< Zechariah 5 >
1 Nígbà náà ni mo yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ìwé kíká ti ń fò.
Então novamente levantei meus olhos e vi, e eis que um pergaminho voador.
2 Ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Èmi sì dáhùn pé, “Mo rí ìwé kíká tí ń fò; gígùn rẹ̀ jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá.”
Ele me disse: “O que você vê?”. Respondi: “Vejo um pergaminho voador; seu comprimento é de vinte cúbitos, e sua largura de dez cúbitos”.
3 Ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ègún tí ó jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀ ayé, nítorí gbogbo àwọn tí ó bá jalè ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀; gbogbo àwọn tí ó bá sì búra èké ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀.
Então ele me disse: “Esta é a maldição que se estende sobre a superfície de toda a terra, pois todo aquele que rouba será cortado de acordo com ela de um lado; e todo aquele que jurar falsamente será cortado de acordo com ela do outro lado”.
4 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò mú un jáde, Èmi yóò si wọ inú ilé olè lọ, àti inú ilé ẹni ti o bá fi orúkọ mi búra èké, yóò si wà ni àárín ilé rẹ̀, yóò si rún pẹ̀lú igi àti òkúta inú rẹ̀.’”
Eu a farei sair”, diz Javé dos Exércitos, “e entrará na casa do ladrão, e na casa daquele que jurar falsamente pelo meu nome; e permanecerá no meio de sua casa, e a destruirá com sua madeira e suas pedras”.
5 Angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ sì jáde lọ, ó sì wí fún mi pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wo nǹkan tí yóò jáde lọ.”
Então o anjo que falou comigo se aproximou e me disse: “Levantem agora os olhos e vejam o que é isto que está aparecendo”.
6 Mo sì wí pé, “Kí ni nǹkan náà?” Ó sì wí pé, “Èyí ni òsùwọ̀n tí ó jáde lọ.” Ó sì wí pé, “Èyí ni àwòrán ní gbogbo ilẹ̀ ayé.”
Eu disse: “O que é isso?” Ele disse: “Esta é a cesta efah que está aparecendo”. Ele disse ainda: “Esta é a aparência deles em toda a terra -
7 Sì kíyèsi i, a gbé tálẹ́ǹtì òjé sókè, obìnrin kan sì nìyìí tí ó jókòó sí àárín àpẹẹrẹ òsùwọ̀n.
e eis que uma tampa de chumbo pesando um talento foi levantada - e havia uma mulher sentada no meio da cesta da efah”.
8 Ó sì wí pé, “Èyí ni ìwà búburú.” Ó sì ti sí àárín òsùwọ̀n, ó sì ju ìdérí òjé sí ẹnu rẹ̀.
Ele disse: “Isto é maldade”; e ele a jogou no meio da cesta da efah; e jogou o peso de chumbo na boca dela.
9 Mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, obìnrin méjì jáde wá, ẹ̀fúùfù sì wá nínú ìyẹ́ wọn; nítorí wọ́n ní ìyẹ́ bí ìyẹ́ àkọ̀, wọ́n sì gbé àpẹẹrẹ òsùwọ̀n náà dé àárín méjì ayé àti ọ̀run.
Então levantei os olhos e vi, e eis que havia duas mulheres; e o vento estava em suas asas. Agora elas tinham asas como as asas de uma cegonha, e levantaram a cesta efah entre a terra e o céu.
10 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Níbo ni àwọn wọ̀nyí ń gbé òsùwọ̀n náà lọ.”
Então eu disse ao anjo que falou comigo: “Onde estão estes carregando a cesta da efah?
11 Ó si wí fún mi pé, “Sí orílẹ̀-èdè Babeli láti kọ ilé fún un. Tí ó bá ṣetán, a ó sì fi ìdí rẹ̀ mulẹ̀, a o sì fi ka orí ìpìlẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.”
Ele me disse: “Para construir-lhe uma casa no terreno de Shinar”. Quando ela estiver preparada, ela será colocada lá em seu próprio lugar”.