< Zechariah 7 >

1 Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dariusi ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekariah wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kisleu tí ń ṣe oṣù kẹsànán.
Şi s-a întâmplat că, în anul al patrulea al împăratului Darius, cuvântul DOMNULUI a venit la Zaharia, în ziua a patra a lunii a noua, în luna Chislev,
2 Nígbà tí wọ́n ènìyàn Beteli rán Ṣareseri àti Regemmeleki, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojúrere Olúwa.
Când ei trimiseseră la casa lui Dumnezeu pe Şareţer şi pe Reghem-Melec şi pe oamenii lor, pentru a se ruga înaintea DOMNULUI;
3 Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù karùn-ún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
Şi să vorbească preoţilor, care erau în casa DOMNULUI oştirilor, şi profeţilor, spunând: Să plâng în luna a cincea, punându-mă deoparte, precum am făcut aceşti atât de mulţi ani?
4 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,
Atunci cuvântul DOMNULUI oştirilor a venit la mine, spunând:
5 “Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùn-ún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin ha ń gbààwẹ̀ yín fún?
Vorbeşte întregului popor al ţării şi preoţilor, spunând: Când aţi postit şi aţi jelit în luna a cincea şi în luna a şaptea, în aceşti şaptezeci de ani, cu adevărat aţi postit pentru mine, chiar pentru mine?
6 Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?
Şi când aţi mâncat şi aţi băut, nu aţi mâncat şi nu aţi băut pentru voi înşivă?
7 Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jerusalẹmu, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’”
Nu trebuia să auziţi cuvintele pe care DOMNUL le-a strigat prin profeţii dinainte, când Ierusalimul era locuit şi în prosperitate, şi cetăţile lui de jur împrejurul lui, când oamenii locuiau partea de sud şi câmpia?
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekariah wá, wí pé,
Şi cuvântul DOMNULUI a venit la Zaharia, spunând:
9 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti ìyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.
Astfel vorbeşte DOMNUL oştirilor, spunând: Faceţi judecată adevărată şi arătaţi milă şi mângâieri, fiecare om fratelui său;
10 Má sì ṣe ni opó lára tàbí aláìní baba, àlejò, tàbí tálákà; kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ṣe gbèrò ibi ní ọkàn sí arákùnrin rẹ̀.’
Şi nu oprimaţi nici pe văduvă, nici pe cel fără tată, nici pe străin, nici pe cel sărac; şi nimeni dintre voi să nu îşi închipuie răul în inima sa, împotriva fratelui său.
11 “Ṣùgbọ́n wọ́n kọ̀ láti gbọ́, wọ́n sì gún èjìká, wọ́n sì pa ẹ̀yìn dà, wọ́n di etí wọn, kí wọn má ba à gbọ́.
Dar ei au refuzat să dea ascultare şi şi-au tras umărul şi şi-au astupat urechile, ca să nu audă.
12 Wọ́n sé ọkàn wọn bí òkúta líle, kí wọn má ba à gbọ́ òfin, àti ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fi ẹ̀mí rẹ̀ rán nípa ọwọ́ àwọn wòlíì ìṣáájú wá. Ìbínú ńlá sì dé láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Da, şi-au făcut inima ca o piatră de diamant, ca nu cumva să asculte legea şi cuvintele pe care DOMNUL oştirilor le-a trimis în duhul său, prin profeţii dinainte; de aceea a venit o mare furie de la DOMNUL oştirilor.
13 “‘Ó sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ó ti kígbe, tí wọn kò sì fẹ́ gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kígbe, tí èmi kò sì fẹ́ gbọ́,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
De aceea s-a întâmplat că, pe când el striga totuşi ei au refuzat să audă; tot astfel, ei au strigat şi eu am refuzat să aud, spune DOMNUL oştirilor;
14 ‘Mo sì fi ìjì tú wọn ká sí gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀. Ilẹ̀ náà sì dahoro lẹ́yìn wọn, tí ẹnikẹ́ni kò là á kọjá tàbí kí ó padà bọ̀, wọ́n sì sọ ilẹ̀ ààyò náà dahoro.’”
Ci i-am împrăştiat cu un vârtej de vânt printre toate naţiunile pe care nu le cunoşteau. Astfel ţara a fost pustie după ei, încât nimeni nu trecea prin ea, nici nu se întorcea din ea; fiindcă ei au pustiit ţara cea plăcută.

< Zechariah 7 >