< Zechariah 14 >

1 Kíyèsi i, ọjọ́ Olúwa ń bọ̀, a ó sì pín ìkógun rẹ̀ láàrín rẹ̀.
Lo! daies comen, seith the Lord, and thi spuylis schulen be departid in the myddil of thee.
2 Nítorí èmi ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí Jerusalẹmu fún ogun; a ó sì ko ìlú náà, a ó sì kó àwọn ilé, a ó sì ba àwọn obìnrin jẹ́, ààbọ̀ ìlú náà yóò lọ sí ìgbèkùn, a kì yóò sì gé ìyókù àwọn ènìyàn náà kúrò ni ìlú náà.
And Y schal gadere alle folkis to Jerusalem, in to batel; and the citee schal be takun, and housis schulen be distried, and wymmen schulen be defoulid. And the myddil part of the citee schal go out in to caitiftee, and the `tother part of the puple schal not be takun awei fro the citee.
3 Nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ, yóò sì bá àwọn orílẹ̀-èdè náà jà, gẹ́gẹ́ bí í ti ìjà ní ọjọ́ ogun.
And the Lord schal go out, and schal fiyte ayens tho folkis, as he fauyte in the dai of strijf.
4 Ẹsẹ̀ rẹ̀ yóò sì dúró ni ọjọ́ náà lórí òkè Olifi, tí ó wà níwájú Jerusalẹmu ni ìlà-oòrùn, òkè Olifi yóò sì là á sí méjì, sí ìhà ìlà-oòrùn àti ìhà ìwọ̀-oòrùn, àfonífojì ńlá ńlá yóò wà: ìdajì òkè náà yóò sì ṣí síhà àríwá, àti ìdajì rẹ̀ síhà gúúsù.
And hise feet schulen stonde in that dai on the hil of olyues, that is ayens Jerusalem at the eest. And the hil of olyues schal be coruun of the myddil part therof to the eest and to the west, bi ful greet biforbrekyng; and the myddil of the hil schal be departid to the north, and the myddil therof to the south.
5 Ẹ̀yin ó sì sá sí àfonífojì àwọn òkè mi, nítorí pé àfonífojì òkè náà yóò dé Aseli: nítòótọ́, ẹ̀yin ó sá bí ẹ tí sá fún ìmìmì-ilẹ̀ ni ọjọ́ Ussiah ọba Juda: Olúwa Ọlọ́run mi yóò sì wá, àti gbogbo àwọn Ẹni mímọ́ pẹ̀lú rẹ̀.
And ye schulen fle to the valei of myn hillis, for the valei of hillis schal be ioyned togidere til to the nexte. And ye schulen fle, as ye fledden fro the face of erthe mouyng in the daies of Osie, kyng of Juda; and my Lord God schal come, and alle seyntis with hym.
6 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìmọ́lẹ̀ kì yóò mọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ṣókùnkùn.
And it schal be, in that dai liyt schal not be, but coold and frost.
7 Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ ọjọ́ kan mímọ́ fún Olúwa, kì í ṣe ọ̀sán, kì í ṣe òru; ṣùgbọ́n yóò ṣe pé, ni àṣálẹ́ ìmọ́lẹ̀ yóò wà.
And `ther schal be o dai, which is knowun to the Lord, not day, nether niyt, and in tyme of euentid liyt schal be.
8 Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, omi ìyè yóò tí Jerusalẹmu sàn lọ; ìdajì wọn síhà Òkun ìlà-oòrùn, àti ìdajì wọn síhà okùn ẹ̀yìn: nígbà ẹ̀rùn àti nígbà òtútù ni yóò rí bẹ́ẹ̀.
And it schal be, in that dai quyke watris schulen go out of Jerusalem, the myddil of hem schal go out to the eest see, and the myddil of hem to the laste see; in somer and in wynter thei schulen be.
9 Olúwa yóò sì jẹ ọba lórí gbogbo ayé; ni ọjọ́ náà ni Olúwa kan yóò wa orúkọ rẹ̀ nìkan náà ni orúkọ.
And the Lord schal be kyng on al erthe; in that dai there schal be o Lord, and his name schal be oon.
10 A ó yí gbogbo ilẹ̀ padà bi pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan láti Geba dé Rimoni lápá gúúsù Jerusalẹmu: yóò di bí aginjù, ṣùgbọ́n a ó sì gbé Jerusalẹmu sókè, yóò sì gbe ipò rẹ̀, láti ibodè Benjamini títí dé ibi ibodè èkínní, dé ibodè igun nì, àti láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé ibi ìfúntí wáìnì ọba.
And al erthe schal turne ayen til to desert, fro the litil hil Remmon to the south of Jerusalem. And it schal be reisid, and schal dwelle in his place, fro the yate of Beniamyn til to place of the formere yate, and til to the yate of the corneris, and fro the tour of Ananyel til to the pressouris of the kyng.
