< Zechariah 7 >

1 Ó sì ṣe ní ọdún kẹrin Dariusi ọba, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ Sekariah wá ni ọjọ́ kẹrin oṣù Kisleu tí ń ṣe oṣù kẹsànán.
Et il arriva dans la quatrième année du roi Darius, que la parole du Seigneur fut adressée à Zacharie, au quatrième jour du neuvième mois, qui est appelé Casleu.
2 Nígbà tí wọ́n ènìyàn Beteli rán Ṣareseri àti Regemmeleki, àti àwọn ènìyàn wọn sí ilé Ọlọ́run láti wá ojúrere Olúwa.
Or Sarasar et Rogommélech et les hommes qui étaient avec lui, envoyèrent à la maison de Dieu pour implorer la face du Seigneur,
3 Àti láti bá àwọn àlùfáà tí ó wà ní ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti àwọn wòlíì sọ̀rọ̀ wí pé, “Ṣé kí èmi ó sọkún ní oṣù karùn-ún kí èmi ya ara mi sọ́tọ̀, bí mo ti ń ṣe láti ọdún mélòó wọ̀nyí wá bí?”
Afin de parler aux prêtres de la maison du Seigneur des armées et aux prophètes, en leur disant: Faut-il que je pleure dans le cinquième mois, ou dois-je me sanctifier comme je l’ai déjà fait pendant beaucoup d’années?
4 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tọ̀ mí wá pé,
Et la parole du Seigneur des armées me fut adressée, disant:
5 “Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti fún àwọn àlùfáà pé, ‘Nígbà tí ẹ̀yin gbààwẹ̀, tí ẹ sì ṣọ̀fọ̀ ní oṣù karùn-ún àti keje, àní fun àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, ǹjẹ́ èmi ni ẹ̀yin ha ń gbààwẹ̀ yín fún?
Parle à tout le peuple de la terre et aux prêtres, en disant: Lorsque vous avez jeûné et pleuré dans le cinquième et le septième mois, pendant ces soixante-dix années, est-ce pour moi que vous avez jeûné?
6 Nígbà tí ẹ sì jẹ, àti nígbà tí ẹ mu, fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin jẹ, àti fún ara yín kọ́ ni ẹ̀yin mú bí?
Et lorsque vous avez mangé et que vous avez bu, n’est-ce pas pour vous que vous avez mangé et pour vous que vous avez bu?
7 Wọ̀nyí kọ́ ni ọ̀rọ̀ ti Olúwa ti kígbe láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì ìṣáájú wá, nígbà tí a ń gbé Jerusalẹmu, tí ó sì wà ní àlàáfíà, pẹ̀lú àwọn ìlú rẹ̀ tí ó yí i káàkiri, nígbà tí a ń gbé gúúsù àti pẹ̀tẹ́lẹ̀.’”
Ne sont-ce pas là les paroles qu’a dites le Seigneur par l’entremise des prophètes antérieurs, lorsque Jérusalem était encore habitée, et qu’elle était opulente, elle-même et les villes autour d’elle, et qu’au midi et dans la plaine tout était habité?
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Sekariah wá, wí pé,
Et la parole du Seigneur des armées fut adressée à Zacharie, disant:
9 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ṣe ìdájọ́ òtítọ́, kí ẹ sì ṣe àánú àti ìyọ́nú olúkúlùkù sí arákùnrin rẹ̀.
Voici ce que dit le Seigneur des armées: Jugez selon la vérité, usez de miséricorde et de clémence, chacun envers son frère.
10 Má sì ṣe ni opó lára tàbí aláìní baba, àlejò, tàbí tálákà; kí ẹnikẹ́ni nínú yín má ṣe gbèrò ibi ní ọkàn sí arákùnrin rẹ̀.’
Et n’opprimez point la veuve, ni l’orphelin, ni l’étranger, ni le pauvre; et qu’un homme ne médite pas dans son cœur le mal contre son frère.
11 “Ṣùgbọ́n wọ́n kọ̀ láti gbọ́, wọ́n sì gún èjìká, wọ́n sì pa ẹ̀yìn dà, wọ́n di etí wọn, kí wọn má ba à gbọ́.
Mais vos pères n’ont pas voulu être attentifs à ma voix, et ils ont détourné l’épaule en se retirant, et ils ont appesanti leurs oreilles pour ne pas entendre.
12 Wọ́n sé ọkàn wọn bí òkúta líle, kí wọn má ba à gbọ́ òfin, àti ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti fi ẹ̀mí rẹ̀ rán nípa ọwọ́ àwọn wòlíì ìṣáájú wá. Ìbínú ńlá sì dé láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Et leur cœur, ils l’ont rendu dur comme un diamant, pour ne pas écouter la loi et la parole que le Seigneur des armées leur envoya avec son esprit, par l’entremise de ses prophètes antérieurs; et le Seigneur des armées conçut une grande indignation.
13 “‘Ó sì ṣe, gẹ́gẹ́ bí ó ti kígbe, tí wọn kò sì fẹ́ gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kígbe, tí èmi kò sì fẹ́ gbọ́,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Or il est arrivé comme il a parlé, et ils n’ont pas écouté; ainsi ils crieront, et je ne les écouterai pas, dit le Seigneur des armées.
14 ‘Mo sì fi ìjì tú wọn ká sí gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀. Ilẹ̀ náà sì dahoro lẹ́yìn wọn, tí ẹnikẹ́ni kò là á kọjá tàbí kí ó padà bọ̀, wọ́n sì sọ ilẹ̀ ààyò náà dahoro.’”
Et je les ai dispersés dans tous les royaumes qu’ils ne connaissent pas; et leur terre a été désolée derrière eux, en sorte qu’il n’y avait personne qui y passât, et qui en revînt; et ils ont fait d’une terre délicieuse un désert.

< Zechariah 7 >