< Zechariah 2 >

1 Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
And Y reiside myn iyen, and siy, and lo! a man, and lo! in his hoond a litil coorde of meteris.
2 Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
And Y seide, Whidir goist thou? And he seide to me, That Y mete Jerusalem, and Judee; hou myche is the breede therof, and hou myche is the lengthe therof.
3 Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
And lo! the aungel that spak in me, wente out, and another aungel wente out in to the metyng of hym, and seide to hym,
4 Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
Renne thou, speke to this child, and seie thou, Jerusalem shal be enhabitid with out wal, for the multitude of men and of beestis in the myddil therof.
5 Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
And Y schal be to it, seith the Lord, a wal of fier in cumpas; and Y schal be in glorie in myddil therof.
6 “Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
A! A! A! fle ye fro the lond of the north, seith the Lord, for in foure wyndis of heuene Y scateride you, seith the Lord.
7 “Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
A! thou Sion, fle, that dwellist at the douyter of Babiloyne.
8 Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
For the Lord of oostis seith these thingis, After glorie he sente me to hethene men, whiche robbiden you; for he that schal touche you, schal touche the apple of myn iye.
9 Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
For lo! Y reise myn hond on hem, and thei schulen be preyes to these that seruyden hem; and ye schulen knowe, that the Lord of oostis sente me.
10 “Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Douyter of Sion, herie thou, and be glad; for lo! Y come, and Y schal dwelle in myddil of thee, seith the Lord.
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
And many folkis schulen be applied to the Lord in that dai, and thei schulen be to me in to puple, and Y schal dwelle in myddil of thee; and thou schalt wite, that the Lord of oostis sente me to thee.
12 Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
And the Lord schal welde Juda in to his part, in the loud halewid, and schal cheese yit Jerusalem.
13 Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”
Ech fleisch be stil fro the face of the Lord, for he roos of his hooli dwelling place.

< Zechariah 2 >