< Zechariah 8 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun si tún tọ́ mí wá.
And the word of the Lord of oostis was maad to me,
2 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Owú ńlá ńlá ni mo jẹ fún Sioni, pẹ̀lú ìbínú ńlá ńlá ni mo fi jowú fún un.”
and seide, The Lord of oostis seith these thingis, Y hatide Sion with greet feruour, and with greet indignacioun Y hatide it.
3 Báyìí ni Olúwa wí, “Mo yípadà sí Sioni èmi ó sì gbé àárín Jerusalẹmu. Nígbà náà ni a ó sì pé Jerusalẹmu ni ìlú ńlá òtítọ́; àti òkè ńlá Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ni a ó pè ní òkè ńlá mímọ́.”
The Lord of oostis seith these thingis, Y am turned ayen to Sion, and Y schal dwelle in the myddil of Jerusalem; and Jerusalem schal be clepid a citee of treuthe, and hil of the Lord schal be clepid an hil halewid.
4 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Arúgbó ọkùnrin, àti arúgbó obìnrin, yóò gbé ìgboro Jerusalẹmu, àti olúkúlùkù pẹ̀lú ọ̀pá ni ọwọ́ rẹ̀ fún ogbó.
The Lord of oostis seith these thingis, Yit elde men and elde wymmen schulen dwelle in the stretis of Jerusalem, and the staf of man in his hond, for the multitude of yeeris.
5 Ìgboro ìlú yóò sì kún fún ọmọdékùnrin, àti ọmọdébìnrin, tí ń ṣiré ní ìta wọn.”
And the stretis of the cite schulen be fillid with `yonge children and maidens, pleiynge in the stretis `of it.
6 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Bí ó bá ṣe ìyanu ní ojú ìyókù àwọn ènìyàn yìí ni ọjọ́ wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó ha lè jẹ́ ìyanu ni ojú mi bí?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
The Lord of oostis seith these thingis, Though it schal be seyn hard bifor the iyen of relifs of this puple in tho daies, whether bifor myn iyen it schal be hard, seith the Lord of oostis?
7 Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Kíyèsi i, èmi ó gba àwọn ènìyàn mi kúrò ni ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti kúrò ni ilẹ̀ ìwọ̀-oòrùn.
The Lord of oostis seith these thingis, Lo! Y schal saue my puple fro the lond of the eest, and fro lond of goynge doun of the sunne;
8 Èmi ó sì mú wọn padà wá, wọn ó sì máa gbé àárín Jerusalẹmu. Wọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ní òtítọ́, àti ní òdodo.”
and Y schal brynge hem, and thei schulen dwelle in the myddil of Jerusalem; and thei schulen be to me in to a puple, and Y schal be to hem in to God, and in treuthe, and in riytwisnesse.
9 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Jẹ́ kí ọwọ́ yín le ẹ̀yin ti ń gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní ọjọ́ wọ̀nyí ni ẹnu àwọn wòlíì tí ó wà ni ọjọ́ tí a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun lélẹ̀, jẹ́ ki ọwọ́ rẹ̀ le kí a bá lè kọ́ tẹmpili.
The Lord of oostis seith these thingis, Be youre hondis coumfortid, whiche heren in these daies these wordis bi the mouth of profetis, in the dai in which the hous of the Lord of oostis is foundid, that the temple schulde be bildid.
10 Nítorí pé, ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, owó ọ̀yà ènìyàn kò tó nǹkan, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀yà ẹran pẹ̀lú, bẹ́ẹ̀ ni kò sí àlàáfíà fún ẹni ń jáde lọ, tàbí ẹni ti ń wọlé bọ, nítorí ìpọ́njú náà: nítorí mo dojú gbogbo ènìyàn, olúkúlùkù kọ aládùúgbò rẹ̀.
Sotheli bifore tho daies hire of men was not, nether hire of werk beestis was, nether to man entrynge and goynge out was pees for tribulacioun; and Y lefte alle men, ech ayens his neiybore.
11 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí èmi kì yóò ṣè sí ìyókù àwọn ènìyàn yìí gẹ́gẹ́ bí tí ìgbà àtijọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
But now not after the formere daies Y schal do to relifs of this puple, seith the Lord of oostis,
12 “Nítorí irúgbìn yóò gbilẹ̀, àjàrà yóò ṣo èso rẹ̀, ilẹ̀ yóò sì hu ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan rẹ̀ jáde, àwọn ọ̀run yóò sì mu ìrì wọn wá; èmi ó sì mu kí èyí jẹ ogún ìní àwọn ìyókù ènìyàn yìí ni gbogbo nǹkan wọ̀nyí.
but seed of pees schal be; vyneyerd schal yyue his fruyt, and erthe schal yyue his buriownyng, and heuenes schulen yyue her dew; and Y schal make the relifs of this puple for to welde alle these thingis.
