< Zechariah 2 >
1 Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
J'élevai encore mes yeux, et regardai; et voilà un homme qui avait à la main un cordeau à mesurer,
2 Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
Auquel je dis: Où vas-tu? Et il me répondit: Je vais mesurer Jérusalem, pour voir quelle est sa largeur, et quelle est sa longueur.
3 Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
Et voici, l'Ange qui parlait avec moi sortit, et un autre Ange sortit au-devant de lui;
4 Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
Et lui dit: Cours, et parle à ce jeune homme-là, en disant: Jérusalem sera habitée sans murailles, à cause de la multitude d'hommes et de bêtes qui seront au milieu d'elle.
5 Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
Mais je lui serai, dit l'Eternel, une muraille de feu tout autour, et je serai pour gloire au milieu d'elle.
6 “Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
Ha! Fuyez, fuyez hors du pays de l'Aquilon, dit l'Eternel: car je vous ai dispersés vers les quatre vents des cieux, dit l'Eternel.
7 “Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
Ha! Sion qui demeures avec la fille de Babylone, sauve-toi.
8 Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
Car ainsi a dit l'Eternel des armées, lequel après la gloire m'a envoyé vers les nations qui vous ont pillés, que qui vous touche, touche la prunelle de son œil.
9 Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
Car voici, je vais lever ma main sur eux, et ils seront en proie à leurs serviteurs, et vous connaîtrez que l'Eternel des armées m'a envoyé.
10 “Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Réjouis-toi avec chant de triomphe, et t'égaye, fille de Sion; car voici, je viens, et j'habiterai au milieu de toi, dit l'Eternel.
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
Et plusieurs nations se joindront à l’Eternel en ce jour-là, et deviendront mon peuple; et j'habiterai au milieu de toi; et tu sauras que l'Eternel des armées m'a envoyé vers toi.
12 Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
Et l'Eternel héritera Juda pour son partage en la terre de sa sainteté, et il choisira encore Jérusalem.
13 Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”
Que toute chair se taise, devant la face de l'Eternel, car il s'est réveillé de la demeure de sa sainteté.