< Zechariah 3 >
1 Ó sì fi Joṣua olórí àlùfáà hàn mí, ó dúró níwájú angẹli Olúwa, Satani sí dúró lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀ láti kọjú ìjà sí i.
Then he showed me Joshua, the high priest, standing before the messenger of the Lord and the Adversary standing at his right hand to accuse him.
2 Olúwa si wí fún Satani pé, “Olúwa bá ọ wí ìwọ Satani; àní Olúwa tí ó ti yan Jerusalẹmu, bá ọ wí, igi iná kọ́ ni èyí tí a mú kúrò nínú iná?”
And the messenger of the Lord said to the Adversary, ‘May the Lord rebuke you, Adversary! The Lord, who has chosen Jerusalem, rebuke you! Is not this man a brand plucked out of the fire?’
3 A sì wọ Joṣua ni aṣọ èérí, ó sì dúró níwájú angẹli náà.
Now Joshua was clothed with filthy garments and was standing before the messenger.
4 Ó sì dáhùn ó wí fún àwọn tí ó dúró níwájú rẹ̀ pé, “Bọ́ aṣọ èérí nì kúrò ní ara rẹ̀.” Ó sì wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo mú kí àìṣedéédéé rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, èmi yóò sì wọ̀ ọ́ ní aṣọ ẹ̀yẹ.”
The messenger said to those who stood before him, ‘Take off his filthy garments.’ Then to Joshua he said, ‘I have taken your guilt from you and I will clothe you in priestly robes.’
5 Mó sì wí pé, “Jẹ kí wọn fi gèlè mímọ́ wé e lórí.” Wọn sì fi gèlè mímọ́ wé e lórí, wọn sì fi aṣọ wọ̀ ọ́. Angẹli Olúwa sì dúró tì í.
And he ordered: ‘Set a clean turban upon his head.’ So they set a clean turban on his head, and clothed him with garments. The messenger of the Lord was standing by.
6 Angẹli Olúwa sì tẹnumọ́ ọn fún Joṣua pé:
And the messenger of the Lord testified to Joshua:
7 “Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Bí ìwọ ọ́ bá rìn ní ọ̀nà mi, bí ìwọ yóò bá sì pa àṣẹ mi mọ́, ìwọ yóò sì ṣe ìdájọ́ ilé mi pẹ̀lú, ìwọ yóò sì ṣe àkóso ààfin mi, èmi yóò fún ọ ní ààyè láti rìn láàrín àwọn tí ó dúró yìí.
The Lord of hosts says: ‘If you walk in my ways, and if you will keep my instructions, then you will rule my house and keep my courts and I will give you a place of access among these that stand by.
8 “‘Gbọ́, ìwọ Joṣua olórí àlùfáà, ìwọ, àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ tí ó jókòó níwájú rẹ: nítorí ẹni ìyanu ni wọ́n: nítorí kíyèsi i, èmi yóò mú ẹ̀ka náà wá fun ìránṣẹ́ mi.
Hear now, Joshua the high priest, you and your associates who sit before me; for they are men who are a sign; for I am going to bring forth my servant the Branch.
9 Nítorí kíyèsi i, òkúta tí mo tí gbé kalẹ̀ níwájú Joṣua; lórí òkúta kan ni ojú méje wà: kíyèsi i, èmi yóò fín àkọlé rẹ̀,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò sì mú ẹ̀bi ilẹ̀ náà kúrò ní ọjọ́ kan.
On the stone that I have set before Joshua, on one stone, are seven facets. I will engrave it,’ says the Lord of hosts, ‘and I will remove the guilt of that land in one day.
10 “‘Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ní ọjọ́ náà ni olúkúlùkù yóò pe ẹnìkejì láti jókòó rẹ̀ sábẹ́ igi àjàrà àti sábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́.’”
On that day,’ says the Lord of hosts, ‘you will each invite your neighbour under the vine and under the fig tree.’