< Zechariah 2 >

1 Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
Et je levai les yeux, et je regardai, et voilà qu'un homme tenait en sa main un cordeau de mesureur.
2 Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
Et je lui dit: Où vas-tu? Et il me dit: Je vais mesurer Jérusalem, et voir quelle est sa largeur et sa longueur.
3 Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
Et voilà que l'ange qui parlait avec moi s'arrêta, et un autre ange marchait à sa rencontre.
4 Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
Et il lui parla, disant: Cours et parle à ce jeune homme, et dis-lui: Jérusalem regorgera d'une multitude d'hommes et d'un nombreux bétail en son enceinte.
5 Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
Et Moi, dit le Seigneur, Je serai un rempart de feu autour d'elle; et Je résiderai au milieu d'elle en Ma gloire.
6 “Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
Fuyez, fuyez de la terre de l'Aquilon, dit le Seigneur; car Je vous ramènerai des quatre vents du ciel, dit le Seigneur;
7 “Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
Je vous ramènerai dans Sion; sauvez-vous, vous qui habitez chez la fille de Babylone!
8 Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
Car voici ce que dit le Seigneur tout-puissant: Sur les pas de leur gloire, Il m'a envoyé contre les nations qui vous ont dépouillés; car celui qui touche à vous est comme celui qui touche à la prunelle de Son œil.
9 Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
Aussi voilà que Je porte la main sur eux, et ils seront la proie de ceux qu'ils ont asservis; et vous connaîtrez que je suis l'envoyé du Seigneur tout- puissant.
10 “Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Réjouis-toi, tressaille d'allégresse, Sion, Ma fille; car voilà que J'arrive, et Je placerai Ma tente au milieu de toi, dit le Seigneur.
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
Et en ce jour nombre de nations se réfugieront auprès du Seigneur, et elles seront à Lui comme un peuple nouveau; et elles résideront au milieu de toi, et tu connaîtras que le Seigneur tout-puissant m'a envoyé près de toi.
12 Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
Et le Seigneur aura Juda pour héritage; ce sera Sa part dans la terre sainte, et Jérusalem sera encore Son élue.
13 Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”
Que toute chair craigne en face du Seigneur; car Il S'est élancé de Ses nuées saintes.

< Zechariah 2 >