< Zechariah 8 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun si tún tọ́ mí wá.
Ponovno je prišla k meni beseda Gospoda nad bojevniki, rekoč:
2 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Owú ńlá ńlá ni mo jẹ fún Sioni, pẹ̀lú ìbínú ńlá ńlá ni mo fi jowú fún un.”
»Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Z velikim ljubosumjem sem bil ljubosumen zaradi Siona in zaradi njega sem bil ljubosumen s silno razjarjenostjo.‹
3 Báyìí ni Olúwa wí, “Mo yípadà sí Sioni èmi ó sì gbé àárín Jerusalẹmu. Nígbà náà ni a ó sì pé Jerusalẹmu ni ìlú ńlá òtítọ́; àti òkè ńlá Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni a ó pè ní òkè ńlá mímọ́.”
Tako govori Gospod: ›Vrnem se k Sionu in prebival bom v sredi Jeruzalema in Jeruzalem bo imenovan mesto resnice in gora Gospoda nad bojevniki sveta gora.‹
4 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Arúgbó ọkùnrin, àti arúgbó obìnrin, yóò gbé ìgboro Jerusalẹmu, àti olúkúlùkù pẹ̀lú ọ̀pá ni ọwọ́ rẹ̀ fún ogbó.
Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Še bodo starci in starke prebivali na ulicah Jeruzalema in vsak mož s svojo palico v svoji roki zaradi visoke starosti.
5 Ìgboro ìlú yóò sì kún fún ọmọdékùnrin, àti ọmọdébìnrin, tí ń ṣiré ní ìta wọn.”
Ulice mesta bodo polne fantov in deklet, ki se bodo igrali na ulicah le-tega.‹
6 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Bí ó bá ṣe ìyanu ní ojú ìyókù àwọn ènìyàn yìí ni ọjọ́ wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó ha lè jẹ́ ìyanu ni ojú mi bí?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Če je to čudovito v očeh preostanka tega ljudstva v tistih dneh, mar ne bi bilo čudovito tudi v mojih očeh?‹ govori Gospod nad bojevniki.
7 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Kíyèsi i, èmi ó gba àwọn ènìyàn mi kúrò ni ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti kúrò ni ilẹ̀ ìwọ̀-oòrùn.
Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Glej, rešil bom svoje ljudstvo iz vzhodne dežele in iz zahodne dežele
8 Èmi ó sì mú wọn padà wá, wọn ó sì máa gbé àárín Jerusalẹmu. Wọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ní òtítọ́, àti ní òdodo.”
in privedel jih bom in prebivali bodo v sredi Jeruzalema. In oni bodo moje ljudstvo in jaz bom njihov Bog v resnici in v pravičnosti.‹
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Jẹ́ kí ọwọ́ yín le ẹ̀yin ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ọjọ́ wọ̀nyí ni ẹnu àwọn wòlíì tí ó wà ni ọjọ́ tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun lélẹ̀, jẹ́ ki ọwọ́ rẹ̀ le kí a bá lè kọ́ tẹmpili.
Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Naj bodo vaše roke močne, vi, ki v teh dneh slišite te besede po ustih prerokov, ki so bili na dan, ko je bil položen temelj hiše Gospoda nad bojevniki, da bi bil tempelj lahko zgrajen.
10 Nítorí pé, ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, owó ọ̀yà ènìyàn kò tó nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀yà ẹran pẹ̀lú, bẹ́ẹ̀ ni kò sí àlàáfíà fún ẹni ń jáde lọ, tàbí ẹni ti ń wọlé bọ, nítorí ìpọ́njú náà: nítorí mo dojú gbogbo ènìyàn, olúkúlùkù kọ aládùúgbò rẹ̀.
Kajti pred temi dnevi ni bilo plačila za moža niti kateregakoli plačila za žival; niti zaradi stiske ni bilo nobenega miru tistemu, ki je odhajal ali prihajal, kajti vse ljudi sem naravnal, vsakega zoper svojega soseda.
11 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí èmi kì yóò ṣè sí ìyókù àwọn ènìyàn yìí gẹ́gẹ́ bí tí ìgbà àtijọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Toda sedaj preostanku tega ljudstva ne bom kakor v prejšnjih dneh, ‹ govori Gospod nad bojevniki.
12 “Nítorí irúgbìn yóò gbilẹ̀, àjàrà yóò ṣo èso rẹ̀, ilẹ̀ yóò sì hu ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan rẹ̀ jáde, àwọn ọ̀run yóò sì mu ìrì wọn wá; èmi ó sì mu kí èyí jẹ ogún ìní àwọn ìyókù ènìyàn yìí ni gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
›Kajti seme bo uspešno; trta bo dajala svoj sad in tla bodo dajala svoj prirastek in nebo bo dajalo svojo roso. In preostanku tega ljudstva bom povzročil, da vzamejo v last vse te stvari.
