< Zechariah 7 >

1 Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dariusi ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekariah wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kisleu tí ń ṣe oṣù kẹsànán.
Pripetilo se je v četrtem letu kralja Dareja, da je Gospodova beseda prišla Zahariju na četrti dan devetega meseca, torej v kislévu,
2 Nígbà tí wọ́n ènìyàn Beteli rán Ṣareseri àti Regemmeleki, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojúrere Olúwa.
ko so poslali v Božjo hišo Sarécerja in Regem Meleha in njune može, da molijo pred Gospodom
3 Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù karùn-ún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
in da govorijo duhovnikom, ki so bili v hiši Gospoda nad bojevniki in prerokom, rekoč: »Ali naj bi jokal v petem mesecu in se zadrževal, kot sem to počel ta mnoga leta?«
4 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,
Potem je prišla k meni beseda Gospoda nad bojevniki, rekoč:
5 “Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùn-ún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin ha ń gbààwẹ̀ yín fún?
»Govori vsemu ljudstvu dežele in duhovnikom, rekoč: ›Ko ste se postili in žalovali v petem in sedmem mesecu, celo teh sedemdeset let, ali ste se sploh postili meni, celó zame?
6 Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?
In ko ste jedli in ko ste pili, mar niste jedli zase in pili zase?
7 Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jerusalẹmu, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’”
Mar naj ne bi slišali besed, ki jih je Gospod klical po prejšnjih prerokih, ko je bil Jeruzalem naseljen in v uspevanju in njegova mesta okoli njega, ko so ljudje naseljevali jug in ravnino?‹«
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekariah wá, wí pé,
Gospodova beseda je prišla Zahariju, rekoč:
9 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti ìyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.
»Tako govori Gospod nad bojevniki, rekoč: ›Izvajajte resnično sodbo in izkazujte usmiljenje in sočutja vsakdo svojemu bratu,
10 Má sì ṣe ni opó lára tàbí aláìní baba, àlejò, tàbí tálákà; kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ṣe gbèrò ibi ní ọkàn sí arákùnrin rẹ̀.’
in ne stiskajte vdove, niti osirotelega, niti tujca, niti revnega, in naj si nihče izmed vas v svojem srcu ne domišlja zla zoper svojega brata.
11 “Ṣùgbọ́n wọ́n kọ̀ láti gbọ́, wọ́n sì gún èjìká, wọ́n sì pa ẹ̀yìn dà, wọ́n di etí wọn, kí wọn má ba à gbọ́.
Toda zavrnili so, da bi prisluhnili in odmaknili so ramo in si zamašili svoja ušesa, da ne bi slišali.
12 Wọ́n sé ọkàn wọn bí òkúta líle, kí wọn má ba à gbọ́ òfin, àti ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fi ẹ̀mí rẹ̀ rán nípa ọwọ́ àwọn wòlíì ìṣáájú wá. Ìbínú ńlá sì dé láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Da, svoja srca so naredili kakor diamantni kamen, da ne bi slišali postave in besed, ki jih je Gospod nad bojevniki poslal po svojem duhu po prejšnjih prerokih, zato je prišel velik bes od Gospoda nad bojevniki.
13 “‘Ó sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ó ti kígbe, tí wọn kò sì fẹ́ gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kígbe, tí èmi kò sì fẹ́ gbọ́,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Zato se je zgodilo, da kakor je on klical in niso hoteli slišati, tako so klicali in nisem hotel slišati, « govori Gospod nad bojevniki,
14 ‘Mo sì fi ìjì tú wọn ká sí gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀. Ilẹ̀ náà sì dahoro lẹ́yìn wọn, tí ẹnikẹ́ni kò là á kọjá tàbí kí ó padà bọ̀, wọ́n sì sọ ilẹ̀ ààyò náà dahoro.’”
»temveč sem jih z vrtinčastim vetrom razkropil med vse narode, ki jih niso poznali. Tako je bila dežela za njimi zapuščena, da noben človek ni šel skoznjo niti se ni vrnil, kajti prijetno deželo so spremenili v opustošeno.«

< Zechariah 7 >