< Zechariah 14 >
1 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀, a ó sì pín ìkógun rẹ̀ láàrín rẹ̀.
Mana, Pǝrwǝrdigarƣa has kün kelidu; [u küni] arangdin mal-mülküng bulang-talang ⱪilinip bɵlüxüwelinidu.
2 Nítorí èmi ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí Jerusalẹmu fún ogun; a ó sì ko ìlú náà, a ó sì kó àwọn ilé, a ó sì ba àwọn obìnrin jẹ́, ààbọ̀ ìlú náà yóò lọ sí ìgbèkùn, a kì yóò sì gé ìyókù àwọn ènìyàn náà kúrò ni ìlú náà.
Mǝn barliⱪ ǝllǝrni Yerusalemƣa jǝng ⱪilixⱪa yiƣimǝn; xǝⱨǝr ixƣal ⱪilinidu, ɵylǝr bulang-talang ⱪilinip, ⱪiz-ayallar ayaƣ-asti ⱪilinidu; xǝⱨǝrning yerimi ǝsirgǝ qüxüp sürgün ⱪilinidu; tirik ⱪalƣan hǝlⱪ xǝⱨǝrdin elip ketilmǝydu.
3 Nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ, yóò sì bá àwọn orílẹ̀-èdè náà jà, gẹ́gẹ́ bí í ti ìjà ní ọjọ́ ogun.
Andin Pǝrwǝrdigar qiⱪip xu ǝllǝr bilǝn uruxidu; U Uning jǝng ⱪilƣan künidikidǝk uruxidu.
4 Ẹsẹ̀ rẹ̀ yóò sì dúró ni ọjọ́ náà lórí òkè Olifi, tí ó wà níwájú Jerusalẹmu ni ìlà-oòrùn, òkè Olifi yóò sì là á sí méjì, sí ìhà ìlà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrùn, àfonífojì ńlá ńlá yóò wà: ìdajì òkè náà yóò sì ṣí síhà àríwá, àti ìdajì rẹ̀ síhà gúúsù.
Uning putliri xu küni Yerusalemning xǝrⱪiy tǝripining ǝng aldi bolƣan Zǝytun teƣida turidu; xuning bilǝn Zǝytun teƣi otturidin xǝrⱪ wǝ ƣǝrb tǝrǝpkǝ yerilidu; zor yoƣan bir jilƣa pǝyda bolidu; taƣning yerimi ximal tǝrǝpkǝ, yerimi jǝnub tǝrǝpkǝ yɵtkilidu.
5 Ẹ̀yin ó sì sá sí àfonífojì àwọn òkè mi, nítorí pé àfonífojì òkè náà yóò dé Aseli: nítòótọ́, ẹ̀yin ó sá bí ẹ tí sá fún ìmìmì-ilẹ̀ ni ọjọ́ Ussiah ọba Juda: Olúwa Ọlọ́run mi yóò sì wá, àti gbogbo àwọn Ẹni mímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Wǝ silǝr Mening taƣlirimning dǝl muxu jilƣisi bilǝn ⱪaqisilǝr; qünki taƣlarning jilƣisi Azǝlgiqǝ baridu; silǝr Yǝⱨuda padixaⱨi Uzziyaning künliridǝ bolƣan yǝr tǝwrǝxtǝ ⱪaqⱪininglardǝk ⱪaqisilǝr. Andin Pǝrwǝrdigar Hudayim kelidu; ⱨǝmdǝ Sǝn bilǝn barliⱪ «muⱪǝddǝs bolƣuqilar»mu kelidu!
6 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìmọ́lẹ̀ kì yóò mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ṣókùnkùn.
Xu küni xundaⱪ boliduki, nur tohtap ⱪalidu; parlaⱪ yultuzlarmu ⱪarangƣulixip ketidu;
7 Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ọjọ́ kan mímọ́ fún Olúwa, kì í ṣe ọ̀sán, kì í ṣe òru; ṣùgbọ́n yóò ṣe pé, ni àṣálẹ́ ìmọ́lẹ̀ yóò wà.
Biraⱪ u Pǝrwǝrdigarƣa mǝlum bolƣan alaⱨidǝ bir kün, ya keqǝ ya kündüz bolmaydu; xundaⱪ ǝmǝlgǝ axuruliduki, kǝq kirgǝndǝ, alǝm yorutulidu.
