< Zechariah 5 >

1 Nígbà náà ni mo yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ìwé kíká ti ń fò.
Potem odwróciłem się i gdy podniosłem swe oczy, spojrzałem, a oto latający zwój.
2 Ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Èmi sì dáhùn pé, “Mo rí ìwé kíká tí ń fò; gígùn rẹ̀ jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá.”
I zapytał mnie: Co widzisz? Odpowiedziałem: Widzę latający zwój, jego długość dwadzieścia łokci, a jego szerokość dziesięć łokci.
3 Ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ègún tí ó jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀ ayé, nítorí gbogbo àwọn tí ó bá jalè ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀; gbogbo àwọn tí ó bá sì búra èké ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀.
Wtedy powiedział do mnie: To [jest] przekleństwo, które wyjdzie na całą powierzchnię ziemi. Każdy złodziej bowiem zostanie wykorzeniony według [przekleństwa] z tej strony i każdy krzywoprzysięzca zostanie wykorzeniony według [przekleństwa] z drugiej strony.
4 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò mú un jáde, Èmi yóò si wọ inú ilé olè lọ, àti inú ilé ẹni ti o bá fi orúkọ mi búra èké, yóò si wà ni àárín ilé rẹ̀, yóò si rún pẹ̀lú igi àti òkúta inú rẹ̀.’”
Wyprowadzę je, mówi PAN zastępów, aby weszło do domu złodzieja i do domu tego, kto krzywo przysięga na moje imię. Pozostanie w jego domu i zniszczy go wraz z jego drewnem i kamieniem.
5 Angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ sì jáde lọ, ó sì wí fún mi pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wo nǹkan tí yóò jáde lọ.”
Wtedy wyszedł Anioł, który ze mną rozmawiał, i powiedział mi: Podnieś teraz swoje oczy i zobacz, co to jest, co wychodzi.
6 Mo sì wí pé, “Kí ni nǹkan náà?” Ó sì wí pé, “Èyí ni òsùwọ̀n tí ó jáde lọ.” Ó sì wí pé, “Èyí ni àwòrán ní gbogbo ilẹ̀ ayé.”
Zapytałem: Co to [jest]? On odpowiedział: To, co wychodzi, to efa. I dodał: Taki jest ich wygląd w całej ziemi.
7 Sì kíyèsi i, a gbé tálẹ́ǹtì òjé sókè, obìnrin kan sì nìyìí tí ó jókòó sí àárín àpẹẹrẹ òsùwọ̀n.
A oto podniósł się talent ołowiu, a przy tym była kobieta, która siedziała wewnątrz efy.
8 Ó sì wí pé, “Èyí ni ìwà búburú.” Ó sì ti sí àárín òsùwọ̀n, ó sì ju ìdérí òjé sí ẹnu rẹ̀.
Wtedy [Anioł] powiedział: To jest bezbożność. I wrzucił ją do wnętrza efy, wrzucił także do otworu efy ten talent ołowiu.
9 Mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, obìnrin méjì jáde wá, ẹ̀fúùfù sì wá nínú ìyẹ́ wọn; nítorí wọ́n ní ìyẹ́ bí ìyẹ́ àkọ̀, wọ́n sì gbé àpẹẹrẹ òsùwọ̀n náà dé àárín méjì ayé àti ọ̀run.
Potem podniosłem swoje oczy i spojrzałem, a oto wyszły dwie kobiety mające wiatr pod swoimi skrzydłami, a [ich] skrzydła przypominały skrzydła bocianie. I podniosły efę między ziemią i niebem.
10 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Níbo ni àwọn wọ̀nyí ń gbé òsùwọ̀n náà lọ.”
Wtedy zapytałem tego Anioła, który rozmawiał ze mną: Dokąd niosą [tę] efę?
11 Ó si wí fún mi pé, “Sí orílẹ̀-èdè Babeli láti kọ ilé fún un. Tí ó bá ṣetán, a ó sì fi ìdí rẹ̀ mulẹ̀, a o sì fi ka orí ìpìlẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.”
Powiedział mi: By zbudować dla niej dom w ziemi Szinear, a gdy będzie założony, postawią ją na jej [własnej] podstawie.

< Zechariah 5 >