< Zechariah 13 >

1 “Ní ọjọ́ náà ìsun kan yóò ṣí sílẹ̀ fún ilé Dafidi àti fún àwọn ará Jerusalẹmu, láti wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìmọ́ wọn.
در آن روز برای خاندان داود و ساکنان اورشلیم چشمه‌ای به جهت گناه ونجاست مفتوح خواهد شد.۱
2 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ni èmi ó gé orúkọ àwọn òrìṣà kúrò ni ilẹ̀ náà, a kì yóò sì rántí wọn mọ́, àti pẹ̀lú èmi ó mú àwọn wòlíì èké àti àwọn ẹ̀mí àìmọ́ kúrò ni ilẹ̀ náà.
و یهوه صبایوت می‌گوید در آن روز نامهای بتها را از روی زمین منقطع خواهم ساخت که بار دیگر آنها رابیادنخواهند‌آورد و انبیا و روح پلید را نیز از زمین دور خواهم کرد.۲
3 Yóò sì ṣe, nígbà tí ẹnìkan yóò sọtẹ́lẹ̀ síbẹ̀, ni baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí ó bí í yóò wí fún un pé, ‘Ìwọ ki yóò yè, nítorí ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ èké ni orúkọ Olúwa.’ Àti baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí o bí í yóò gun un ni àgúnpa nígbà tí ó bá sọtẹ́lẹ̀.
و هر‌که بار دیگر نبوت نمایدپدر و مادرش که او را تولید نموده‌اند، وی راخواهند گفت که زنده نخواهی ماند زیرا که به اسم یهوه دروغ می‌گویی. و چون نبوت نماید پدر ومادرش که او را تولید نموده‌اند، وی را عرضه تیغ خواهند ساخت.۳
4 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ojú yóò tí àwọn wòlíì èké olúkúlùkù nítorí ìran rẹ̀, nígbà tí òun ba tí sọtẹ́lẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì wọ aṣọ wòlíì onírun rẹ̀ tí o fi ń tan ní jẹ.
و در آن روز هر کدام از آن انبیاچون نبوت می‌کنند، از رویاهای خویش خجل خواهند شد و جامه پشمین به جهت فریب دادن نخواهند پوشید.۴
5 Ṣùgbọ́n òun o wí pé, ‘Èmi kí í ṣe wòlíì, àgbẹ̀ ni èmi; nítorí tí a ti fi mí ṣe ìránṣẹ́ láti ìgbà èwe mi wá.’
و هر یک خواهد گفت: من نبی نیستم بلکه زرع کننده زمین می‌باشم زیرا که ازطفولیت خود به غلامی فروخته شده‌ام.۵
6 Ẹnìkan ó sì wí fún un pé, ‘Ọgbẹ́ kín ní wọ̀nyí ni ẹ̀yìn rẹ?’ Òun o sì dáhùn pé, ‘Wọ̀nyí ni ibi tí a ti sá mi ní ilé àwọn ọ̀rẹ́ mi.’
و او راخواهند گفت: این جراحات که در دستهای تومی باشد چیست؟ و او جواب خواهد داد آنهایی است که در خانه دوستان خویش به آنها مجروح شده‌ام.۶
7 “Dìde, ìwọ idà, sí Olùṣọ́-àgùntàn mi, àti sí ẹni tí í ṣe ẹnìkejì mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Kọlu Olùṣọ́-àgùntàn, àwọn àgùntàn a sì túká: èmi o sì yí ọwọ́ mi sí àwọn kéékèèké.
یهوه صبایوت می‌گوید: «ای شمشیر به ضدشبان من و به ضد آن مردی که همدوش من است برخیز! شبان را بزن و گوسفندان پراکنده خواهندشد و من دست خود را بر کوچکان خواهم برگردانید.»۷
8 Yóò sì ṣe, ni gbogbo ilẹ̀,” ni Olúwa wí, “a ó gé apá méjì nínú rẹ̀ kúrò yóò sì kú; ṣùgbọ́n apá kẹta yóò kù nínú rẹ̀.
و خداوند می‌گوید که «در تمامی زمین دوحصه منقطع شده خواهند مرد و حصه سوم درآن باقی خواهد ماند.۸
9 Èmi ó sì mú apá kẹta náà la àárín iná, èmi yóò sì yọ́ wọn bí a ti yọ́ fàdákà, èmi yóò sì dán wọn wò, bi a tí ń dán wúrà wò: wọn yóò sì pé orúkọ mi, èmi yóò sì dá wọn lóhùn: èmi yóò wí pé, ‘Àwọn ènìyàn mi ni,’ àwọn yóò sì wí pé, ‘Olúwa ni Ọlọ́run wa.’”
و حصه سوم را از میان آتش خواهم گذرانید و ایشان را مثل قال گذاشتن نقره قال خواهم گذاشت و مثل مصفی ساختن طلا ایشان را مصفی خواهم نمود و اسم مراخواهند خواند و من ایشان را اجابت نموده، خواهم گفت که ایشان قوم من هستند و ایشان خواهند گفت که یهوه خدای ما می‌باشد.»۹

< Zechariah 13 >