< Zechariah 4 >
1 Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ sì tún dé, ó sì jí mi, bí ọkùnrin tí a jí lójú oorun rẹ̀,
Na ka hoki mai te anahera i korero ra ki ahau, ka whakaarahia ahau, ko toku rite kei te tangata e whakaarahia ana i te moe.
2 ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Mo sì wí pé, “Mo wò, sì kíyèsi i, ọ̀pá fìtílà tí gbogbo rẹ̀ jẹ́ wúrà, pẹ̀lú àwokòtò rẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú fìtílà méje rẹ̀ lórí rẹ̀, àti ẹnu méje fún fìtílà méjèèje, tí ó wà lórí rẹ̀.
Na ka mea ia ki ahau, Ko te aha e kitea ana e koe? Ano ra ko ahau, Kua kite ahau, na, ko tetahi turanga rama, he koura katoa, me tona peihana i tona pito ki runga, ko ona rama e whitu ki runga o tera; e whitu nga korere o te rama kotahi i tona pi to ki runga;
3 Igi olifi méjì sì wà létí rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àwokòtò náà, àti èkejì ní apá òsì rẹ̀.”
Na e rua nga oriwa i tona taha, ko tetahi i te taha ki matau o te peihana, ko tetahi i tona taha maui.
4 Mo sì dáhùn mo sì wí fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀, pé, “Kín ni wọ̀nyí, olúwa mi?”
Na ka oho atu ahau, ka mea ki te anahera i korero ki ahau, ka ki atu, He aha enei, e toku ariki?
5 Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n, olúwa mi.”
Katahi te anahera i korero ra ki ahau ka oho, ka mea ki ahau, Kahore ranei koe e mohio he aha enei? Ano ra ko ahau, Kahore, e toku ariki.
6 Ó sì dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Serubbabeli tó wí pé: ‘Kì í ṣe nípa ipá, kì í ṣe nípa agbára, bí kò ṣe nípa Ẹ̀mí mi,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Na ka oho mai ia, ka korero ki ahau, ka mea, Ko te kupu tenei a Ihowa ki a Herupapera, e ki ana: Ehara i te mea ma te uaua, ma te kaha, engari ma toku wairua, e ai ta Ihowa o nga mano.
7 “Ta ni ìwọ, ìwọ òkè ńlá? Ìwọ yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀ níwájú Serubbabeli: òun yóò sì fi ariwo mú òkúta téńté orí rẹ̀ wá, yóò máa kígbe wí pé, ‘Ọlọ́run bùkún fun! Ọlọ́run bùkún fun!’”
Ko wai koe, e te maunga nui? i te aroaro o Herupapera hei papatairite koe: a ka whakaputaina mai e ia te kohatu o runga rawa, me te pa ano nga karanga, He pai, he pai mona.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
I puta mai ano te kupu a Ihowa ki ahau, i mea,
9 “Ọwọ́ Serubbabeli ni a ti ṣe ìpìlẹ̀ ilé yìí, ọwọ́ rẹ̀ ni yóò sì parí rẹ̀; ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí i yín.
Na nga ringa o Herupapera i whakatakoto te turanga mo tenei whare, ma ona ringa ano e whakaoti; a ka mohio koe na Ihowa o nga mano ahau i unga mai ki a koutou.
10 “Ṣùgbọ́n ta ni ha kẹ́gàn ọjọ́ ohun kékeré? Nítorí wọn ó yọ̀ nígbà ti wọ́n bá rí okùn ìwọ̀n nì lọ́wọ́ Serubbabeli. “(Àwọn méje wọ̀nyí ni àwọn ojú Olúwa, tí ó ń sáré síyìn-ín sọ́hùn-ún ní gbogbo ayé.)”
Ko wai oti i whakahawea ki te ra o nga mea ririki? ka koa hoki ratou, ka kite hoki i te kohatu paramu i roto i te ringa o Herupapera, ara enei e whitu nei, koia nei nga kanohi o Ihowa; e kopikopiko ana ratou i te whenua katoa.
11 Mo sì béèrè, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn igi olifi méjì wọ̀nyí jásí, tí ó wà ní apá ọ̀tún fìtílà àti ní apá òsì rẹ̀?”
Katahi ahau ka oho atu, ka mea ki a ia, He aha enei oriwa e rua i te taha ki matau o te turanga rama, i te taha hoki ki maui?
12 Mo sì tún dáhùn, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn ẹ̀ka méjì igi olifi wọ̀nyí jásí, tí ń tú òróró wúrà jáde nínú ara wọn láti ẹnu ọ̀pá oníhò wúrà méjì.”
I whakahoki atu ano ahau, he tuarua, ka mea ki a ia, He aha enei manga oriwa e rua, e rua nga korere koura i piri atu ai raua, i rere atu ai te hinu koura i roto i aua korere ra?
13 Ó sì dáhùn, ó wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa à mi.”
Katahi tera ka korero mai ki ahau, ka mea, Kahore ranei koe e mohio ko te aha enei? Ano ra ko ahau, Kahore, e toku ariki.
14 Ó sì wí pé, “Àwọn méjì wọ̀nyí ni àwọn tí a fi òróró yàn, tí ó dúró ti Olúwa gbogbo ayé.”
Na ka ki mai ia, Ko enei e rua ko nga tama a te hinu, e tu ana i te taha o te Ariki o te whenua katoa.