< Zechariah 9 >

1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa kọjú ìjà sí Hadiraki, Damasku ni yóò sì jẹ́ ibi ìsinmi rẹ̀; nítorí ojú Olúwa ń bẹ lára ènìyàn, àti lára gbogbo ẹ̀yà Israẹli.
[This is another] message [that I received] from Yahweh. [Yahweh said, ] “I watch [MTY] everyone, especially the tribes of Israel; [so] I will [punish the people in] the Hadrach [region] and in Damascus [city] [because of what they did to the people of Israel].
2 Àti Hamati pẹ̀lú yóò ṣe ààlà rẹ̀ Tire àti Sidoni bí o tilẹ̀ ṣe ọlọ́gbọ́n gidigidi.
[I will also punish the people in] nearby Hamath [city]. I will also [punish the people in] Tyre and Sidon [cities], even though they are [considered to be] [IRO] very wise.
3 Tire sì mọ odi líle fún ara rẹ̀, ó sì kó fàdákà jọ bí eruku, àti wúrà dáradára bí ẹrẹ̀ ìgboro.
[The people in] Tyre built a high wall [around their city]. They piled up [huge amounts of] silver and gold as though they were [piles of] dirt in the streets.
4 Ṣùgbọ́n, Olúwa yóò kó gbogbo ohun ìní rẹ̀ lọ, yóò sì pa agbára rẹ̀ run ní ojú Òkun, a ó sì fi iná jó o run.
But [I], Yahweh, will cause their precious possessions to be taken away and all their ships to be destroyed, and their city will be destroyed by a fire.
5 Aṣkeloni yóò rí í, yóò sì bẹ̀rù; Gasa pẹ̀lú yóò rí í, yóò sì káàánú gidigidi, àti Ekroni: nítorí tí ìrètí rẹ̀ yóò ṣákì í. Gasa yóò pàdánù ọba rẹ̀, Aṣkeloni yóò sì di ahoro.
[The people in Ashkelon city] will see that [happen], and they will become very afraid. [The people in] Gaza [city] will shake because of being terrified, and [the people in Ekron city] will shake too, because they will no longer expect [to prosper]. The king of [the city of] Gaza will be killed, and [the city of] Ashkelon will be deserted.
6 Ọmọ àlè yóò sì gbé inú Aṣdodu, Èmi yóò sì gé ìgbéraga àwọn Filistini kúrò.
Foreigners will occupy Ashdod [city]. I will cause the [people in all those cities of] Philistia to no longer be proud.
7 Èmi yóò sì mu ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ kúrò ni ẹnu rẹ̀, àti àwọn ohun èèwọ̀ kúrò láàrín eyín rẹ̀: ṣùgbọ́n àwọn tó ṣẹ́kù yóò jẹ́ tí Ọlọ́run wa, wọn yóò sì jẹ baálẹ̀ ní Juda, àti Ekroni ni yóò rí bí Jebusi.
I will no longer allow them to eat [MTY] meat that still has blood in it, and I will forbid them to eat [MTY] food that I [MTY] have not allowed them to eat [because it was offered to idols]. [At that time, ] the people [in Philistia] who survive will worship me, and they will become [my people, like] the people of Judah are. The Philistine people of Ekron will also become my people like [SIM] the people of Jebus did [when they were conquered].
8 Èmi yóò sì dó yí ilẹ̀ mi ká nítorí ogun àwọn tí wọ́n ń wá ohun tí wọn yóò bàjẹ́ kiri, kò sí aninilára tí yóò bori wọn mọ́: nítorí ni ìsinsin yìí ni mo fi ojú ṣọ́ wọn.
I will protect my temple, and I will not allow any [enemy soldiers] to enter it. No [enemies] will harm my people again, because I will be watching [over my people] carefully.
9 Kún fún ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, hó ìhó ayọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu. Wò ó, ọba rẹ ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ: òdodo ni òun, ó sì ní ìgbàlà; ó ní ìrẹ̀lẹ̀, ó sì ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àní ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Rejoice very much, [you people of] Jerusalem [APO, DOU] and shout joyfully, because your king will be coming to you. He is righteous and victorious; [but he will be] gentle, and [he will be] riding on a donkey, on a young female donkey.
