< Zechariah 14 >

1 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀, a ó sì pín ìkógun rẹ̀ láàrín rẹ̀.
Oto przychodzi dzień PANA, a twój łup będzie rozdzielony pośród ciebie.
2 Nítorí èmi ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí Jerusalẹmu fún ogun; a ó sì ko ìlú náà, a ó sì kó àwọn ilé, a ó sì ba àwọn obìnrin jẹ́, ààbọ̀ ìlú náà yóò lọ sí ìgbèkùn, a kì yóò sì gé ìyókù àwọn ènìyàn náà kúrò ni ìlú náà.
Zgromadzę bowiem do bitwy wszystkie narody przeciwko Jerozolimie, a miasto zostanie zdobyte, domy splądrowane i kobiety zgwałcone. Połowa miasta pójdzie do niewoli, a resztka ludu nie będzie wygnana z miasta.
3 Nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ, yóò sì bá àwọn orílẹ̀-èdè náà jà, gẹ́gẹ́ bí í ti ìjà ní ọjọ́ ogun.
Wtedy PAN wyruszy i będzie walczył przeciwko tym narodom, tak jak wtedy, gdy walczył w dniu bitwy.
4 Ẹsẹ̀ rẹ̀ yóò sì dúró ni ọjọ́ náà lórí òkè Olifi, tí ó wà níwájú Jerusalẹmu ni ìlà-oòrùn, òkè Olifi yóò sì là á sí méjì, sí ìhà ìlà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrùn, àfonífojì ńlá ńlá yóò wà: ìdajì òkè náà yóò sì ṣí síhà àríwá, àti ìdajì rẹ̀ síhà gúúsù.
I jego nogi staną w tym dniu na Górze Oliwnej, która [leży] naprzeciw Jerozolimy od strony wschodniej, a Góra Oliwna rozpadnie się na pół, na wschód i na zachód, [tworząc] wielką dolinę; i połowa tej góry cofnie się na północ, a połowa jej – na południe.
5 Ẹ̀yin ó sì sá sí àfonífojì àwọn òkè mi, nítorí pé àfonífojì òkè náà yóò dé Aseli: nítòótọ́, ẹ̀yin ó sá bí ẹ tí sá fún ìmìmì-ilẹ̀ ni ọjọ́ Ussiah ọba Juda: Olúwa Ọlọ́run mi yóò sì wá, àti gbogbo àwọn Ẹni mímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Wtedy będziecie uciekać do doliny [tych] gór, bo dolina tych gór będzie sięgać aż do Azal. Będziecie uciekać, jak uciekaliście przed trzęsieniem ziemi za dni Uzjasza, króla Judy. Potem przyjdzie PAN, mój Bóg, [a] z nim wszyscy święci.
6 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìmọ́lẹ̀ kì yóò mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ṣókùnkùn.
A w tym dniu nie będzie wspaniałej światłości ani gęstej ciemności;
7 Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ọjọ́ kan mímọ́ fún Olúwa, kì í ṣe ọ̀sán, kì í ṣe òru; ṣùgbọ́n yóò ṣe pé, ni àṣálẹ́ ìmọ́lẹ̀ yóò wà.
Lecz będzie to jeden dzień, który jest znany [tylko] PANU, nie [będzie] to dzień ani noc. A o wieczornej porze nastanie światło.
8 Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, omi ìyè yóò tí Jerusalẹmu sàn lọ; ìdajì wọn síhà Òkun ìlà-oòrùn, àti ìdajì wọn síhà okùn ẹ̀yìn: nígbà ẹ̀rùn àti nígbà òtútù ni yóò rí bẹ́ẹ̀.
W tym dniu wyjdą wody żywe z Jerozolimy; połowa ich do morza wschodniego, a połowa – do morza zachodniego. Będzie [to] w lecie i w zimie.
9 Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí gbogbo ayé; ni ọjọ́ náà ni Olúwa kan yóò wa orúkọ rẹ̀ nìkan náà ni orúkọ.
A PAN będzie królem nad całą ziemią. W tym dniu jeden będzie PAN i jedno jego imię.
10 A ó yí gbogbo ilẹ̀ padà bi pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan láti Geba dé Rimoni lápá gúúsù Jerusalẹmu: yóò di bí aginjù, ṣùgbọ́n a ó sì gbé Jerusalẹmu sókè, yóò sì gbe ipò rẹ̀, láti ibodè Benjamini títí dé ibi ibodè èkínní, dé ibodè igun nì, àti láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé ibi ìfúntí wáìnì ọba.
Cała ziemia zamieni się w równinę od Geba aż do Rimmon, na południe od Jerozolimy. Będzie wywyższona i zamieszkana na swoim miejscu, od Bramy Beniamina aż do miejsca dawnej bramy i aż do Bramy Narożnej i od Wieży Chananeela aż do tłoczni królewskich.