13 Yóò sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí jẹ́ ègún láàrín àwọn kèfèrí, ẹ̀yin ilé Juda, àti ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó gbà yín sílẹ̀; ẹ̀yin o sì jẹ́ ìbùkún, ẹ má bẹ̀rù, ṣùgbọ́n jẹ́ ki ọwọ́ yín le.”
And it schal be, as the hous of Juda and hous of Israel weren cursyng in hethene men, so Y schal saue you, and ye schulen be blessyng. Nyle ye drede, be youre hondis coumfortid;
14 Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Gẹ́gẹ́ bí mo ti rò láti ṣe yín níbi nígbà tí àwọn baba yín mú mi bínú,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, tí èmi kò sì ronúpìwàdà.
for the Lord of oostis seith these thingis, As Y thouyte for to turmente you, whanne youre fadris hadden terrid me to wraththe,
15 “Bẹ́ẹ̀ ni èmi sì ti ro ọjọ́ wọ̀nyí láti ṣe rere fún Jerusalẹmu, àti fún ilé Juda: ẹ má bẹ̀rù.
seith the Lord, and Y hadde not merci, so Y conuertid thouyte in these daies for to do wel to the hous of Juda and Jerusalem; nyle ye drede.
16 Wọ̀nyí ni nǹkan tí ẹ̀yin ó ṣe: ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́; ṣe ìdájọ́ tòótọ́ àti àlàáfíà ní àwọn ibodè yín.
Therfor these ben the wordis whiche ye schulen do; speke ye treuthe, ech man with his neiybore; deme ye treuthe and dom of pees in youre yatis;
17 Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ro ibi ni ọkàn rẹ̀ sí ẹnìkejì rẹ̀; ẹ má fẹ́ ìbúra èké; nítorí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni mo kórìíra,” ni Olúwa wí.
and thenke ye not in youre hertis, ony man yuel ayens his frend, and loue ye not a fals ooth; for alle thes thingis it ben, whiche Y hate, seith the Lord.
18 Ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun sì tọ mi wá wí pé.
And the word of the Lord of oostis was maad to me,
19 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwẹ̀ oṣù kẹrin, karùn-ún, keje, àti tí ẹ̀kẹwàá, yóò jẹ́ ayọ̀ àti dídùn inú, àti àpéjọ àríyá fún ilé Juda; nítorí náà, ẹ fẹ́ òtítọ́ àti àlàáfíà.”
and seide, The Lord of oostis seith these thingis, Fastyng of the fourthe monethe, `and fastyng of the fyuethe, and fastyng of the seuenthe, and fasting of the tenthe, schal be to the hous of Juda in to ioie and gladnes, and in to solempnitees ful cleer; loue ye oneli treuthe and pees.
20 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Àwọn ènìyàn yóò sá à tún wa, àti ẹni tí yóò gbe ìlú ńlá púpọ̀.
The Lord of oostis seith these thingis, Puplis schulen come on ech side, and dwelle in many citees;
21 Àwọn ẹni tí ń gbé ìlú ńlá kan yóò lọ sí òmíràn, wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a yára lọ gbàdúrà kí a sì wá ojúrere Olúwa, àti láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi pẹ̀lú yóò sì lọ.’
and the dwelleris schulen go, oon to an other, and seie, Go we, and biseche the face of the Lord, and seke we the Lord of oostis; also I shal go.
22 Nítòótọ́, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn àti àwọn alágbára orílẹ̀-èdè yóò wá láti wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní Jerusalẹmu; àti láti gbàdúrà, àti láti wá ojúrere Olúwa.”
And many puplis schulen come, and strong folkis, for to seke the Lord of oostis in Jerusalem, and for to biseche the face of the Lord.
23 Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni ọkùnrin mẹ́wàá láti inú gbogbo èdè àti orílẹ̀-èdè yóò dìímú, àní yóò di etí aṣọ ẹni tí i ṣe Júù mú, wí pé, ‘Àwa yóò ba ọ lọ, nítorí àwa tí gbọ́ pé, Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ.’”
The Lord of oostis seith these thingis, In tho daies, in whiche ten men of alle langagis of hethene men schulen catche, and thei schulen catche the hemme of a man Jew, and seye, We schulen go with you; for we han herd, that God is with you.

< Zechariah 8 >