< Zechariah 7 >

1 Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dariusi ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekariah wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kisleu tí ń ṣe oṣù kẹsànán.
Potem stało się roku czwartego Daryjusza króla, stało się słowo Pańskie do Zacharyjasza dnia czwartego, miesiąca dziewiątego, który jest Kislew;
2 Nígbà tí wọ́n ènìyàn Beteli rán Ṣareseri àti Regemmeleki, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojúrere Olúwa.
Gdy posłał lud do domu Bożego Sarassara i Regiemmelecha, i mężów jego, aby się modlili przed obliczem Pańskiem;
3 Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù karùn-ún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
I aby mówili do kapłanów, którzy byli w domu Pana zastępów, także i do proroków, mówiąc: Izali jeszcze płakać będę miesiąca piątego, wyłączywszy się tak, jakom już czynił przez kilka lat?
4 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,
I stało się słowo Pana zastępów do mnie, mówiąc:
5 “Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùn-ún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin ha ń gbààwẹ̀ yín fún?
Rzecz do wszystkiego ludu tej ziemi, i do kapłanów, mówiąc: Gdyście pościli i płakali piątego i siódmego miesiąca przez te siedmdziesiąt lat, izażeście mnie, mnie, mówię, post pościli?
6 Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?
A gdy jecie albo pijecie, izali nie sobie jecie i nie sobie pijecie?
7 Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jerusalẹmu, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’”
Izaliście nie tak czynić mieli według słowa, które przepowiedział Pan przez proroków przeszłych, gdy jeszcze Jeruzalem bezpieczeństwa i pokoju używało, i miasta jego około niego, i lud w stronie południowej i po polach mieszkał (w pokoju?)
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekariah wá, wí pé,
I stało się słowo Pańskie do Zacharyjasza, mówiąc:
9 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti ìyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.
Tak powiedział Pan zastępów, mówiąc: Sprawiedliwie sądźcie, a miłosierdzie i litość pokazujcie każdy nad bliźnim swoim;
10 Má sì ṣe ni opó lára tàbí aláìní baba, àlejò, tàbí tálákà; kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ṣe gbèrò ibi ní ọkàn sí arákùnrin rẹ̀.’
A wdowy i sieroty, i przychodnia, i ubogiego nie uciskajcie, i złego jeden przeciwko drugiemu nie myślcie w sercu swojem.
11 “Ṣùgbọ́n wọ́n kọ̀ láti gbọ́, wọ́n sì gún èjìká, wọ́n sì pa ẹ̀yìn dà, wọ́n di etí wọn, kí wọn má ba à gbọ́.
Ale nie chcieli dbać; i obrócili się tyłem, a uszy swe zatulili, aby nie słuchali.
12 Wọ́n sé ọkàn wọn bí òkúta líle, kí wọn má ba à gbọ́ òfin, àti ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fi ẹ̀mí rẹ̀ rán nípa ọwọ́ àwọn wòlíì ìṣáájú wá. Ìbínú ńlá sì dé láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Serca też swe zatwardzili jako dyjament, aby nie słuchali zakonu tego i słów, które posyłał Pan zastępów duchem swoim przez proroków przeszłych, skąd przyszedł wielki gniew od Pana zastępów.
13 “‘Ó sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ó ti kígbe, tí wọn kò sì fẹ́ gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kígbe, tí èmi kò sì fẹ́ gbọ́,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Bo jako oni, gdy ich wołano, nie słuchali, tak też, gdy oni wołali, nie wysłuchałem, mówi Pan zastępów.
14 ‘Mo sì fi ìjì tú wọn ká sí gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀. Ilẹ̀ náà sì dahoro lẹ́yìn wọn, tí ẹnikẹ́ni kò là á kọjá tàbí kí ó padà bọ̀, wọ́n sì sọ ilẹ̀ ààyò náà dahoro.’”
I rozproszyłem ich jako wicher między wszystkie narody, które nie znali, i ta ziemia spustoszała po nich, tak, że nie był przechodzący i wracający się, a tak ziemię pożądaną w spustoszenie obrócili.

< Zechariah 7 >