< Zechariah 2 >
1 Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
Fölemeltem a szemeimet és láttam, s íme egy férfiú, s kezében mérő kötél.
2 Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
És mondtam: Hová mégy? Szólt hozzám: Kimérni Jeruzsálemet, hogy lássam, mennyi a szélessége és mennyi a hossza.
3 Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
És íme, az angyal, ki velem beszélt, elment, és egy másik angyal kiment elejébe.
4 Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
És szólt hozzá: Fuss, beszélj amaz ifjúhoz, mondván nyílt városként lesz majd lakva Jeruzsálem a benne levő ember és barom sokasága, miatt.
5 Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
Én pedig leszek neki, úgymond az Örökkévaló, tüzes fal gyanánt köröskörül, és dicsőségül leszek benne.
6 “Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
Haj, haj, fussatok hát az észak országából, úgymond az Örökkévaló; mert az égnek négy széle szerint szórtalak el benneteket, úgymond az Örökkévaló.
7 “Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
Haj, Czión, menekülj, lakója te Bábel leányának.
8 Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
Mert így szól az Örökkévaló, a seregek ura: dicsőség után küldött engem azon nemzetekhez, melyek kifosztottak benneteket; mert ki hozzátok nyúl, az saját szemefényéhez nyúl.
9 Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
Mert íme, én kezemet emelem reájuk, hogy zsákmányul legyenek szolgáiknak; és megtudjátok, hogy az Örökkévaló, a seregek ura küldött engem.
10 “Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Ujjongj és örülj, Czión leánya, mert íme én megyek, hogy lakozzam közepetted, úgymond az Örökkévaló.
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
Majd csatlakoznak számos nemzetek az Örökkévalóhoz ama napon és lesznek nekem népül és majd lakozom közepetted, és megtudod, hogy az Örökkévaló, a seregek ura küldött engem hozzád.
12 Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
És bírni fogja az Örökkévaló Jehúdát, mint osztályrészét, a szerit földön, és újból kiválasztja Jeruzsálemet.
13 Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”
Csitt, minden halandó, az Örökkévaló előtt! Mert fölserkent az ő szent hajlékából.