< Zechariah 6 >

1 Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
Potem obróciwszy się podniosłem oczu swych i ujrzałem, a oto cztery wozy wychodziły z pośrodku dwóch gór, a góry one były góry miedziane.
2 Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
W pierwszym wozie były konie rydze, a w drugim wozie konie wrone (kare):
3 Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
W trzecim wozie konie białe, a w czwartym wozie były konie strokate, a wszystkie mocne.
4 Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
Tedy odpowiadając rzekłem do Anioła, który mówił zemną: Co to jest, Panie mój?
5 Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
I odpowiedział Anioł a rzekł do mnie: Te są cztery wiatry niebieskie, wychodzące z miejsca, gdzie stały, przed panującym nad wszystką ziemią.
6 Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
Konie wrone zaprzężone wychodzą do ziemi północnej, a białe wychodzą za nimi, strokate zaś wychodzą do ziemi południowej.
7 Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
Te tedy mocne konie wyszedłszy chciały iść, aby obeszły ziemię; tedy rzekł: Idźcie, a obejdźcie ziemię! I obeszły ziemię.
8 Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
A zawoławszy mię rzekł do mnie, mówiąc: Oto te, które wyszły do ziemi północnej, uspokoiły ducha mego w ziemi północnej.
9 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
10 “Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
Weźmij od tych, co byli pojmani od Cheldajego i od Tobijasza, i od Jedajasza; (a ty przyjdziesz tegoż dnia, i wnijdziesz do domu Josyjasza, syna Sofonijaszowego) którzy idą z Babilonu;
11 Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
Weźmij, mówię, srebro i złoto, a uczyń korony, a włóż je na głowę Jesuego, syna Jozedekowego, kapłana najwyższego.
12 Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
I rzecz do niego, mówiąc: Tak powiada Pan zastępów, mówiąc: Oto mąż, którego imię jest Latorośl, który z miejsca swego wyrośnie, ten wystawi kościół Panu.
13 Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
Bo ten ma wystawić kościół Panu, ten zaś przyniesie sławę, i siedzieć i panować będzie na stolicy swojej, i będzie kapłanem na stolicy swojej, a rada pokoju będzie między nimi obiema.
14 Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
A te korony zostaną Chelemowi, i Tobijaszowi, i Jedajaszowi, i Chenowi, synowi Sofonijaszowemu, na pamiątkę w kościele Pańskim.
15 Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”
Bo dalecy przyjdą, a będą budować kościół Pański; i dowiecie się, że Pan zastępów posłał mię do was; a to się stanie, jeźli pilnie słuchać będziecie głosu Pana, Boga swego.

< Zechariah 6 >