< Zechariah 5 >

1 Nígbà náà ni mo yípadà, mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ìwé kíká ti ń fò.
A LAWA hou ae la ko'u mau maka iluna, ike aku la au, aia hoi, he owili pepa e lele ana.
2 Ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Èmi sì dáhùn pé, “Mo rí ìwé kíká tí ń fò; gígùn rẹ̀ jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́, ìbú rẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá.”
I mai la kela ia'u, Heaha kau mea ike? I aku la au, Ke ike aku nei au i ka owili pepa lele ana; he iwakalua hailima ka loa, a he umi hailima ka laula.
3 Ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ègún tí ó jáde lọ sí gbogbo ilẹ̀ ayé, nítorí gbogbo àwọn tí ó bá jalè ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀; gbogbo àwọn tí ó bá sì búra èké ni a ó ké kúrò láti ìhín lọ nípa rẹ̀.
Olelo mai la kela ia'u, Eia ka hoahewa ana e hele aku maluna o ka ili a pau o ka honua. No ka mea, o kela mea keia mea aihue, e hookiia auanei oia ma keia aoao, e like me ka keia; a o kela mea keia mea e hoohiki wahahee ana, e hookiia'e oia ma kela aoao, e like me ka kela.
4 Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò mú un jáde, Èmi yóò si wọ inú ilé olè lọ, àti inú ilé ẹni ti o bá fi orúkọ mi búra èké, yóò si wà ni àárín ilé rẹ̀, yóò si rún pẹ̀lú igi àti òkúta inú rẹ̀.’”
Ua lawe mai nei au in, wahi a Iehova o na kaua, a e komo aku ia iloko o ka hale o ka aihue, a o ka hale o ka mea e hoohiki wahahee ana ma ko'u inoa; e noho ia iloko o kona hale, a e hoopau oia ia mea me ka laau a me ka pohaku ona.
5 Angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ sì jáde lọ, ó sì wí fún mi pé, “Gbé ojú rẹ sókè nísinsin yìí, kí o sì wo nǹkan tí yóò jáde lọ.”
Alaila, hele aku la ka anela i kamailio pu me au, a i mai la ia'u, E nana ae oe iluna, a e ike i kela mea e hele aku ana.
6 Mo sì wí pé, “Kí ni nǹkan náà?” Ó sì wí pé, “Èyí ni òsùwọ̀n tí ó jáde lọ.” Ó sì wí pé, “Èyí ni àwòrán ní gbogbo ilẹ̀ ayé.”
I aku la au, Heaha ia mea? I mai la kela, He epa ia mea e hele aku ana. I mai la hoi oia, Eia ko lakou helehelena ma ka honua a pau.
7 Sì kíyèsi i, a gbé tálẹ́ǹtì òjé sókè, obìnrin kan sì nìyìí tí ó jókòó sí àárín àpẹẹrẹ òsùwọ̀n.
Aia hoi, ua kaikaiia'e he popo kepau; a o ka mea e noho ana iwaenakonu o ka epa, he wahine ia.
8 Ó sì wí pé, “Èyí ni ìwà búburú.” Ó sì ti sí àárín òsùwọ̀n, ó sì ju ìdérí òjé sí ẹnu rẹ̀.
I mai la kela, O keia ka aia. A hoolei aku la oia ia mea mawaena konu o ka epa; a hoolei iho la ia i ka pohaku kepau maluna iho o kona waha.
9 Mo sì gbé ojú mi sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, obìnrin méjì jáde wá, ẹ̀fúùfù sì wá nínú ìyẹ́ wọn; nítorí wọ́n ní ìyẹ́ bí ìyẹ́ àkọ̀, wọ́n sì gbé àpẹẹrẹ òsùwọ̀n náà dé àárín méjì ayé àti ọ̀run.
Alaila, nana ae la au iluna, ike aku la, aia hoi, puka mai la na wahine elua iwaho, a iloko o ko laua mau eheu ka makani; no ka mea, he mau eheu ia laua e like me na eheu o ka setoreka: a kaikai ae la lakou i ka epa iluna iwaena o ka honua a me ka lani.
10 Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Níbo ni àwọn wọ̀nyí ń gbé òsùwọ̀n náà lọ.”
Ninau aku la au i ka anela i kamailio me au, Mahea la laua nei e lawe aku ai i ka epa?
11 Ó si wí fún mi pé, “Sí orílẹ̀-èdè Babeli láti kọ ilé fún un. Tí ó bá ṣetán, a ó sì fi ìdí rẹ̀ mulẹ̀, a o sì fi ka orí ìpìlẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.”
I mai la kela ia'u, No ka hana i hale nona ma ka aina i Sinara; ilaila ia e hoonohoia'i, a e kau ia maluna o kona kumu.

< Zechariah 5 >