8 Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, omi ìyè yóò tí Jerusalẹmu sàn lọ; ìdajì wọn síhà Òkun ìlà-oòrùn, àti ìdajì wọn síhà okùn ẹ̀yìn: nígbà ẹ̀rùn àti nígbà òtútù ni yóò rí bẹ́ẹ̀.
Xu küni xundaⱪ boliduki, ⱨayatliⱪ suliri Yerusalemdin eⱪip qiⱪidu; ularning yerimi xǝrⱪiy dengizƣa, yerimi ƣǝrbiy dengizƣa ⱪarap aⱪidu; yazda wǝ ⱪixta xundaⱪ bolidu.
9 Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí gbogbo ayé; ni ọjọ́ náà ni Olúwa kan yóò wa orúkọ rẹ̀ nìkan náà ni orúkọ.
Pǝrwǝrdigar pütkül yǝr yüzi üstidǝ padixaⱨ bolidu; xu küni pǝⱪǝt bir «Pǝrwǝrdigar» bolidu, [yǝr yüzidǝ] birdinbir Uningla nami bolidu.
10 A ó yí gbogbo ilẹ̀ padà bi pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan láti Geba dé Rimoni lápá gúúsù Jerusalẹmu: yóò di bí aginjù, ṣùgbọ́n a ó sì gbé Jerusalẹmu sókè, yóò sì gbe ipò rẹ̀, láti ibodè Benjamini títí dé ibi ibodè èkínní, dé ibodè igun nì, àti láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé ibi ìfúntí wáìnì ọba.
Gebadin Yerusalemning jǝnubidiki Rimmonƣiqǝ bolƣan pütün zemin «Arabaⱨ»dǝk tüzlǝnglikkǝ aylandurulidu; Yerusalem bolsa «Binyamin dǝrwazisi»din «Birinqi dǝrwaza»ƣiqǝ wǝ yǝnǝ «Burjǝk dǝrwazisi»ƣiqǝ, «Ⱨananiyǝlning munari»din padixaⱨning xarab kɵlqǝklirigiqǝ yuⱪiri kɵtürülidu, lekin xǝⱨǝr yǝnila ɵz jayida xu peti turidu;
11 Ènìyàn yóò sì máa gbé ibẹ̀, kì yóò sì sí ìparun mọ́; ṣùgbọ́n a ó máa gbé Jerusalẹmu láìléwu.
Adǝmlǝr yǝnǝ uningda turidu. «Ⱨalak pǝrmani» yǝnǝ ⱨeq qüxürülmǝydu; Yerusalem hatirjǝmliktǝ turidu.
12 Èyí ni yóò sì jẹ́ ààrùn tí Olúwa yóò fi kọlu gbogbo àwọn ènìyàn ti ó tí ba Jerusalẹmu jà; ẹran-ara wọn yóò rù nígbà tí wọn dúró ni ẹsẹ̀ wọn, ojú wọn yóò sì rà ni ihò wọn, ahọ́n wọn yóò sì bàjẹ́ ni ẹnu wọn.
Wǝ Pǝrwǝrdigar Yerusalemƣa jǝng ⱪilƣan barliⱪ ǝllǝrni uruxⱪa ixlǝtkǝn waba xundaⱪ boliduki, ular ɵrǝ bolsila gɵxliri qirip ketidu; kɵzliri qanaⱪlirida qirip ketidu; tilliri aƣzida qirip ketidu.
13 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò wà láàrín wọn; wọn ó sì di ọwọ́ ara wọn mú, ọwọ́ èkínní yóò sì dìde sì ọwọ́ èkejì rẹ̀.
Xu küni xundaⱪ boliduki, ularning arisiƣa Pǝrwǝrdigardin zor bir alaⱪzadilik qüxidu; ular ⱨǝrbiri ɵz yeⱪinining ⱪolini tutuxidu, ⱨǝrbirining ⱪoli yeⱪinining ⱪoliƣa ⱪarxi kɵtürülidu.
14 Juda pẹ̀lú yóò sì jà ni Jerusalẹmu: ọrọ̀ gbogbo àwọn kèfèrí tí ó wà káàkiri ni a ó sì kójọ, wúrà àti fàdákà, àti aṣọ, ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Yǝⱨudamu Yerusalemda jǝng ⱪilidu; ǝtrapidiki barliⱪ ǝllǝrning mal-mülükliri jǝm ⱪilip yiƣilidu — san-sanaⱪsiz altun-kümüx wǝ kiyim-keqǝklǝr bolidu.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ààrùn ẹṣin, ìbáaka, ìbákasẹ, àti tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, yóò sì wà, àti gbogbo ẹranko tí ń bẹ nínú àgọ́.
