< Zechariah 14 >

1 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀, a ó sì pín ìkógun rẹ̀ láàrín rẹ̀.
Atĩrĩrĩ, mũthenya wa Jehova nĩũrooka, rĩrĩa indo cianyu igaatahwo na igayanĩrwo gatagatĩ-inĩ kanyu.
2 Nítorí èmi ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí Jerusalẹmu fún ogun; a ó sì ko ìlú náà, a ó sì kó àwọn ilé, a ó sì ba àwọn obìnrin jẹ́, ààbọ̀ ìlú náà yóò lọ sí ìgbèkùn, a kì yóò sì gé ìyókù àwọn ènìyàn náà kúrò ni ìlú náà.
Nĩngongania ndũrĩrĩ ciothe ciũkĩrĩre itũũra rĩa Jerusalemu, ihũũrane narĩo; itũũra rĩu inene nĩrĩkanyiitwo nĩ thũ, na indo cia nyũmba ciũngũrũrio nao andũ-a-nja manyiitwo na hinya. Andũ nuthu ya itũũra nĩmagathaamio, no andũ acio angĩ matikeherio itũũra-inĩ rĩu.
3 Nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ, yóò sì bá àwọn orílẹ̀-èdè náà jà, gẹ́gẹ́ bí í ti ìjà ní ọjọ́ ogun.
Hĩndĩ ĩyo Jehova nĩakoimagara, okĩrĩre ndũrĩrĩ icio arũe nacio, o ta ũrĩa arũaga mũthenya wa mbaara.
4 Ẹsẹ̀ rẹ̀ yóò sì dúró ni ọjọ́ náà lórí òkè Olifi, tí ó wà níwájú Jerusalẹmu ni ìlà-oòrùn, òkè Olifi yóò sì là á sí méjì, sí ìhà ìlà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrùn, àfonífojì ńlá ńlá yóò wà: ìdajì òkè náà yóò sì ṣí síhà àríwá, àti ìdajì rẹ̀ síhà gúúsù.
Mũthenya ũcio-rĩ, Jehova nĩakarũgama Kĩrĩma-inĩ kĩa Mĩtamaiyũ, mwena wa irathĩro wa Jerusalemu. Nakĩo Kĩrĩma kĩu kĩa Mĩtamaiyũ nĩgĩgatũkana maita meerĩ kuuma mwena wa irathĩro nginya mwena wa ithũĩro; naho hagĩe mũkuru mũnene, nuthu ĩmwe ya kĩrĩma ĩthiĩ mwena wa gathigathini, nayo nuthu ĩyo ĩngĩ ĩthiĩ mwena wa gũthini.
5 Ẹ̀yin ó sì sá sí àfonífojì àwọn òkè mi, nítorí pé àfonífojì òkè náà yóò dé Aseli: nítòótọ́, ẹ̀yin ó sá bí ẹ tí sá fún ìmìmì-ilẹ̀ ni ọjọ́ Ussiah ọba Juda: Olúwa Ọlọ́run mi yóò sì wá, àti gbogbo àwọn Ẹni mímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
Mũkoorĩra mũkuru-inĩ ũcio wa kĩrĩma gĩakwa tondũ ũgaakinya o Azeli. Mũkoora o ta ũrĩa mworĩire gĩthingithia matukũ-inĩ ma Uzia, mũthamaki wa Juda. Nake Jehova Ngai wakwa nĩagooka, arĩ hamwe na andũ arĩa atheru othe.
6 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìmọ́lẹ̀ kì yóò mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ṣókùnkùn.
Mũthenya ũcio gũtigakorwo na ũtheri kana heho o na kana mbaa.
7 Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ọjọ́ kan mímọ́ fún Olúwa, kì í ṣe ọ̀sán, kì í ṣe òru; ṣùgbọ́n yóò ṣe pé, ni àṣálẹ́ ìmọ́lẹ̀ yóò wà.
Ũcio ũgaakorwo ũrĩ mũthenya wa mwanya, ũtarĩ mũthenya kana ũtukũ, mũthenya ũũĩo nĩ Jehova. Hwaĩ-inĩ wakinya, nĩgũkagĩa na ũtheri.
