< Zechariah 14 >

1 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀, a ó sì pín ìkógun rẹ̀ láàrín rẹ̀.
Oto przychodzi dzień Pański, a rozdzielone będą korzyści twoje w pośrodku ciebie.
2 Nítorí èmi ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí Jerusalẹmu fún ogun; a ó sì ko ìlú náà, a ó sì kó àwọn ilé, a ó sì ba àwọn obìnrin jẹ́, ààbọ̀ ìlú náà yóò lọ sí ìgbèkùn, a kì yóò sì gé ìyókù àwọn ènìyàn náà kúrò ni ìlú náà.
Bo zgromadzę wszystkie narody przeciwko Jeruzalemowi na wojnę, a miasto wzięte będzie, i domy rozchwycone będą, i niewiasty pogwałcone będą; a gdy pójdzie część miasta w pojmanie, ostatek ludu nie będzie wygładzony z miasta.
3 Nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ, yóò sì bá àwọn orílẹ̀-èdè náà jà, gẹ́gẹ́ bí í ti ìjà ní ọjọ́ ogun.
Bo wyjdzie Pan, i będzie walczył przeciwko onym narodom, jako zwykł wojować w dzień potykania.
4 Ẹsẹ̀ rẹ̀ yóò sì dúró ni ọjọ́ náà lórí òkè Olifi, tí ó wà níwájú Jerusalẹmu ni ìlà-oòrùn, òkè Olifi yóò sì là á sí méjì, sí ìhà ìlà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrùn, àfonífojì ńlá ńlá yóò wà: ìdajì òkè náà yóò sì ṣí síhà àríwá, àti ìdajì rẹ̀ síhà gúúsù.
I staną nogi jego w on dzień na górze Oliwnej, która jest przeciwko Jeruzalemowi na wschód słońca, a góra Oliwna się na poły rozszczepi, na wschód i na zachód słońca rozpadliną bardzo wielką, i odwali się połowa onej góry na północ, a połowa jej na południe.
5 Ẹ̀yin ó sì sá sí àfonífojì àwọn òkè mi, nítorí pé àfonífojì òkè náà yóò dé Aseli: nítòótọ́, ẹ̀yin ó sá bí ẹ tí sá fún ìmìmì-ilẹ̀ ni ọjọ́ Ussiah ọba Juda: Olúwa Ọlọ́run mi yóò sì wá, àti gbogbo àwọn Ẹni mímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Tedy ucieczecie przed doliną gór; (bo dolina tych gór dosięże aż do Azal) będziecie, mówię, uciekać, jakoście uciekali przed trzęsieniem ziemi za dni Ozyjasza, króla Judzkiego, gdy przyjdzie Pan, Bóg mój, i wszyscy święci z nim.
6 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìmọ́lẹ̀ kì yóò mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ṣókùnkùn.
I stanie się dnia onego, że nie będzie światłości drogiej, ani ciemności gęstej;
7 Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ọjọ́ kan mímọ́ fún Olúwa, kì í ṣe ọ̀sán, kì í ṣe òru; ṣùgbọ́n yóò ṣe pé, ni àṣálẹ́ ìmọ́lẹ̀ yóò wà.
Lecz będzie dzień jeden, który jest wiadomy Panu, a nie będzie dnia ani nocy; wszakże czasu wieczornego będzie światło.
8 Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, omi ìyè yóò tí Jerusalẹmu sàn lọ; ìdajì wọn síhà Òkun ìlà-oòrùn, àti ìdajì wọn síhà okùn ẹ̀yìn: nígbà ẹ̀rùn àti nígbà òtútù ni yóò rí bẹ́ẹ̀.
A dnia onego wyjdą wody żywe z Jeruzalemu; połowa ich do morza na wschód słońca, a połowa ich do morza ostatniego, a to będzie w lecie i w zimie.
9 Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí gbogbo ayé; ni ọjọ́ náà ni Olúwa kan yóò wa orúkọ rẹ̀ nìkan náà ni orúkọ.
A Pan będzie królem nad wszystką ziemią; w on dzień będzie Pan jeden, i imię jego jedno.
10 A ó yí gbogbo ilẹ̀ padà bi pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan láti Geba dé Rimoni lápá gúúsù Jerusalẹmu: yóò di bí aginjù, ṣùgbọ́n a ó sì gbé Jerusalẹmu sókè, yóò sì gbe ipò rẹ̀, láti ibodè Benjamini títí dé ibi ibodè èkínní, dé ibodè igun nì, àti láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé ibi ìfúntí wáìnì ọba.
I uczyniona będzie ta wszystka ziemia, jako równina od Gabaa aż do Remmon na południe ku Jeruzalemowi, który wywyższony będąc, stać będzie na miejscu swojem od bramy Benjaminowej aż do miejsca bramy pierwszej i aż do bramy węgielnej, a od wieży Chananeel aż do pras królewskich.
