< Zechariah 6 >

1 Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
När jag sedan åter lyfte upp mina ögon, fick jag se fyra vagnar komma fram mellan två berg, och bergen voro av koppar.
2 Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
För den första vagnen voro röda hästar, för den andra vagnen svarta hästar,
3 Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
för den tredje vagnen vita hästar, och för den fjärde vagnen fläckiga hästar, starkare än de andra.
4 Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
Då tog jag till orda och frågade ängeln som talade med mig: "Vad betyda dessa, min herre?"
5 Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
Ängeln svarade och sade till mig: "Det är himmelens fyra vindar, vilka nu draga ut, sedan de hava fått träda inför hela jordens Herre.
6 Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
Vagnen med de svarta hästarna drager mot nordlandet, de vita följa efter dem, och de fläckiga draga mot sydlandet."
7 Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
Men när de som voro starkast skulle draga ut, voro de ivriga att få fara omkring på jorden. Då sade han: "Ja, I mån fara omkring på jorden." Och de foro åstad omkring på jorden.
8 Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
Därefter ropade han på mig och talade till mig och sade: "Se, genom dem som draga ut mot nordlandet skall jag släcka min vrede på nordlandet."
9 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
10 “Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
Tag emot av Heldai gåvorna från de landsflyktiga, från Tobia och Jedaja; du själv må redan samma dag gå åstad bort till Josias, Sefanjas sons, hus, dit dessa hava kommit från Babel.
11 Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
När du så har fått silver och guld, skall du därav låta göra kronor; och du skall sätta en på översteprästen Josuas, Josadaks sons, huvud.
12 Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
Och du skall säga till honom: "Så säger HERREN Sebaot: Se, där är en man som skall kallas Telningen. Under honom skall det gro, och han skall bygga upp HERRENS tempel.
13 Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
Ja, han skall bygga upp HERRENS tempel och förvärva majestät och sitta på sin tron och regera; och en präst skall han vara på sin tron; och fridens rådslag skola vara mellan båda.
14 Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
Men kronorna skola förvaras i HERRENS tempel, till en åminnelse av Helem, Tobia och Jedaja och Hen, Sefanjas son.
15 Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”
Och fjärran ifrån skall man komma och bygga på HERRENS tempel; och I skolen så förnimma att HERREN Sebaot har sänt mig till eder. Och så skall ske, om I troget hören HERRENS, eder Guds, röst."

< Zechariah 6 >