8 Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, omi ìyè yóò tí Jerusalẹmu sàn lọ; ìdajì wọn síhà Òkun ìlà-oòrùn, àti ìdajì wọn síhà okùn ẹ̀yìn: nígbà ẹ̀rùn àti nígbà òtútù ni yóò rí bẹ́ẹ̀.
Mũthenya ũcio maaĩ ma muoyo nĩmagatherera moimĩte Jerusalemu; nuthu yamo yerekere iria-inĩ rĩa mwena wa irathĩro, nayo nuthu ĩyo ĩngĩ yerekere iria-inĩ rĩa mwena wa ithũĩro. Maaĩ macio magathereraga hĩndĩ ya ũrugarĩ na hĩndĩ ya heho.
9 Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí gbogbo ayé; ni ọjọ́ náà ni Olúwa kan yóò wa orúkọ rẹ̀ nìkan náà ni orúkọ.
Jehova nĩwe ũgaatuĩka mũthamaki wa thĩ yothe. Mũthenya ũcio gũgaakorwo Jehova arĩ o we wiki, narĩo rĩĩtwa rĩake rĩkorwo no rĩo riiki.
10 A ó yí gbogbo ilẹ̀ padà bi pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan láti Geba dé Rimoni lápá gúúsù Jerusalẹmu: yóò di bí aginjù, ṣùgbọ́n a ó sì gbé Jerusalẹmu sókè, yóò sì gbe ipò rẹ̀, láti ibodè Benjamini títí dé ibi ibodè èkínní, dé ibodè igun nì, àti láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé ibi ìfúntí wáìnì ọba.
Bũrũri wothe kuuma Geba nginya Rimoni, mwena wa gũthini wa Jerusalemu, ũkaahaana ta Araba. No rĩrĩ, itũũra rĩa Jerusalemu nĩrĩgatũũgĩrio na rĩtũũre o hau rĩrĩ, kuuma Kĩhingo-inĩ kĩa Benjamini nginya harĩa Kĩhingo kĩa Mbere kĩrĩ, o nginya Kĩhingo-inĩ gĩa Koine, na kuuma mũthiringo ũrĩa mũraaya na igũrũ wa Hananeli gũthiĩ nginya ihihĩro-inĩ cia ndibei cia mũthamaki.
11 Ènìyàn yóò sì máa gbé ibẹ̀, kì yóò sì sí ìparun mọ́; ṣùgbọ́n a ó máa gbé Jerusalẹmu láìléwu.
Itũũra rĩu rĩgaatuĩka rĩa gũtũũrwo; rĩtikaanangwo hĩndĩ ĩngĩ. Itũũra rĩa Jerusalemu rĩgaatũũra rĩtarĩ na ũgwati.
12 Èyí ni yóò sì jẹ́ ààrùn tí Olúwa yóò fi kọlu gbogbo àwọn ènìyàn ti ó tí ba Jerusalẹmu jà; ẹran-ara wọn yóò rù nígbà tí wọn dúró ni ẹsẹ̀ wọn, ojú wọn yóò sì rà ni ihò wọn, ahọ́n wọn yóò sì bàjẹ́ ni ẹnu wọn.
Na rĩrĩ, ũyũ nĩguo mũthiro ũrĩa Jehova akaahũũra ndũrĩrĩ ciothe naguo, iria cianarũa na Jerusalemu: Mĩĩrĩ yao ĩkaabuthaga o marũgamĩte na magũrũ mao, maitho mao namo mabuthĩre marima-inĩ mamo, nacio nĩmĩ ciao ikaabutha irĩ tũnua-inĩ twao.
13 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò wà láàrín wọn; wọn ó sì di ọwọ́ ara wọn mú, ọwọ́ èkínní yóò sì dìde sì ọwọ́ èkejì rẹ̀.
Mũthenya ũcio-rĩ, Jehova nĩakahũũra andũ na kĩmako kĩnene. O mũndũ nĩakaguthũkĩra guoko kwa mũndũ ũrĩa ũngĩ akũnyiite, nao matharĩkanĩre marũe.