11 Ènìyàn yóò sì máa gbé ibẹ̀, kì yóò sì sí ìparun mọ́; ṣùgbọ́n a ó máa gbé Jerusalẹmu láìléwu.
I będą w niej mieszkać, a nie będzie już przekleństwem. Jerozolima będzie zamieszkiwać w pokoju.
12 Èyí ni yóò sì jẹ́ ààrùn tí Olúwa yóò fi kọlu gbogbo àwọn ènìyàn ti ó tí ba Jerusalẹmu jà; ẹran-ara wọn yóò rù nígbà tí wọn dúró ni ẹsẹ̀ wọn, ojú wọn yóò sì rà ni ihò wọn, ahọ́n wọn yóò sì bàjẹ́ ni ẹnu wọn.
A taka będzie plaga, którą PAN dotknie wszystkie narody, które walczyły przeciwko Jerozolimie: Ich ciała będą się rozkładać, gdy jeszcze będą stać na nogach, ich oczy będą gnić w oczodołach i ich język zgnije w ustach.
13 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò wà láàrín wọn; wọn ó sì di ọwọ́ ara wọn mú, ọwọ́ èkínní yóò sì dìde sì ọwọ́ èkejì rẹ̀.
W tym dniu będzie wśród nich wielkie zamieszanie od PANA, tak że jeden uchwyci rękę drugiego, a jego ręka podniesie się na rękę swego bliźniego.
14 Juda pẹ̀lú yóò sì jà ni Jerusalẹmu: ọrọ̀ gbogbo àwọn kèfèrí tí ó wà káàkiri ni a ó sì kójọ, wúrà àti fàdákà, àti aṣọ, ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Juda także będzie walczyć w Jerozolimie, a bogactwa wszystkich narodów okolicznych będą zgromadzone: złoto, srebro i szaty w wielkiej ilości.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ààrùn ẹṣin, ìbáaka, ìbákasẹ, àti tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, yóò sì wà, àti gbogbo ẹranko tí ń bẹ nínú àgọ́.
A taka sama plaga jak tamta dotknie konie, muły, wielbłądy, osły oraz wszystkie zwierzęta, które będą w tym obozie.
16 Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ẹni tí o kù nínú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó dìde sí Jerusalẹmu yóò máa gòkè lọ lọ́dọọdún láti sìn ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
Wszyscy pozostali [spośród] wszystkich narodów, które wyruszyły przeciwko Jerozolimie, będą przychodzić od roku do roku, by oddawać pokłon Królowi, PANU zastępów, i obchodzić Święto Namiotów;
17 Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí kì yóò gòkè wá nínú gbogbo ìdílé ayé sí Jerusalẹmu láti sín ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, òjò kì yóò rọ̀ fún wọn.
A jeśli ktoś spośród rodów ziemi nie pójdzie do Jerozolimy, by oddawać pokłon Królowi, PANU zastępów, na tego nie będzie [padać] deszcz.
18 Bí ìdílé Ejibiti kò bá sì gòkè lọ, tí wọn kò sì wá, fi ara wọn hàn tí wọn kò ní òjò; ààrùn náà yóò wà, tí Olúwa yóò fi kọlù àwọn kèfèrí tí kò gòkè wá láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
A jeśli ród Egiptu nie wyruszy i nie przyjdzie, choć na niego deszcz nie [pada], spadnie jednak [na niego ta] plaga, którą PAN dotknie narody, które nie przyjdą, by obchodzić Święto Namiotów.
19 Èyí ni yóò sì jẹ́ ìyà Ejibiti, àti ìyà gbogbo orílẹ̀-èdè tí kò gòkè wá láti pa àsè àgọ́ mọ́.
Taka będzie kara dla Egiptu i kara dla wszystkich narodów, które nie przychodzą na obchody Święta Namiotów.
20 Ní ọjọ́ náà ni “mímọ́ sí Olúwa” yóò wà lára ṣaworo ẹṣin: àti àwọn ìkòkò ni ilé Olúwa yóò sì dàbí àwọn ọpọ́n tí ń bẹ níwájú pẹpẹ.
W tym dniu na dzwoneczkach koni będzie [taki napis]: Świętość PANU; a kotłów w domu PANA będzie jak czasz przed ołtarzem.
21 Nítòótọ́, gbogbo ìkòkò ni Jerusalẹmu àti ni Juda yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun: àti gbogbo àwọn tí ń rú ẹbọ yóò wá, wọn ó sì mú ìkòkò díẹ̀, wọn ó sì bọ ẹran wọn nínú rẹ̀, ni ọjọ́ náà ni àwọn Kenaani kò ní sí mọ́ ni ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Każdy kocioł w Jerozolimie i Judzie będzie poświęcony PANU zastępów. Wszyscy, którzy składają ofiary, przyjdą i będą je brali, i będą w nich gotowali. W tym dniu nie będzie już Kananejczyka w domu PANA zastępów.

< Zechariah 14 >