< Zechariah 6 >

1 Mo sì yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, kẹ̀kẹ́ mẹ́rin jáde wá láti àárín òkè ńlá méjì, àwọn òkè ńlá náà sì jẹ́ òkè ńlá idẹ.
И пак подигнах очите си та погледнах, и, ето четири колесници излизаха изсред две планини; и планините бяха медни,
2 Àwọn ẹṣin pupa wà ní kẹ̀kẹ́ èkínní; àti àwọn ẹṣin dúdú ní kẹ̀kẹ́ èkejì.
В първата колесница имаше червени коне, във втората колесница черни коне,
3 Àti àwọn ẹṣin funfun ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹta; àti àwọn adíkálà àti alágbára ẹṣin ní kẹ̀kẹ́ ẹ̀kẹrin.
в третата колесница бели коне, а в четвъртата колесница пъстри пепеляви коне.
4 Mo sì dáhùn, mo sì béèrè lọ́wọ́ angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni ìwọ̀nyí, olúwa mi.”
Тогава проговаряйки рекох на ангела, който говореше с мене: Какви са тия, господарю мой?
5 Angẹli náà si dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀mí mẹ́rin ti ọ̀run, tí wọn ń lọ kúrò lẹ́yìn tí wọ́n ti fi ara wọn hàn níwájú Olúwa gbogbo ayé.
И отговор ангелът ми рече: Тия са четирите небесни духове, които излизат отпред Господаря на целия свят, пред Когото са стояли.
6 Àwọn ẹṣin dúdú tí ó wà nínú rẹ̀ jáde lọ sí ilẹ̀ àríwá; àwọn funfun sì jáde lọ si ìwọ̀-oòrùn; àwọn adíkálà sì jáde lọ sí ìhà ilẹ̀ gúúsù.”
Черните коне, които са в едната колесница, излизат към северната страна, и белите излизат след тях; а пъстрите излизат към южната страна.
7 Àwọn alágbára ẹṣin sì jáde lọ, wọ́n sì ń wá ọ̀nà àti lọ kí wọn bá a lè rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ni ayé; ó sì wí pé, “Ẹ lọ, ẹ lọ rìn síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé!” Wọ́n sì rín síyìn-ín sọ́hùn-ún ní ayé.
Но пепелявите като излязоха поискаха да отидат и обходят света; и той им рече: Идете, обходете. И тъй обходиха света.
8 Nígbà náà ni ohùn kan sì ké sí mi, ó sì bá mi sọ̀rọ̀ wí pé, “Wò ó, àwọn wọ̀nyí tí ó lọ síhà ilẹ̀ àríwá ti mú ẹ̀mí mi parọ́rọ́ ni ilẹ̀ àríwá.”
Тогава извика към мене та ми говори казвайки: Виж, ония, които излизат към северната страна, успокоиха духа Ми в северната страна.
9 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
И Господното слово дойде към мене и рече:
10 “Mú nínú ìgbèkùn, nínú àwọn Heldai, tí Tobiah, àti ti Jedaiah, tí ó ti Babeli dé, kí ìwọ sì wá ní ọjọ́ kan náà, kí o sì wọ ilé Josiah ọmọ Sefaniah lọ.
От върналите се от плен, сиреч, от Хелдая, от Товия и от Иедаия, вземи та дойди в същия ден, и влез в къщата на Иосия Софониевия син, гдето дойдоха от Вавилон,
11 Kí o sì mú fàdákà àti wúrà, kí o sì fi ṣe adé púpọ̀, sì gbé wọn ka orí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
да! Вземи от тях сребро и злато, направи корони и положи ги на главата на великия свещеник Исус Иосиевият син;
12 Sì sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé, wo ọkùnrin náà ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ẹ̀ka; yóò sì yọ ẹ̀ka láti abẹ́ rẹ̀ wá, yóò si kọ́ tẹmpili Olúwa wa.
и говори му казвайки: Така говори Господ на Силите, Който казва: Ето мъжът, чието име е Отрасъл; Той ще израсте от мястото си, И ще построи храма Господен.
13 Òun ni yóò sì kọ́ tẹmpili Olúwa òun ni yóò sì wọ̀ ní ògo, yóò sì jókòó, yóò sì jẹ ọba lórí ìtẹ́ rẹ̀; òun ó sì jẹ́ àlùfáà lórí ìtẹ́ rẹ̀; ìmọ̀ àlàáfíà yóò sì wá láàrín àwọn méjèèjì.’
Да! Той ще построи храма Господен; И като приеме славата, Ще седне на престола си като управител; Ще бъде и свещеник на престола си; И съвещание за установление на мир има между двамата.
14 Adé wọ̀nyí yóò sì wà fún Helemu àti fún Tobiah, àti fún Jedaiah, àti fún Heni ọmọ Sefaniah fún ìrántí ni tẹmpili Olúwa.
И короните ще се дават на Елема, на Товия, на Иедаия и на Хена Софониевия син за спомен в Господния храм.
15 Àwọn tí ó jìnnà réré yóò wá láti kọ́ tẹmpili Olúwa, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rán mi sí yín. Yóò sì rí bẹ́ẹ̀ bí ẹ̀yin yóò bá gbà ohùn Olúwa, Ọlọ́run yín gbọ́ nítòótọ́.”
И далечните люде ще дойдат и ще градят в Господния храм; и ще познаете, че Господ на Силите ме е пратил при вас. А това ще се сбъдне ако послушате внимателно гласа на Господа вашия Бог.

< Zechariah 6 >