< Zechariah 4 >
1 Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ sì tún dé, ó sì jí mi, bí ọkùnrin tí a jí lójú oorun rẹ̀,
Nibalik’ amy zao i anjely nisaontsy amakoy le nitsekafe’e, manahake ty fampivañonañe ‘ndaty miròtse.
2 ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Mo sì wí pé, “Mo wò, sì kíyèsi i, ọ̀pá fìtílà tí gbogbo rẹ̀ jẹ́ wúrà, pẹ̀lú àwokòtò rẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú fìtílà méje rẹ̀ lórí rẹ̀, àti ẹnu méje fún fìtílà méjèèje, tí ó wà lórí rẹ̀.
Le hoe re amako, Ino o oni’oo? Le hoe ty asako: Mahatrea fitàm-pailo volamena ki’e, reketse ty korobo ambone’e eo, ama’e ty failo fito; fito ty toiô’e, eka fito mb’amy failo fito ambone’e rey;
3 Igi olifi méjì sì wà létí rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àwokòtò náà, àti èkejì ní apá òsì rẹ̀.”
naho hatae olive roe ty añ’ila’e, raike ankavana’ i koroboy, le raike ankavia’e.
4 Mo sì dáhùn mo sì wí fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀, pé, “Kín ni wọ̀nyí, olúwa mi?”
Nañontaneako i anjely nifanaontsy amakoy, ty hoe: Inoñe o reroañeo, ry talèko?
5 Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n, olúwa mi.”
Le nanoiñe ahy i anjely nifanaontsy amakoy, ami’ty hoe: Tsy apota’o hao o retiañeo? Le hoe iraho: Aiy! talèko!
6 Ó sì dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Serubbabeli tó wí pé: ‘Kì í ṣe nípa ipá, kì í ṣe nípa agbára, bí kò ṣe nípa Ẹ̀mí mi,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Le hoe ty navale’ i anjeliy amako: Ty tsara’ Iehovà amy Zerobabele, manao ty hoe: Tsy an-kafatrarañe, tsy an-kaozarañe, fa an-Troko hoe t’Iehovà’ i Màroy.
7 “Ta ni ìwọ, ìwọ òkè ńlá? Ìwọ yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀ níwájú Serubbabeli: òun yóò sì fi ariwo mú òkúta téńté orí rẹ̀ wá, yóò máa kígbe wí pé, ‘Ọlọ́run bùkún fun! Ọlọ́run bùkún fun!’”
Ia v’iheo, ry haboañe aboo? ie aolo’ i Zerobabele eo ro hinjare tane-mira? le hendese’e boak’ ao ty vato-fampikatohañe, hikoikoike ty hoe, Fañisohañe, fañisohañe.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
Nimb’ amako indraike ty tsara’ Iehovà nanao ty hoe:
9 “Ọwọ́ Serubbabeli ni a ti ṣe ìpìlẹ̀ ilé yìí, ọwọ́ rẹ̀ ni yóò sì parí rẹ̀; ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí i yín.
Nampipetake o mananta’ ty anjomba toio o fità’ i Zerobabeleo, le o fità’eo ka ro hamonitse aze; vaho ho fohi’o te nañirak’ ahy ama’ areo t’Iehovà’ i Màroy.
10 “Ṣùgbọ́n ta ni ha kẹ́gàn ọjọ́ ohun kékeré? Nítorí wọn ó yọ̀ nígbà ti wọ́n bá rí okùn ìwọ̀n nì lọ́wọ́ Serubbabeli. “(Àwọn méje wọ̀nyí ni àwọn ojú Olúwa, tí ó ń sáré síyìn-ín sọ́hùn-ún ní gbogbo ayé.)”
Ia ty nanirìka ty andron-draha pilipito’e? Ho isa’ iareo an-kafaleañe o talim-pahity am-pità’ i Zerobabeleo, toe o fito retoañe, o fihaino’ Iehovà manitsike ty tane toio mb’eo mb’eo.
11 Mo sì béèrè, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn igi olifi méjì wọ̀nyí jásí, tí ó wà ní apá ọ̀tún fìtílà àti ní apá òsì rẹ̀?”
Le nañontaneako ty hoe: Inoñ’ o hatae olive ankavana o fitàm-pailo naho ankavia’eo?
12 Mo sì tún dáhùn, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn ẹ̀ka méjì igi olifi wọ̀nyí jásí, tí ń tú òróró wúrà jáde nínú ara wọn láti ẹnu ọ̀pá oníhò wúrà méjì.”
Tinovoko fañindroe’e, ty hoe: Ino o singan’ olive roe añ’ila’ i toiò volamena roe rey, mañiliñe menake volamena boak’ ama’eo?
13 Ó sì dáhùn, ó wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa à mi.”
Natoi’e ami’ty hoe: Tsy fohi’o hao t’ie inoñe? Le hoe ty natoiko: Aiy! ry taleko.
14 Ó sì wí pé, “Àwọn méjì wọ̀nyí ni àwọn tí a fi òróró yàn, tí ó dúró ti Olúwa gbogbo ayé.”
Le hoe re tamako: Ie i roe norizañe ami'ty menake rey: ie mijohañe añ’ila’ i Talè’ ty tane toy eo.