< Zechariah 7 >
1 Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dariusi ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekariah wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kisleu tí ń ṣe oṣù kẹsànán.
Történt Darjáves királynak negyedik évében, lett az Örökkévaló igéje Zekarjához, a kilenczedik hónap negyedikén: Kiszlévben.
2 Nígbà tí wọ́n ènìyàn Beteli rán Ṣareseri àti Regemmeleki, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojúrere Olúwa.
Küldte ugyanis Bét-Él Saréczert és Régem-Mélekhet meg embereit, hogy könyörögjenek az Örökkévalóhoz,
3 Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù karùn-ún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
hogy szóljanak az Örökkévaló, a seregek ura házához való papokhoz meg a prófétákhoz, mondván: Vajon sírjak-e az ötödik hónapban, megtartózkodással, amint tettem immár annyi év óta?
4 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,
Akkor lett hozzám az Örökkévalónak, a seregek urának igéje, mondván:
5 “Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùn-ún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin ha ń gbààwẹ̀ yín fún?
Szólj az ország egész népéhez és a papokhoz, mondván: Midőn böjtöltök és gyászt tartotok az ötödik és hetedik hóban – és pedig már hetven év óta – vajon nékem böjtöltök-e böjtölve?
6 Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?
S midőn esztek és midőn isztok, nemde ti vagytok az evők, és ti az ivók?
7 Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jerusalẹmu, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’”
Nemde tudjátok azon szavakat, melyeket hirdetett az Örökkévaló, az előbbi próféták által, mikor Jeruzsálem lakva volt és jólétben, meg városai körülötte, a Délvidék s az Alföld is lakva volt!
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekariah wá, wí pé,
És lett az Örökkévaló igéje Zekarjához, mondván:
9 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti ìyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.
Így szól az Örökkévaló, a seregek ura, mondván: Igaz ítélettel ítéljetek, s szeretetet és irgalmat míveljetek kiki testvérével.
10 Má sì ṣe ni opó lára tàbí aláìní baba, àlejò, tàbí tálákà; kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ṣe gbèrò ibi ní ọkàn sí arákùnrin rẹ̀.’
Özvegyet és árvát, jövevényt és szegényt ne fosztogassatok, és rosszat senki a testvére ellen ne gondoljatok ki szívetekben.
11 “Ṣùgbọ́n wọ́n kọ̀ láti gbọ́, wọ́n sì gún èjìká, wọ́n sì pa ẹ̀yìn dà, wọ́n di etí wọn, kí wọn má ba à gbọ́.
De vonakodtak figyelni, makacs vállat mutattak és füleiket megnehezítették, úgy hogy nem hallottak;
12 Wọ́n sé ọkàn wọn bí òkúta líle, kí wọn má ba à gbọ́ òfin, àti ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fi ẹ̀mí rẹ̀ rán nípa ọwọ́ àwọn wòlíì ìṣáájú wá. Ìbínú ńlá sì dé láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
szívöket pedig gyémánttá tették, úgy hogy nem hallották a tant és a szavakat, melyeket küldött az Örökkévaló, a seregek ura az ő szellemével, az előbbi próféták által; és lett nagy harag az Örökkévaló, a seregek ura részéről.
13 “‘Ó sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ó ti kígbe, tí wọn kò sì fẹ́ gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kígbe, tí èmi kò sì fẹ́ gbọ́,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
És volt, valamint szólította, de nem hallgattak rá, úgy szólítottak ők, de nem hallgattam rájuk, mondja az Örökkévaló, a seregek ura;
14 ‘Mo sì fi ìjì tú wọn ká sí gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀. Ilẹ̀ náà sì dahoro lẹ́yìn wọn, tí ẹnikẹ́ni kò là á kọjá tàbí kí ó padà bọ̀, wọ́n sì sọ ilẹ̀ ààyò náà dahoro.’”
Vihar módjára szétszórtam őket mind a nemzetekhez, amelyeket nem ismertek, az ország pedig elpusztult ő utánok, járó-kelő nélkül; így tették pusztasággá a gyönyörűséges országot.