13 Yóò sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí jẹ́ ègún láàrín àwọn kèfèrí, ẹ̀yin ilé Juda, àti ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó gbà yín sílẹ̀; ẹ̀yin o sì jẹ́ ìbùkún, ẹ má bẹ̀rù, ṣùgbọ́n jẹ́ ki ọwọ́ yín le.”
In zgodilo se bo, da kakor ste bili prekletstvo med pogani, oh hiša Judova in hiša Izraelova, tako vas bom rešil in boste blagoslov. Ne bojte se, temveč naj bodo vaše roke močne.
14 Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Gẹ́gẹ́ bí mo ti rò láti ṣe yín níbi nígbà tí àwọn baba yín mú mi bínú,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, tí èmi kò sì ronúpìwàdà.
Kajti tako govori Gospod nad bojevniki: ›Kakor sem vas mislil kaznovati, ko so me vaši očetje dražili do besa, ‹ govori Gospod nad bojevniki in se nisem pokesal,
15 “Bẹ́ẹ̀ ni èmi sì ti ro ọjọ́ wọ̀nyí láti ṣe rere fún Jerusalẹmu, àti fún ilé Juda: ẹ má bẹ̀rù.
tako sem v teh dneh ponovno mislil, da storim dobro Jeruzalemu in Judovi hiši. Ne bojte se.
16 Wọ̀nyí ni nǹkan tí ẹ̀yin ó ṣe: ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́; ṣe ìdájọ́ tòótọ́ àti àlàáfíà ní àwọn ibodè yín.
To so stvari, ki jih boste storili: ›Govorite vsak človek resnico svojemu sosedu; izvršujte sodbo resnice in miru v svojih velikih vratih
17 Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ro ibi ni ọkàn rẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀; ẹ má fẹ́ ìbúra èké; nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo kórìíra,” ni Olúwa wí.
in naj si nihče izmed vas v svojih srcih ne domišlja zla zoper svojega soseda in ne ljubite krive prisege, kajti vse to so stvari, ki jih sovražim, ‹ govori Gospod.«
18 Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun sì tọ mi wá wí pé.
Prišla mi je beseda Gospoda nad bojevniki, rekoč:
19 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwẹ̀ oṣù kẹrin, karùn-ún, keje, àti tí ẹ̀kẹwàá, yóò jẹ́ ayọ̀ àti dídùn inú, àti àpéjọ àríyá fún ilé Juda; nítorí náà, ẹ fẹ́ òtítọ́ àti àlàáfíà.”
»Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Post četrtega meseca, post petega, post sedmega in post desetega bo Judovi hiši radost in veselje in vedre gostije, zato ljubite resnico in mir.‹
20 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Àwọn ènìyàn yóò sá à tún wa, àti ẹni tí yóò gbe ìlú ńlá púpọ̀.
Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Še se bo zgodilo, da bodo prihajala ljudstva in prebivalci mnogih mest
21 Àwọn ẹni tí ń gbé ìlú ńlá kan yóò lọ sí òmíràn, wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a yára lọ gbàdúrà kí a sì wá ojúrere Olúwa, àti láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi pẹ̀lú yóò sì lọ.’
in prebivalci enega mesta bodo šli k drugemu, rekoč: ›Pojdimo naglo, da molimo pred Gospodom in da iščemo Gospoda nad bojevniki.‹ ›Tudi jaz bom šel.‹«
22 Nítòótọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn àti àwọn alágbára orílẹ̀-èdè yóò wá láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní Jerusalẹmu; àti láti gbàdúrà, àti láti wá ojúrere Olúwa.”
Da, številna ljudstva in močni narodi bodo prišli, da iščejo Gospoda nad bojevniki v Jeruzalemu in da molijo pred Gospodom.
23 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àti orílẹ̀-èdè yóò dìímú, àní yóò di etí aṣọ ẹni tí i ṣe Júù mú, wí pé, ‘Àwa yóò ba ọ lọ, nítorí àwa tí gbọ́ pé, Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.’”
Tako govori Gospod nad bojevniki: »V tistih dneh se bo zgodilo, da bo deset mož iz vseh jezikov narodov prijelo tistega, ki je Jud in celo prijelo krajec njegovega oblačila, rekoč: ›Šli bomo s teboj, kajti slišali smo, da je z vami Bog.‹«

< Zechariah 8 >