14 Juda pẹ̀lú yóò sì jà ni Jerusalẹmu: ọrọ̀ gbogbo àwọn kèfèrí tí ó wà káàkiri ni a ó sì kójọ, wúrà àti fàdákà, àti aṣọ, ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Andũ a Juda o nao nĩmakarũĩra kũu Jerusalemu. Ũtonga wa ndũrĩrĩ iria irigiicĩirie kũu nĩũkonganio, naguo nĩ ũtonga mũingĩ wa thahabu, na wa betha na wa nguo.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ààrùn ẹṣin, ìbáaka, ìbákasẹ, àti tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, yóò sì wà, àti gbogbo ẹranko tí ń bẹ nínú àgọ́.
Mũthiro o ta ũcio nĩũkaniina mbarathi na nyũmbũ, na ngamĩĩra na ndigiri, na nyamũ ciothe iria igaakorwo kambĩ-inĩ icio.
16 Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ẹni tí o kù nínú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó dìde sí Jerusalẹmu yóò máa gòkè lọ lọ́dọọdún láti sìn ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
Ningĩ-rĩ, matigari ma ndũrĩrĩ icio ciothe iria cianatharĩkĩra Jerusalemu makaambataga mwaka o mwaka kũhooya Mũthamaki, o we Jehova Mwene-Hinya-Wothe, na gũkũngũĩra Gĩathĩ gĩa Ithũnũ.
17 Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí kì yóò gòkè wá nínú gbogbo ìdílé ayé sí Jerusalẹmu láti sín ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, òjò kì yóò rọ̀ fún wọn.
Kũngĩkaagĩa andũ gũkũ thĩ matakaambata Jerusalemu kũhooya Mũthamaki, o we Jehova Mwene-Hinya-Wothe-rĩ, kwao gũtikoira mbura.
18 Bí ìdílé Ejibiti kò bá sì gòkè lọ, tí wọn kò sì wá, fi ara wọn hàn tí wọn kò ní òjò; ààrùn náà yóò wà, tí Olúwa yóò fi kọlù àwọn kèfèrí tí kò gòkè wá láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
Andũ a Misiri mangĩkaaga gũthiĩ kũnyiitanĩra na arĩa angĩ-rĩ, kwao gũtikoira mbura. Jehova nĩakamarehera mũthiro ũrĩa ahũũraga ndũrĩrĩ naguo iria itaambataga gũkũngũĩra Gĩathĩ kĩu gĩa Ithũnũ.
19 Èyí ni yóò sì jẹ́ ìyà Ejibiti, àti ìyà gbogbo orílẹ̀-èdè tí kò gòkè wá láti pa àsè àgọ́ mọ́.
Rĩĩrĩ nĩrĩo rĩgaakorwo rĩrĩ iherithia rĩa bũrũri wa Misiri, o na rĩa ndũrĩrĩ ciothe iria itaambataga igathiĩ gũkũngũĩra Gĩathĩ kĩu gĩa Ithũnũ.
20 Ní ọjọ́ náà ni “mímọ́ sí Olúwa” yóò wà lára ṣaworo ẹṣin: àti àwọn ìkòkò ni ilé Olúwa yóò sì dàbí àwọn ọpọ́n tí ń bẹ níwájú pẹpẹ.
Mũthenya ũcio-rĩ, mbugi cia mbarathi ikaandĩkwo, ICI CIAMŨRĨIRWO JEHOVA, nacio nyũngũ cia kũruga iria irĩ nyũmba ya Jehova thĩinĩ igaatuĩka ta mbakũri iria nyamũre irĩ mbere ya kĩgongona.
21 Nítòótọ́, gbogbo ìkòkò ni Jerusalẹmu àti ni Juda yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun: àti gbogbo àwọn tí ń rú ẹbọ yóò wá, wọn ó sì mú ìkòkò díẹ̀, wọn ó sì bọ ẹran wọn nínú rẹ̀, ni ọjọ́ náà ni àwọn Kenaani kò ní sí mọ́ ni ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Nyũngũ o yothe ĩrĩ kũu Jerusalemu na Juda ĩkaamũrĩrwo Jehova Mwene-Hinya-Wothe, nao arĩa othe magookaga kũruta igongona-rĩ, makooyaga nyũngũ imwe cia cio makaruga nacio. Na mũthenya ũcio-rĩ, gũtigacooka kũgĩa na mwonjorithia thĩinĩ wa nyũmba ya Jehova Mwene-Hinya-Wothe.

< Zechariah 14 >