< Zechariah 4 >

1 Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ sì tún dé, ó sì jí mi, bí ọkùnrin tí a jí lójú oorun rẹ̀,
Hĩndĩ ĩyo mũraika ũrĩa twaranagĩria nake akĩhũndũka, akĩnjarahũra, ta ũrĩa mũndũ aarahũragwo kuuma toro.
2 ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Mo sì wí pé, “Mo wò, sì kíyèsi i, ọ̀pá fìtílà tí gbogbo rẹ̀ jẹ́ wúrà, pẹ̀lú àwokòtò rẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú fìtílà méje rẹ̀ lórí rẹ̀, àti ẹnu méje fún fìtílà méjèèje, tí ó wà lórí rẹ̀.
Nake akĩnjũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ ũroona?” Na niĩ ngĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndĩrona mũtĩ wa thahabu theri wa kũigĩrĩrwo tawa, ũrĩ na mbakũri igũrũ rĩaguo, na ũigĩrĩirwo matawa mũgwanja na mĩberethi mũgwanja ya gũtwara maguta matawa-inĩ macio.
3 Igi olifi méjì sì wà létí rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àwokòtò náà, àti èkejì ní apá òsì rẹ̀.”
Ningĩ harĩ na mĩtĩ ĩĩrĩ ya mĩtamaiyũ ĩriganĩtie naguo, ũmwe ũrĩ mwena wa ũrĩo wa mbakũri, na ũrĩa ũngĩ mwena wayo wa ũmotho.”
4 Mo sì dáhùn mo sì wí fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀, pé, “Kín ni wọ̀nyí, olúwa mi?”
Ngĩũria mũraika ũrĩa twaranagĩria atĩrĩ, “Mwathi wakwa, ici nacio nĩ ndũũ?”
5 Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n, olúwa mi.”
Nake akĩnjũũria atĩrĩ, “Wee-rĩ, ndũũĩ ici nĩ ndũũ?” Na niĩ ngĩmũcookeria atĩrĩ, “Aca, Mwathi wakwa, ndiũĩ.”
6 Ó sì dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Serubbabeli tó wí pé: ‘Kì í ṣe nípa ipá, kì í ṣe nípa agbára, bí kò ṣe nípa Ẹ̀mí mi,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Nĩ ũndũ ũcio akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Ĩno nĩyo ndũmĩrĩri ya Jehova kũrĩ Zerubabeli, nayo ĩkuuga ũũ: ‘Ti ũndũ wa hinya kana wa ũhoti, no nĩ ũndũ wa Roho wakwa,’ ũguo nĩguo Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga.
7 “Ta ni ìwọ, ìwọ òkè ńlá? Ìwọ yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀ níwájú Serubbabeli: òun yóò sì fi ariwo mú òkúta téńté orí rẹ̀ wá, yóò máa kígbe wí pé, ‘Ọlọ́run bùkún fun! Ọlọ́run bùkún fun!’”
“Wee kĩrĩma gĩkĩ kĩnene-rĩ, ũkĩrĩ ũ? Ũgaatuĩka kũndũ kwaraganu mbere ya Zerubabeli. Ningĩ nĩwe ũkaarehe ihiga rĩa kũrĩĩkia mwako o gũkĩanagĩrĩrwo atĩrĩ, ‘Ngai rĩrathime! Ngai rĩrathime!’”
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
Ningĩ ndũmĩrĩri ya Jehova ĩkĩnginyĩrĩra ngĩĩrwo atĩrĩ:
9 “Ọwọ́ Serubbabeli ni a ti ṣe ìpìlẹ̀ ilé yìí, ọwọ́ rẹ̀ ni yóò sì parí rẹ̀; ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí i yín.
“Moko ma Zerubabeli nĩmo maakĩte mũthingi wa hekarũ ĩno, na moko make no mo makaamĩrĩkia. Hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩwe ũndũmĩte kũrĩ inyuĩ.
10 “Ṣùgbọ́n ta ni ha kẹ́gàn ọjọ́ ohun kékeré? Nítorí wọn ó yọ̀ nígbà ti wọ́n bá rí okùn ìwọ̀n nì lọ́wọ́ Serubbabeli. “(Àwọn méje wọ̀nyí ni àwọn ojú Olúwa, tí ó ń sáré síyìn-ín sọ́hùn-ún ní gbogbo ayé.)”
“Nũũ ũmenaga mũthenya wa kĩambĩrĩria kĩa maũndũ manini? Andũ nĩmagakena moona kabirũ karĩ guoko-inĩ gwa Zerubabeli. (Maya nĩmo maitho mũgwanja ma Jehova, marĩa moonaga thĩ yothe.)”
11 Mo sì béèrè, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn igi olifi méjì wọ̀nyí jásí, tí ó wà ní apá ọ̀tún fìtílà àti ní apá òsì rẹ̀?”
Ningĩ ngĩũria mũraika ũcio atĩrĩ, “Mĩtamaiyũ ĩno ĩĩrĩ ĩrĩ mwena wa ũrĩo na wa ũmotho wa mũtĩ wa kũigĩrĩra tawa nĩ mĩtũũ?”
12 Mo sì tún dáhùn, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn ẹ̀ka méjì igi olifi wọ̀nyí jásí, tí ń tú òróró wúrà jáde nínú ara wọn láti ẹnu ọ̀pá oníhò wúrà méjì.”
Ningĩ ngĩmũũria atĩrĩ, “Honge ici igĩrĩ cia mĩtamaiyũ irũgamanĩte na mĩberethi ĩno ya thahabu iraita maguta mahaana ta thahabu nĩ ndũũ?”
13 Ó sì dáhùn, ó wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa à mi.”
Nake agĩcookia atĩrĩ, “Wee-rĩ, ndũũĩ ici nĩ ndũũ?” Na niĩ ngiuga atĩrĩ, “Aca, Mwathi wakwa, ndiũĩ.”
14 Ó sì wí pé, “Àwọn méjì wọ̀nyí ni àwọn tí a fi òróró yàn, tí ó dúró ti Olúwa gbogbo ayé.”
Nĩ ũndũ ũcio akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Aya eerĩ nĩo maitĩrĩirio maguta nĩguo matungatage Mwathani wa thĩ yothe.”

< Zechariah 4 >