< Zechariah 6 >
1 Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
Og jeg opløftede atter mine Øjne og saa, og se, fire Vogne, som gik frem imellem de to Bjerge, og Bjergene vare Kobberbjerge.
2 Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
For den første Vogn var der røde Heste, og for den anden Vogn sorte Heste,
3 Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
og for den tredje Vogn hvide Heste, og for den fjerde Vogn spraglede, stærke Heste.
4 Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
Og jeg svarede og sagde til Engelen, som talte med mig: Hvad betyde disse, min Herre?
5 Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
Og Engelen svarede og sagde til mig: Disse ere de fire Vejr under Himmelen, som gaa ud, efter at de have stillet sig frem for al Jordens Herre.
6 Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
Hvad angaar Vognen med de sorte Heste for, da gaa de ud imod Nordens Land og de hvide ere gangne ud bag efter dem, og de spraglede ere gangne ud imod Sydens Land.
7 Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
Og de stærke ere gangne ud, men de begærede at gaa hen for at vandre Jorden rundt, og han sagde: Gaar, vandrer Jorden rundt; saa vandrede de Jorden rundt.
8 Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
Da raabte han til mig og talte til mig og sagde: Se, de, som udgaa imod Nordens Land, bringe min Aand til at hvile i Nordens Land.
9 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
Og Herrens Ord kom til mig saaledes:
10 “Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
Tag af de bortførte, nemlig af Keldaj, af Tobias og Jedaja, og gaa du paa denne Dag, ja, gaa ind i Josias's, Zefanias's Søns, Hus, hvorhen de ere komne fra Babel:
11 Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
Ja, tag Sølv og Guld, og gør Kroner, og sæt dem paa Ypperstepræsten Josuas, Jozadaks Søns, Hoved;
12 Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
og sig til ham: Saa siger den Herre Zebaoth: Se, en Mand, Zemak er hans Navn; og fra sit Sted skal han skyde frem, og han skal bygge Herrens Tempel.
13 Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
Ja, han skal bygge Herrens Tempel, og han skal bære Kongeherlighed, og han skal sidde og herske paa sin Trone, og han skal være Præst paa sin Trone, og der skal være Freds Raad imellem dem begge.
14 Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
Og Kronerne skulle være for Kelem og for Tobias og for Jedaja og for Hen, Zefanias's Søn, til en Ihukommelse i Herrens Tempel.
15 Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”
Og fjerne Folk skulle komme og bygge paa Herrens Tempel, og I skulle fornemme, at den Herre Zebaoth har sendt mig til eder; og dette skal ske, dersom I flittigt ville høre Herren eders Guds Røst.