< Zechariah 6 >

1 Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
در یک رؤیای دیگر چهار ارابه دیدم که از میان دو کوه مسی بیرون آمدند.
2 Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
ارابهٔ اول به‌وسیلۀ اسبهای سرخ، ارابهٔ دوم به‌وسیلۀ اسبهای سیاه،
3 Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
ارابهٔ سوم به‌وسیله اسبهای سفید و ارابهٔ چهارم به‌وسیلۀ اسبهای ابلق کشیده می‌شدند.
4 Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
از فرشته پرسیدم: «ای سرورم، اینها چه هستند؟»
5 Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
جواب داد: «اینها چهار روح آسمانی هستند که در حضور خداوند تمامی زمین می‌ایستند و اینک برای انجام فرمان او به حرکت درآمده‌اند.
6 Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
اسبهای سیاه به طرف شمال، اسبهای سفید به طرف غرب و اسبهای ابلق به طرف جنوب خواهند رفت.»
7 Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
اسبهای قوی بیتابی می‌کردند که حرکت کنند و در سراسر زمین بگردند. خداوند فرمود: «بروید و گشت خود را آغاز کنید.» پس آنها راه افتادند و تمام زمین را گشتند.
8 Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
آنگاه خداوند مرا احضار کرد و فرمود: «آنهایی که به سرزمین شمال رفتند، حکم مرا اجرا کرده خشم مرا در آنجا فرو نشاندند.»
9 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
در پیامی دیگر خداوند به من فرمود:
10 “Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
«حلدای، طوبیا و یدعیا از طرف یهودیان تبعید شده در بابِل، هدایایی از طلا و نقره آورده‌اند. هدایا را از آنها بگیر و به خانهٔ یوشیا (پسر صفنیا) برو و با آنها تاجی بساز. سپس تاج را بر سر یهوشع (پسر یهوصادق) کاهن اعظم بگذار.
11 Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
12 Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
به او بگو که خداوند لشکرهای آسمان چنین می‌فرماید:”تو نمونه‌ای هستی از آن مردی که «شاخه» نامیده می‌شود. او از جایی که هست جوانه خواهد زد و خانهٔ خداوند را بازسازی خواهد کرد.
13 Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
اوست آنکه خانهٔ خداوند را بنا می‌کند و از شکوه پادشاهی برخوردار می‌شود. او در مقام کاهن و پادشاه حکمرانی خواهد کرد، و بین این دو مقام هماهنگی کامل خواهد بود.“
14 Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
سپس، این تاج را به عنوان هدیه‌ای از طرف حلدای، طوبیا، یدعیا و یوشیا در خانهٔ خداوند بگذار تا یادگاری باشد.»
15 Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”
مردمی که در جاهای دور دست زندگی می‌کنند، خواهند آمد و در بازسازی خانهٔ خداوند کمک خواهند کرد؛ آنگاه خواهید دانست که خداوند لشکرهای آسمان مرا نزد شما فرستاده است. این هنگامی اتفاق خواهد افتاد که شما از خداوند، خدای خویش کاملاً اطاعت کنید.

< Zechariah 6 >