< Zechariah 2 >

1 Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
Es atkal pacēlu savas acis un skatījos, un redzi, tur bija vīrs, un viņa rokā mēra aukla.
2 Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
Un es sacīju: kurp iedams? Un viņš sacīja uz mani: Jeruzālemi mērot un lūkot, kāds viņas platums un kāds viņas garums.
3 Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
Un redzi, tas eņģelis, kas ar mani runāja, izgāja ārā. Un viens cits eņģelis tam nāca pretī.
4 Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
Un viņš uz to sacīja: teci, runā uz šo jaunekli un saki: Jeruzālemē dzīvos bez mūriem aiz liela cilvēku un lopu pulka viņas vidu.
5 Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
Un Es, saka Tas Kungs, viņai būšu par degošu mūri visapkārt, un Es būšu par godību viņas vidū.
6 “Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
Vai, vai, bēdziet jel no ziemeļa zemes! saka Tas Kungs; jo Es jūs izpletīšu uz tiem četriem debess vējiem, saka Tas Kungs.
7 “Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
Vai, Ciāna, glābies, tu, kas dzīvo pie Bābeles meitas.
8 Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
Jo tā saka Tas Kungs Cebaot: pēc godības Viņš mani sūtījis pie tiem pagāniem, kas jūs aplaupījuši; jo kas jūs aizskar, tas aizskar Viņa acs raugu.
9 Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
Jo redzi, Es cilāšu Savu roku pār tiem; tie būs par laupījumu saviem kalpiem; tā jūs samanīsiet, ka Tas Kungs Cebaot mani sūtījis.
10 “Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Gavilē un priecājies, Ciānas meita, jo redzi, Es nāku un dzīvošu tavā vidū, saka Tas Kungs;
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
Un daudz pagāni tai dienā piebiedrosies Tam Kungam, un tie Man būs par ļaudīm, un Es dzīvošu tavā vidū, un tu samanīsi, ka Tas Kungs Cebaot mani pie tevis sūtījis.
12 Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
Tad Tas Kungs iemantos Jūdu par Savu tiesu tai svētā zemē un izredzēs atkal Jeruzālemi.
13 Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”
Ciet klusu, visa miesa, Tā Kunga priekšā! Jo Viņš ir uzcēlies no Savas svētās vietas.

< Zechariah 2 >