóbi tó, ẹwà rẹ̀ sì tí pọ̀! Ọkà yóò mú ọ̀dọ́mọkùnrin dárayá, àti ọtí wáìnì tuntun yóò mú àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
Car si quelque chose est Son bien, si quelque chose est Sa beauté, c'est le pain pour les jeunes hommes, et le vin d'odeur de suavité pour les vierges.