11 Ènìyàn yóò sì máa gbé ibẹ̀, kì yóò sì sí ìparun mọ́; ṣùgbọ́n a ó máa gbé Jerusalẹmu láìléwu.
And thei schulen dwelle there ynne, and cursidnesse schal no more be, but Jerusalem schal sitte sikir.
12 Èyí ni yóò sì jẹ́ ààrùn tí Olúwa yóò fi kọlu gbogbo àwọn ènìyàn ti ó tí ba Jerusalẹmu jà; ẹran-ara wọn yóò rù nígbà tí wọn dúró ni ẹsẹ̀ wọn, ojú wọn yóò sì rà ni ihò wọn, ahọ́n wọn yóò sì bàjẹ́ ni ẹnu wọn.
And this schal be the wounde, bi which the Lord schal smyte alle folkis, that fouyten ayens Jerusalem; the fleisch of ech man stondynge on hise feet schal faile, and hise iyen schulen faile togidere in her hoolis, and her tunge schal faile togidere in her mouth.
13 Yóò sì ṣe ni ọjọ́ náà, ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá yóò wà láàrín wọn; wọn ó sì di ọwọ́ ara wọn mú, ọwọ́ èkínní yóò sì dìde sì ọwọ́ èkejì rẹ̀.
In that dai greet noise of the Lord schal be in hem, and a man schal catche the hond of his neiybore; and his hond schal be lockid togidere on hond of his neiybore.
14 Juda pẹ̀lú yóò sì jà ni Jerusalẹmu: ọrọ̀ gbogbo àwọn kèfèrí tí ó wà káàkiri ni a ó sì kójọ, wúrà àti fàdákà, àti aṣọ, ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
But and Judas schal fiyte ayens Jerusalem; and richessis of alle folkis in cumpas schulen be gaderide togidere, gold, and siluer, and many clothis ynow.
15 Bẹ́ẹ̀ ni ààrùn ẹṣin, ìbáaka, ìbákasẹ, àti tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, yóò sì wà, àti gbogbo ẹranko tí ń bẹ nínú àgọ́.
And so fallyng schal be of hors, and mule, and camel, and asse, and of alle werk beestis, that weren in tho castels, as this fallyng.
16 Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ẹni tí o kù nínú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó dìde sí Jerusalẹmu yóò máa gòkè lọ lọ́dọọdún láti sìn ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, àti láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
And alle that schulen be residue of alle folkis, that camen ayens Jerusalem, schulen stie vp fro yeer in to yeer, that thei worschipe the kyng, Lord of oostis, and halewe the feeste of tabernaclis.
17 Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí kì yóò gòkè wá nínú gbogbo ìdílé ayé sí Jerusalẹmu láti sín ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, òjò kì yóò rọ̀ fún wọn.
And it schal be, reyn schal not be on hem that schulen not stie vp of the meyneis of erthe to Jerusalem, `that thei worschipe the king, Lord of oostis.
18 Bí ìdílé Ejibiti kò bá sì gòkè lọ, tí wọn kò sì wá, fi ara wọn hàn tí wọn kò ní òjò; ààrùn náà yóò wà, tí Olúwa yóò fi kọlù àwọn kèfèrí tí kò gòkè wá láti ṣe àjọyọ̀ àsè àgọ́ náà.
`That and if the meynee of Egipt schal not stie vp, and schal not come, nether on hem schal be reyn; but fallyng schal be, bi which the Lord schal smyte alle folkis, whiche stieden not, for to halewe the feeste of tabernaclis.
19 Èyí ni yóò sì jẹ́ ìyà Ejibiti, àti ìyà gbogbo orílẹ̀-èdè tí kò gòkè wá láti pa àsè àgọ́ mọ́.
This schal be the synne of Egipt, and this the synne of alle folkis, that stieden not, for to halewe the feeste of tabernaclis.
20 Ní ọjọ́ náà ni “mímọ́ sí Olúwa” yóò wà lára ṣaworo ẹṣin: àti àwọn ìkòkò ni ilé Olúwa yóò sì dàbí àwọn ọpọ́n tí ń bẹ níwájú pẹpẹ.
In that dai, that that is on the bridil of hors schal be hooli to the Lord; and caudruns schulen be in the hous of the Lord, as cruetis bifor the auter.
21 Nítòótọ́, gbogbo ìkòkò ni Jerusalẹmu àti ni Juda yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun: àti gbogbo àwọn tí ń rú ẹbọ yóò wá, wọn ó sì mú ìkòkò díẹ̀, wọn ó sì bọ ẹran wọn nínú rẹ̀, ni ọjọ́ náà ni àwọn Kenaani kò ní sí mọ́ ni ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
And euery caudrun in Jerusalem and Juda schal be halewid to the Lord of oostis. And alle men schulen come offrynge, and schulen take of tho, and schulen sethe in tho; and a marchaunt schal no more be in the hous of the Lord of oostis in that day.

< Zechariah 14 >