< Zechariah 6 >
1 Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
Novamente levantei os olhos, e vi, e eis que quatro carruagens saíram de entre duas montanhas; e as montanhas eram montanhas de bronze.
2 Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
Na primeira carruagem, havia cavalos vermelhos. Na segunda carruagem estavam os cavalos pretos.
3 Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
Na terceira carruagem, os cavalos brancos. Na quarta carruagem estavam os cavalos rabiscados, todos eles poderosos.
4 Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
Então perguntei ao anjo que falou comigo: “O que são estes, meu senhor?”.
5 Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
O anjo me respondeu: “Estes são os quatro ventos do céu, que saem de pé diante do Senhor de toda a terra”.
6 Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
O dos cavalos negros sai em direção ao país do norte; e os brancos saem atrás deles; e os rabiscados saem em direção ao país do sul”.
7 Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
Os fortes saíram, e procuraram ir para que pudessem caminhar para frente e para trás através da terra. Ele disse: “Dêem a volta e atravessem a terra!” Então eles andaram para frente e para trás através da terra.
8 Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
Então ele me chamou, e falou comigo, dizendo: “Eis que aqueles que vão em direção ao país do norte acalmaram meu espírito no país do norte”.
9 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
A palavra de Javé veio a mim, dizendo:
10 “Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
“Tomai deles do cativeiro, até mesmo de Heldai, de Tobias e de Jedaías; e vinde no mesmo dia, e entrei na casa de Josias, filho de Sofonias, de onde vieram da Babilônia.
11 Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
Yes, pegue prata e ouro e faça coroas, e coloque-as na cabeça de Josué, filho de Jeozadaque, o sumo sacerdote;
12 Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
e fale com ele, dizendo: 'Javé dos Exércitos diz: “Eis o homem cujo nome é o Ramo! Ele crescerá fora de seu lugar; e construirá o templo de Yahweh.
13 Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
Ele construirá o templo de Yahweh. Ele carregará a glória, e se sentará e reinará em seu trono. Ele será um sacerdote em seu trono. O conselho de paz será entre os dois.
14 Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
As coroas serão para Helem, para Tobias, para Jedaías e para Hen, filho de Sofonias, para um memorial no templo de Yahweh.
15 Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”
Aqueles que estão longe virão e construirão no templo de Iavé; e você saberá que Iavé dos Exércitos me enviou a você. Isto acontecerá, se obedecerdes diligentemente à voz de Iavé vosso Deus””.