At, ⱪeqir, tɵgǝ, exǝk, xundaⱪla ularning bargaⱨlirida bolƣan barliⱪ mal-waranlar üstigǝ qüxkǝn waba yuⱪiriⱪi wabaƣa ohxax bolidu.
16 Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ẹni tí o kù nínú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó dìde sí Jerusalẹmu yóò máa gòkè lọ lọ́dọọdún láti sìn ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
Xundaⱪ ǝmǝlgǝ axuruliduki, Yerusalemƣa jǝng ⱪilixⱪa kǝlgǝn ⱨǝmmǝ ǝllǝrdin barliⱪ tirik ⱪalƣanlar ⱨǝr yili Yerusalemƣa, padixaⱨⱪa, yǝni samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigarƣa ibadǝt ⱪilixⱪa wǝ «kǝpilǝr ⱨeyti»ni tǝbriklǝxkǝ qiⱪidu.
17 Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí kì yóò gòkè wá nínú gbogbo ìdílé ayé sí Jerusalẹmu láti sín ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, òjò kì yóò rọ̀ fún wọn.
Xundaⱪ boliduki, yǝr yüzidiki ⱪowm-jǝmǝtlǝrdin padixaⱨⱪa, yǝni samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigarƣa ibadǝtkǝ qiⱪmiƣanlar bolsa, ǝmdi ularning üstigǝ yamƣur yaƣmaydu.
18 Bí ìdílé Ejibiti kò bá sì gòkè lọ, tí wọn kò sì wá, fi ara wọn hàn tí wọn kò ní òjò; ààrùn náà yóò wà, tí Olúwa yóò fi kọlù àwọn kèfèrí tí kò gòkè wá láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
Misir jǝmǝti qiⱪip ⱨazir bolmisa, ularƣimu yamƣur bolmaydu; biraⱪ Pǝrwǝrdigar «kǝpilǝr ⱨeyti»ni tǝbriklǝxkǝ qiⱪmaydiƣan barliⱪ ǝllǝr üstigǝ qüxüridiƣan waba ularƣimu qüxürülidu.
19 Èyí ni yóò sì jẹ́ ìyà Ejibiti, àti ìyà gbogbo orílẹ̀-èdè tí kò gòkè wá láti pa àsè àgọ́ mọ́.
Bu Misirning jazasi, xundaⱪla «kǝpilǝr ⱨeyti»ni tǝbriklǝxkǝ qiⱪmaydiƣan barliⱪ ǝllǝrning jazasi bolidu.
20 Ní ọjọ́ náà ni “mímọ́ sí Olúwa” yóò wà lára ṣaworo ẹṣin: àti àwọn ìkòkò ni ilé Olúwa yóò sì dàbí àwọn ọpọ́n tí ń bẹ níwájú pẹpẹ.
Xu küni atlarning ⱪongƣuraⱪliri üstigǝ «Pǝrwǝrdigarƣa atilip pak-muⱪǝddǝs bolsun!» dǝp yezilidu; Pǝrwǝrdigarning ɵyidiki barliⱪ ⱪaqa-ⱪuqilarmu ⱪurbangaⱨ aldidiki ⱪaqilarƣa ohxax ⱨesablinidu;
21 Nítòótọ́, gbogbo ìkòkò ni Jerusalẹmu àti ni Juda yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun: àti gbogbo àwọn tí ń rú ẹbọ yóò wá, wọn ó sì mú ìkòkò díẹ̀, wọn ó sì bọ ẹran wọn nínú rẹ̀, ni ọjọ́ náà ni àwọn Kenaani kò ní sí mọ́ ni ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Yerusalemdiki wǝ Yǝⱨudadiki barliⱪ ⱪaqa-ⱪuqilarmu Pǝrwǝrdigarƣa atilip pak-muⱪǝddǝs bolidu; ⱪurbanliⱪ ⱪilƣuqilar kelip ularni elip ⱪurbanliⱪ gɵxlirini pixuridu; xu küni samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigarning ɵyidǝ «ⱪanaanliⱪ-sodigǝr» ikkinqi bolmaydu.