10 Èmi ó sì gbé kẹ̀kẹ́ kúrò ni Efraimu, àti ẹṣin ogun kúrò ni Jerusalẹmu, a ó sì ṣẹ́ ọrun ogun. Òun yóò sì kéde àlàáfíà sí àwọn kèfèrí. Ìjọba rẹ̀ yóò sì gbilẹ̀ láti Òkun dé Òkun, àti láti odò títí de òpin ayé.
I will get rid of the chariots in the Ephraim [region that are used in battles] and [all] the war horses in Jerusalem. [All] the bows used in wars will be broken. [Your king] will proclaim that he will cause things to go well and peacefully in the nations. He will rule [the area] from the [Mediterranean] Sea to the [Dead] Sea, and from the [Euphrates] River to the most distant places on the earth.
11 Ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, Èmi ó dá àwọn ìgbèkùn rẹ̀ sílẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun.
As for you [my people of Jerusalem], because of the blood [of the animals that were sacrificed to make] my agreement with you, I will free your people who were forced to go to other countries where [it was as though they were kept] in a waterless pit.
12 Ẹ padà sínú odi agbára yín, ẹ̀yin òǹdè ti o ni ìrètí: àní lónìí yìí èmi sọ pé, èmi o san án fún ọ ni ìlọ́po méjì.
[You people who were] prisoners [in those countries] who [still] confidently expect [God to help you], return to [Judah], where you will be safe. This day I declare that I will give you two blessings for [each of the troubles that you have experienced].
13 Èmi ó fa Juda le bí mo ṣe fa ọrun mi le, mo sì fi Efraimu kún un, Èmi yóò gbé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin dìde, ìwọ Sioni, sí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, ìwọ Giriki, mo ṣe ọ́ bí idà alágbára.
I will cause Judah to be like [MET] my bow, and I will cause Israel to be [like] [MET] my arrow. I will enable you young men of Jerusalem to fight against the soldiers of Greece; you will be like [SIM] a warrior’s sword.”
14 Olúwa yóò sì fi ara hàn ní orí wọn; ọfà rẹ̀ yóò sì jáde lọ bí mọ̀nàmọ́ná. Olúwa Olódùmarè yóò sì fọn ìpè, Òun yóò sì lọ nínú atẹ́gùn ìjì gúúsù.
[Some day] Yahweh will appear [in the sky] above his people, and the arrows that he shoots will be like [SIM] lightning. Yahweh [our] Lord will blow his trumpet, and he will march [fiercely] like [MET] the storms from the south.
15 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò dáàbò bò wọ́n; wọn ó sì jẹ ni run, wọn ó sì tẹ òkúta kànnàkànnà mọ́lẹ̀; wọn ó sì mu ẹ̀jẹ̀ wọn bí wáìnì, wọn ó sì kún bí ọpọ́n, wọn ó sì rin ṣinṣin bí àwọn igun pẹpẹ.
The Commander of the armies of angels will protect [his people]; [the soldiers of Judah] will attack and defeat [their enemies who attack them] using slingshots. [Those soldiers of Judah] will drink and celebrate and shout like [SIM] people who are drunk; they will be as full [of wine] as the bowl that holds [the blood of the animals that are sacrificed] and [which is then] sprinkled on the corners of the altar.
16 Olúwa Ọlọ́run wọn yóò sì gbà wọ́n là ni ọjọ́ náà bí agbo ènìyàn rẹ̀: nítorí wọn ó dàbí àwọn òkúta adé, tí a gbé sókè bí àmì lórí ilẹ̀ rẹ̀.
On that day, Yahweh our God will save his people [like a shepherd saves] his flock [of sheep from danger]. In their land, they will be like [SIM] jewels that sparkle on a crown.
17 Nítorí oore rẹ̀ tí tóbi tó, ẹwà rẹ̀ sì tí pọ̀! Ọkà yóò mú ọ̀dọ́mọkùnrin dárayá, àti ọtí wáìnì tuntun yóò mú àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.
They will be delightful and beautiful. The young men will become strong from [eating] grain, and the young women will [become strong] from [drinking] new wine.

< Zechariah 9 >