11 Ènìyàn yóò sì máa gbé ibẹ̀, kì yóò sì sí ìparun mọ́; ṣùgbọ́n a ó máa gbé Jerusalẹmu láìléwu.
I będą w nim mieszkać, a nie będzie więcej przeklęstwem, a Jeruzalem bezpiecznie mieszkać będzie.
12 Èyí ni yóò sì jẹ́ ààrùn tí Olúwa yóò fi kọlu gbogbo àwọn ènìyàn ti ó tí ba Jerusalẹmu jà; ẹran-ara wọn yóò rù nígbà tí wọn dúró ni ẹsẹ̀ wọn, ojú wọn yóò sì rà ni ihò wọn, ahọ́n wọn yóò sì bàjẹ́ ni ẹnu wọn.
A tać będzie plaga, którą uderzy Pan wszystkie narody, któreby walczyły przeciwko Jeruzalemowi: Ciało każdego stojącego na nogach swoich schnąć będzie, a oczy ich wypłyną z dołków swoich, i język ich uschnie w ustach ich.
13 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò wà láàrín wọn; wọn ó sì di ọwọ́ ara wọn mú, ọwọ́ èkínní yóò sì dìde sì ọwọ́ èkejì rẹ̀.
I stanie się dnia onego wielkie uciśnienie Pańskie między nimi, tak, iż rękę jeden drugiego uchwyci, a ręka jego podniesie się na rękę bliźniego swego.
14 Juda pẹ̀lú yóò sì jà ni Jerusalẹmu: ọrọ̀ gbogbo àwọn kèfèrí tí ó wà káàkiri ni a ó sì kójọ, wúrà àti fàdákà, àti aṣọ, ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
I tyć też, Judo! walczyć będziesz w Jeruzalemie, a zgromadzone będą bogactwa wszystkich narodów okolicznych, złoto i srebro i szat obfitość wielka.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ààrùn ẹṣin, ìbáaka, ìbákasẹ, àti tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, yóò sì wà, àti gbogbo ẹranko tí ń bẹ nínú àgọ́.
A takaż będzie plaga na konie, muły, wielbłądy, i osły, i na wszystkie bydlęta, które będą w onym obozie, jako i ta plaga.
16 Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ẹni tí o kù nínú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó dìde sí Jerusalẹmu yóò máa gòkè lọ lọ́dọọdún láti sìn ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
A ile ich pozostanie z onych wszystkich narodów, któreby przyciągnęły przeciwko Jeruzalemowi, będą przychodzić od roku do roku, pokłon oddawać królowi, Panu zastępów, i obchodzić święto Kuczek;
17 Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí kì yóò gòkè wá nínú gbogbo ìdílé ayé sí Jerusalẹmu láti sín ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, òjò kì yóò rọ̀ fún wọn.
A ktoby nie szedł z pokolenia ziemi do Jeruzalemu, pokłon oddawać królowi, Panu zastępów, na tych deszcz padać nie będzie.
18 Bí ìdílé Ejibiti kò bá sì gòkè lọ, tí wọn kò sì wá, fi ara wọn hàn tí wọn kò ní òjò; ààrùn náà yóò wà, tí Olúwa yóò fi kọlù àwọn kèfèrí tí kò gòkè wá láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
A jeśli pokolenie Egipskie nie wstąpi, i nie przyjdzie, choć na nich deszcz nie pada, przyjdzie jednak ta plaga, którą uderzy Pan narody, które nie przyszły, obchodzić święta Kuczek.
19 Èyí ni yóò sì jẹ́ ìyà Ejibiti, àti ìyà gbogbo orílẹ̀-èdè tí kò gòkè wá láti pa àsè àgọ́ mọ́.
A tać będzie kaźń grzechu Egipskiego, i kaźń grzechu wszystkich narodów, któreby nie przychodziły ku obchodzeniu święta Kuczek.
20 Ní ọjọ́ náà ni “mímọ́ sí Olúwa” yóò wà lára ṣaworo ẹṣin: àti àwọn ìkòkò ni ilé Olúwa yóò sì dàbí àwọn ọpọ́n tí ń bẹ níwájú pẹpẹ.
Dnia onego będzie na rzędach końskich napisane: Świętobliwość Pańska; a kotłów będzie w domu Pańskim, jako miednic przed ołtarzem.
21 Nítòótọ́, gbogbo ìkòkò ni Jerusalẹmu àti ni Juda yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun: àti gbogbo àwọn tí ń rú ẹbọ yóò wá, wọn ó sì mú ìkòkò díẹ̀, wọn ó sì bọ ẹran wọn nínú rẹ̀, ni ọjọ́ náà ni àwọn Kenaani kò ní sí mọ́ ni ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Owszem, każdy kocieł w Jeruzalemie i w Judzie poświęcony będzie Panu zastępów; a przychodząc wszyscy, którzy ofiarować mają, brać je i warzyć w nich będą, a nie będzie Chananejczyka więcej w domu Pana zastępów dnia onego.

< Zechariah 14 >